< 2 Királyok 8 >

1 Elísá pedig szólt ahhoz az asszonyhoz, kinek a fiát fölélesztette, mondván: Kelj föl és menj el, te meg házad, és tartózkodj, ahol tartózkodhatsz, mert szólította az Örökkévaló az éhséget, és be is jött az országba hét évre.
Nísinsin yìí, Eliṣa wí fún obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin jí padà sáyé pé, “Jáde lọ pẹ̀lú ìdílé rẹ kí o sì lọ dúró fún ìgbà díẹ̀ ní ibikíbi tí o bá le dúró sí, nítorí Olúwa ti pàṣẹ ìyàn ní ìlú tí yóò lò tó ọdún méje.”
2 Erre fölkelt az asszony és cselekedett az Isten emberének szava szerint; elment ő meg háza s tartózkodott a filiszteusok országában hét évig.
Obìnrin náà tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ti sọ. Òun àti ìdílé rẹ̀ sí lọ, wọ́n sì ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọdún méje.
3 És volt hét év múltán, visszatért az asszony a filiszteusok országából és elindult, hogy kiáltson a királyhoz háza miatt és mezeje miatt.
Ní ẹ̀yìn ọdún méje ó sì padà wá láti ilẹ̀ àwọn ará Filistini ó sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba láti lọ bẹ̀ ẹ́ fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀.
4 A király éppen szólt Géchazíhoz, az Isten emberének legényéhez, mondván: Beszéld el, kérlek, nekem mind a nagy dolgokat, melyeket művelt Elísá.
Ọba sì ń sọ̀rọ̀ sí Gehasi, ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run pé, “Sọ fún mi nípa gbogbo ohun ńlá tí Eliṣa ti ṣe.”
5 S midőn éppen elbeszélte a királynak azt, hogy fölélesztette a halottat, íme az asszony, kinek fiát fölélesztette volt, kiáltott a királyhoz háza miatt és mezeje miatt. Ekkor mondta Géchazí: Uram király, ez az asszony és ez a fia, kit fölélesztett Elísá
Bí Gehasi ti ń sọ bí tí Eliṣa ṣe jí òkú di alààyè, obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tí Eliṣa ti dá padà sí ayé wá láti bẹ ọba fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀. Gehasi sì wí pé, “Obìnrin náà nìyìí olúwa mi ọba, ọmọkùnrin rẹ náà nìyí tí Eliṣa ti jí dìde sí ayé.”
6 Erre megkérdezte a király az asszonyt, és elbeszélte neki. És adott melléje a király egy udvari tisztet, mondván: Szerezd vissza mindazt, a mi az övé és mind a mező termését, azon naptól fogva, hogy elhagyta az országot mostanáig.
Ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà nípa rẹ̀, ó sì sọ fún un. Ó sì yan ìjòyè kan fún ún fún ọ̀rọ̀ rẹ̀ ó sì wí fún un pé, “Ẹ fún un padà gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tirẹ̀, àti pẹ̀lú gbogbo èrè ilé rẹ̀ fún ún láti ọjọ́ tí ó ti kúrò ní ìlú títí di àsìkò yìí.”
7 Elment Elísá Damaszkuszba, Ben-Hadád pedig, Arám királya, beteg volt; tudtára adták neki, mondván: Ide jött az Isten embere.
Eliṣa lọ sí Damasku, Beni-Hadadi ọba Siria ń ṣe àìsàn. Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba pé, “Ènìyàn Ọlọ́run ti wá láti gbogbo ọ̀nà òkè síbí,”
8 És szólt a király Chazáélhez: Végy a kezedbe ajándékot és menj az Isten emberének elejébe és kérdezd meg tőle az Örökkévalót, mondván: meggyógyulok-e ebből a betegségből?
ọba sì wí fún Hasaeli pé, “Mú ọrẹ lọ́wọ́ rẹ, sì lọ pàdé ènìyàn Ọlọ́run. Kí o sì béèrè Olúwa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn yìí?”
9 Elejébe ment tehát Chazáél, vett a kezébe ajándékot, meg Damaszkusz minden javát, negyven teve terhét; oda ment, megállt előtte és mondta: Fiad Ben-Hadád, Arám királya, küldött engem hozzád, mondván: meggyógyulok-e ebből a betegségből?
Hasaeli lọ láti pàdé Eliṣa, ó mú lọ pẹ̀lú rẹ̀ ẹ̀bùn gẹ́gẹ́ bí ogójì ẹrù ìbákasẹ tí gbogbo ìní tí ó dára jù fún wíwò ti Damasku, ó sì wọlé lọ ó sì dúró níwájú rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọ rẹ Beni-Hadadi ọba Siria rán mi láti béèrè pé, ‘Ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn mi yìí?’”
10 Szólt hozzá Elísá: Menj, mondd neki: meg fogsz gyógyulni. De az Örökkévaló azt láttatta velem, hogy meg fog halni.
Eliṣa da á lóhùn pé, “Lọ kí o lọ sọ fún un pé, ‘Ìwo ìbá sàn nítòótọ́’; ṣùgbọ́n Olúwa ti fihàn mí pé nítòótọ́ òun yóò kùú.”
11 Megmerevítette az arcát és feléje fordította szégyellésig; ekkor sírt az Isten embere.
Ó sì ranjú mọ́ ọn pẹ̀lú àtẹjúmọ́ gidigidi títí tí ojú fi ti Hasaeli. Nígbà náà ènìyàn Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
12 És mondta Chazáél: Miért sír uram? Mondta: Mert tudom, mi rosszat fogsz tenni Izraél fiaival: erősségeiket tűzbe borítod, ifjaikat karddal ölöd meg, kisdedeiket szétzúzod és várandósaikat fölhasítod.
“Kí ni ó dé tí olúwa mi fi ń sọkún?” Hasaeli béèrè. “Nítorí pé èmi mọ ibi tí ìwọ yóò ṣe sí Israẹli,” ó sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò fi iná si odi agbára wọn, ìwọ yóò, pa àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin wọn pẹ̀lú idà, ìwọ yóò kọlù àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ wọn, ìwọ ó sì fọ́ wọn túútúú, ìwọ o sì la inú àwọn aboyún wọn.”
13 Erre mondta Chazáél: Micsoda a te szolgád, a kutya, hogy ezt a nagy dolgot mívelje? Mondta Elísá: Láttatta velem az Örökkévaló, hogy te leszel király Arám fölött.
Hasaeli sì wí pé. “Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ, ajá lásán làsàn yóò ṣe ṣe irú nǹkan ńlá bẹ́ẹ̀?” “Olúwa ti fihàn mí pé ìwọ ni yóò jẹ ọba Siria,” Eliṣa dá a lóhùn.
14 Elment Elísától és bement urához. Mondta neki: Mit mondott neked Elísá? Mondta: Azt mondta nekem, meg fogsz gyógyulni.
Nígbà náà Hasaeli fi Eliṣa sílẹ̀ ó sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀. Nígbà tí Beni-Hadadi béèrè, “Kí ni ohun tí Eliṣa sọ fún ọ?” Hasaeli dá a lóhùn, “Ó sọ fún mi wí pé ìwọ yóò sàn nítòótọ́.”
15 És volt másnap, fogta a takarót, vízbe mártotta, arcára terítette, és meghalt. És király lett helyette Chazáél.
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì ó mú aṣọ tí ó nípọn, ó sì kì í bọ inú omi ó sì tẹ̀ ẹ́ sí ojú ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó sì kú. Nígbà náà Hasaeli sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
16 És ötödik évében Jórámnak, Acháb fiának, aki Izraél királya volt, míg Jehósáfát még királya volt Jehúdának, király lett Jehórám, Jehósáfátnak, Jehúda királyának fia.
Ní ọdún karùn-ún ti Joramu ọmọ Ahabu ọba Israẹli, nígbà tí Jehoṣafati jẹ́ ọba Juda, Jehoramu ọmọ Jehoṣafati bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba Juda.
17 Harminckét éves volt, mikor király lett, és nyolc évig uralkodott Jeruzsálemben.
Ó jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
18 És járt Izraél királyainak útjain, amint cselekedtek az Acháb házából valók, mert Achábnak leányát vette feleségül; és tette azt, a mi rossz az Örökkévaló szemeiben.
Ó sì rìn ní ọ̀nà ọba Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti lọ, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu ó sì ṣe ohun búburú níwájú Olúwa.
19 De nem akarta az Örökkévaló elpusztítaní Jehúdát Dávid, az ő szolgája kedvéért, amint mondta neki, hogy ad mécsest neki és fiainak minden időben.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi. Olúwa kò fẹ́ pa Juda run, ó ti ṣèlérí láti ṣètọ́jú ìmọ́lẹ̀ fún Dafidi àti àwọn ilé rẹ̀ títí láéláé.
20 Az ő napjaiban pártolt el Edóm Jehúda keze alól és tettek maguk fölé királyt.
Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
21 Ekkor Jórám Cáírba vonult s az egész szekérhad ő vele. És ő fölkelt éjjel és megverte Edómot, mely körülvette őt meg a szekérhad vezéreit, és megfutott a nép a sátraihoz.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoramu lọ sí Sairi pẹ̀lú gbogbo kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Àwọn ará Edomu sì yí i ká àti kẹ̀kẹ́ àwọn olórí wọn, ṣùgbọ́n ó dìde dúró ní òru; àwọn ogun rẹ̀ síbẹ̀síbẹ̀, sá padà lọ ilé.
22 Így elpártolt Edóm Jehúda keze alól mind e mai napig; akkor pártolt el Libna abban az időben.
Títí ó fi di òní, Edomu wà nínú ọ̀tẹ̀ lórí Juda, Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkókò kan náà.
23 Jórám egyéb dolgai pedig és mindaz, amit tett, nemde meg vannak írva Jehúda királyai történetének könyvében.
Gẹ́gẹ́ bí fún iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Jehoramu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
24 És feküdt Jórám ősei mellé és eltemették ősei mellett Dávid városában. És király lett utána fia, Achazjáhú.
Jehoramu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi, Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
25 Tizenkettedik évében Jórámnak, Acháb fiának, Izraél királyának, király lett Achazjáhú, Jehórámnak, Jehúda királyának fia.
Ní ọdún méjìlá Joramu ọmọkùnrin Ahabu ọba Israẹli, Ahasiah ọmọkùnrin Jehoramu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀.
26 Huszonkét éves volt Achazjáhu, mikor király lett, és egy évig uralkodott Jeruzsálemben; anyjának neve pedig Ataljáhú, Omrinak Izraél királyának leánya.
Ahasiah jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní ọdún kan ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Ataliah, ọmọbìnrin Omri ọba Israẹli.
27 És járt Acháb házának útján és tette azt, a mi rossz az Örökkévaló szemeiben, valamint Acháb háza, mert Acháb házának volt a veje.
Nígbà tí ó rin ọ̀nà ilé Ahabu ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe, nítorí ó tan nípa ìgbéyàwó sí ìdílé Ahabu.
28 Elment Jórámmal, Acháb fiával háborúba Chazáél, Arám királya ellen Rámót-Gileádba; de megverték az Arámbeliek Jórámot.
Ahasiah sì lọ pẹ̀lú Joramu ọmọ Ahabu lọ sí ogun lórí Hasaeli ọba Aramu ní Ramoti Gileadi. Àwọn ará Siria ṣẹ́ Joramu lẹ́sẹ̀.
29 És visszament Jórám király, hogy gyógíttassa magát Jizreélben a sebekből, melyeket ütöttek rajta az Arámbelíek Rámában, amikor harcolt Chazáél, Arám királya ellen; Achazjáhú, Jehórám fia pedig, Jehúda királya, lement, hogy meglátogassa Jórámot, Acháb fiát Jizreélben, mert beteg volt.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Joramu padà sí Jesreeli láti wo ọgbẹ́ rẹ̀ sàn tí ará Siria ti jẹ ní yà lórí rẹ̀ ní Ramoti ní ojú ogun rẹ̀ pẹ̀lú Hasaeli ọba Aramu. Nígbà náà Ahasiah ọmọ Jehoramu ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jesreeli láti lọ wo Joramu ọmọ Ahabu nítorí tí ó fi ara pa.

< 2 Királyok 8 >