< Eszter 8 >

1 Azon a napon, Ahasvéros király Eszter királynénak adta Hámánnak, a zsidók ellenségének házát. Mordecháj pedig a király közvetlen környezetébe került [szó szerint: bement a király elé], mert Eszter felfedte, ki ő neki.
Ní ọjọ́ kan náà ni ọba Ahaswerusi fún Esteri ayaba ní ilé e Hamani, ọ̀tá àwọn Júù. Mordekai sì wá síwájú ọba, nítorí Esteri ti sọ bí ó ṣe jẹ́ sí ọba.
2 A király lehúzta pecsétgyűrűjét amit elvett Hámántól és odaadta Mordechájnak, és Eszter kinevezte Mordechájt Hámán háza fölé.
Ọba sì bọ́ òrùka dídán an rẹ̀, èyí tí ó ti gbà lọ́wọ́ Hamani ó sì fi fún Mordekai, Esteri sì yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí ilé e Hamani.
3 Ezután Eszter ismét beszélt a királlyal, lába elé borult és sírva kért kegyelmet tőle, hogy hiúsítsa meg az agágita Hámán gonosz tervét, amelyet a zsidók ellen kigondolt.
Esteri sì tún bẹ ọba lórí ìkúnlẹ̀, pẹ̀lú omijé lójú. Ó bẹ̀ ẹ́ kí ó fi òpin sí ètò búburú Hamani ará Agagi, èyí tí ó ti pète fún àwọn Júù.
4 A király odanyújtotta Eszternek az aranypálcát, így Eszter felkelt, megállt a király előtt,
Nígbà náà ni ọba na ọ̀pá aládé wúrà sí Esteri ó sì dìde, ó dúró níwájú rẹ̀.
5 és azt mondta: ha jónak látja a király, s ha jóindulattal tekint rám, s helyesli a dolgot, és elnyertem a tetszését, adjon ki egy dekrétumot, melyben visszavonják az agágita Hámánnak, Hámdátá fiának a leveleit, melyeket minden tartományba elküldött a zsidók kipusztításáról,
Ó wí pé, “Bí ó bá wu ọba, tí ó bá sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ojúrere tí ó sì rò pé ohun tí ó dára ni láti ṣe, tí ó bá sì ní inú dídùn pẹ̀lú mi, jẹ́ kí a kọ ìwé àṣẹ láti yí ète tí Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi, tí ó kọ́ pàṣẹ pé kí a pa àwọn Júù tí wọ́n wà ní gbogbo àgbáyé ìjọba ọba run.
6 mert hogyan tudnám elnézni azt a veszedelmet, amely népemre vár, és hogyan tudnám elviselni rokonaim pusztulását?
Nítorí báwo ni èmi yóò ṣe fi ara dà á tí èmi yóò sì rí kí ibi máa ṣubú lu àwọn ènìyàn mi? Báwo ni èmi yóò ṣe fi ara dà á, tí èmi yóò sì máa wo ìparun àwọn ìdílé mi?”
7 Ahasvéros király így felelt Eszter királynénak és a zsidó Mordechájnak: Hámán házát már Eszternek adtam, őt pedig felakasztották, mert kezet emelt a zsidókra.
Ọba Ahaswerusi dá Esteri ayaba àti Mordekai ará a Júù náà lóhùn pé, “Nítorí Hamani kọlu àwọn ará a Júù, èmi ti fi ilé e rẹ̀ fún Esteri, wọ́n sì ti ṣo ó kọ́ sórí igi.
8 Ti meg írjatok a király nevében, amit a zsidók ügyében jónak láttok és pecsételjétek le a király gyűrűjével. Ugyanis az a rendelet, amit a király nevében írtak és a király gyűrűjével pecsételtek le – visszavonhatatlan.
Nísinsin yìí, kọ ìwé àṣẹ mìíràn ní orúkọ ọba bí àwọn Júù ṣe jẹ́ pàtàkì sí ọ, kí o sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì dì í, nítorí kò sí àkọsílẹ̀ tí a bá ti kọ ní orúkọ ọba tí a sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì tí a lè yìí padà.”
9 Abban az időben a harmadik hónapban, Sziván havában, annak huszonharmadik napján hívatták a király írnokait, akik leírtak mindazt, amit Mordecháj megparancsolta, a zsidóknak, a kormányzóknak, a helytartóknak és a tartományok vezető embereinek, melyet Indiától Etiópiáig, 127 tartományba, minden egyes nép saját nyelvén, a tartomány saját írásmódja szerint elküldtek, valamint a zsidóknak is a maguk írásával és a maguk nyelvén.
Lẹ́sẹ̀kan náà àwọn akọ̀wé ọba péjọ ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù kẹta, oṣù Sifani. Wọ́n kọ gbogbo àṣẹ Mordekai sí àwọn Júù, àti sí àwọn alákòóso baálẹ̀ àti àwọn ọlọ́lá ìgbèríko mẹ́tàdínláàádóje tí ó lọ láti India títí ó fi dé Kuṣi. Kí a kọ àṣẹ náà ní ìlànà bí ìgbèríko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọ̀wé àti bí èdè olúkúlùkù àti pẹ̀lú sí àwọn Júù ní ìlànà bí wọ́n ṣe ń kọ̀wé àti èdè e wọn.
10 Achasvéros király nevében íratta és megpecsételte a király gyűrűjével, és elküldte a leveleket a lovas futárokkal, akik a ménesekből származó úri paripákon nyargaltak:
Mordekai sì fi àṣẹ ọba Ahaswerusi kọ̀wé, ó sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì i rẹ̀, ó rán an lọ ní kíákíá, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ ayaba, tiwọn yára bí àṣà àwọn tí wọ́n ń gun ẹṣin tí ó yára, ní pàtàkì èyí tí a ń bọ́ fún ọba.
11 megengedte a király, hogy az egyes városokban lakó zsidók összegyűljenek életük védelmére, elpusztíthassák, megölhessék és elveszejthessék a népek és tartományok velük szemben ellenséges erőit, gyermekeiket és asszonyaikat, és hogy vagyonukat elzsákmányolják –
Àṣẹ ọba sì dé ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní gbogbo ìlú láti kó ara wọn jọ kí wọn sì dáàbò bo ara wọn; láti pa, láti run àti láti kọlu ogunkógun orílẹ̀-èdè kórílẹ̀ èdè kankan tàbí ìgbèríko tí ó bá fẹ́ kọlù wọ́n, àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wọn; kí ẹ sì kó gbogbo ohun ìní àwọn ọ̀tá wọn.
12 ugyanazon a napon Achasvérós király valamennyi tartományában, a tizenkettedik hónapnak, Ádár havának tizenharmadik napján.
Ọjọ́ tí a yàn fún àwọn Júù ní gbogbo agbègbè ọba Ahaswerusi láti ṣe nǹkan yìí ni ọjọ́ kẹtàlá èyí tí í ṣe oṣù kejìlá, oṣù Addari.
13 Az irat másolatát rendeletként adták ki mindegyik tartományban, nyilvánosan mind a népeknek, és a zsidóknak, hogy készen legyenek ezen a napon bosszút állni ellenségeiken.
Ọkàn ìwé àṣẹ náà ni kí a gbé jáde gẹ́gẹ́ bí òfin ní gbogbo ìgbèríko kí ẹ sì jẹ́ kí ó di mí mọ̀ fún gbogbo ènìyàn ìlú nítorí àwọn Júù yóò le è múra ní ọjọ́ náà láti gbẹ̀san fún ara wọn lára àwọn ọ̀tá wọn.
14 Az úri paripákon nyargaló futárok pedig sebtiben és sietve indultak a király parancsára. A rendeletet pedig kiadták Susán fovárosban.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ ayaba tiwọn yára bí àṣà tí wọ́n ń gun ẹṣin ọba, sáré jáde, wọ́n sáré lọ nípa àṣẹ ọba. A sì tún gbé àṣẹ náà jáde ní ilé ìṣọ́ ti Susa.
15 Ezután Mordecháj távozott a király színe elől bíborkék és fehér királyi öltözetben nagy arany koronával, bisszus és bíborpiros palástban. Susán városa ujjongott s örvendett.
Mordekai sì kúrò níwájú ọba, ó wọ aṣọ aláró àti funfun, ó dé adé e wúrà ńlá pẹ̀lú ìgbànú elése àlùkò dáradára, ìlú Susa sì ṣe àjọyọ̀ ńlá.
16 A zsidóknak fény és öröm jutott, meg vígság és megbecsülés.
Àsìkò ìdùnnú àti ayọ̀, inú dídùn àti ọlá ni ó jẹ́ fún àwọn Júù.
17 Minden egyes tartományban és helységben, ahová a király parancsa eljutott örültek a zsidók. Az ország lakosságából sokan zsidóvá lettek, mert elfogta őket a zsidóktól való félelem.
Ní gbogbo ìgbèríko àti ní gbogbo ìlú, ní gbogbo ibi tí àṣẹ ọba dé, ni ayọ̀ àti inú dídùn ti wà láàrín àwọn Júù, wọ́n sì ń ṣe àsè àti àjọyọ̀. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú tókù sọ ara wọn di Júù nítorí ẹ̀rù àwọn Júù bà wọ́n.

< Eszter 8 >