< 2 Krónika 1 >
1 És megerősödött Salamon, Dávid fia, az ő királyságában és az Örökkévaló, az ő Istene vele volt, naggyá tette őt felette naggyá.
Solomoni ọmọ Dafidi fìdí ara rẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin lórí ìjọba rẹ̀. Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú u rẹ̀, ó sì jẹ́ kí ó ga lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
2 És mondta Salamon egész Izraelnek, az ezrek és százak nagyjainak, meg a bíráknak s egész Izrael minden főemberének, az atyai házak fejeinek;
Nígbà náà, Solomoni bá gbogbo Israẹli sọ̀rọ̀ sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, sí àwọn adájọ́ àti sí gbogbo àwọn olórí Israẹli, àwọn olórí ìdílé
3 s elmentek Salamon s az egész gyülekezet vele a Gibeónban levő magaslatra, mert ott volt Istennek a találkozás-sátra, melyet készített Mózes, az Örökkévaló szolgája a pusztában.
pẹ̀lú Solomoni, àti gbogbo àpéjọ lọ sí ibi gíga ní Gibeoni, nítorí àgọ́ Ọlọ́run fún pípàdé wà níbẹ̀, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pa ní aginjù.
4 Azonban az Isten ládáját felvitte Dávid Kirját-Jeárimból azon helyre, melyet előkészített számára Dávid, mert sátrat vont számára Jeruzsálemben.
Nísinsin yìí, Dafidi ti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run wá láti Kiriati-Jearimu sí ibi tí ó ti pèsè fún un, nítorí ó ti kọ́ àgọ́ fún un ni Jerusalẹmu.
5 De a rézoltár, melyet készített Becalél, Úrinak, Chúr fiának fia, ott volt az Örökkévaló hajléka előtt, azt kereste fel Salamon meg a gyülekezet.
Ṣùgbọ́n pẹpẹ idẹ tí Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ṣe wà ní Gibeoni níwájú àgọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Solomoni àti gbogbo àpéjọ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ níbẹ̀.
6 És áldozott Salamon ott az Örökkévaló előtt levő rézoltáron, mely a találkozás sátrához tartozott, áldozott rajta ezer égőáldozatot.
Solomoni gòkè lọ sí ibi pẹpẹ idẹ níwájú Olúwa ní ibi àgọ́ ìpàdé, ó sì rú ẹgbẹ̀rún ẹbọ sísun lórí rẹ̀.
7 Amaz éjjel megjelent az Isten Salamonnak és mondta neki: Kérj, mit adjak neked?
Ní òru ọjọ́ náà, Ọlọ́run farahàn Solomoni, ó sì wí fún un pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́ kí n fún ọ.”
8 És mondta Salamon Istennek: Te nagy szeretetet műveltél atyámmal Dáviddal, és királynak tettél engem ő helyette.
Solomoni dá Ọlọ́run lóhùn pé, “Ìwọ ti fi àánú ńlá han Dafidi baba mi, ìwọ sì ti fi mí jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
9 Most, oh Örökkévaló Isten, valósuljon meg atyámnak tett igéd; mert te királynak tettél engem, oly nép fölött, mely számos, mint a föld pora.
Nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ìlérí rẹ sí baba à mi Dafidi wá sí ìmúṣẹ, nítorí ìwọ ti fi mí jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn tí ó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀.
10 Most bölcsséget és tudást adj nekem, hogy kivonuljak és bevonuljak eme nép előtt, mert ki lehet bírája a nagy népednek?
Fún mi ní ọgbọ́n àti ìmọ̀, kí èmi kí ó lè máa wọ ilé kí ń sì máa jáde níwájú ènìyàn wọ̀nyí, nítorí ta ni ó le è ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ tí ó pọ̀ yanturu wọ̀nyí?”
11 És mondta Isten Salamonnak: Mivelhogy ez van a szívedben s nem kértél gazdagságot, birtokokat és dicsőséget, sem nem gyűlölőidnek életét, hosszú életet sem kértél, hanem kértél magadnak bölcsességet és tudást, hogy bírája légy népemnek, amely fölé királynak tettelek:
Ọlọ́run wí fún Solomoni pé, “Níwọ́n ìgbà tí ó jẹ́ pé ìfẹ́ ọkàn rẹ nìyí, tí ìwọ kò sì béèrè, fún ọrọ̀, ọlá tàbí ọ̀wọ̀, tàbí fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, àti nígbà tí ìwọ kò ti béèrè fún ẹ̀mí gígùn, ṣùgbọ́n tí ìwọ béèrè fún ọgbọ́n àti ìmọ̀ láti ṣàkóso àwọn ènìyàn mi tí èmi fi ọ́ jẹ ọba lé lórí.
12 a bölcsesség és a tudás meg van adva neked, de gazdagságot s birtokokat és dicsőséget fogok neked adni, amilyen még nem volt az előtted volt királyoknak a utánad sem lesz olyan.
Nítorí náà, ọgbọ́n àti ìmọ̀ ni a ó fi fún ọ, Èmi yóò sì fún ọ ní ọrọ̀, ọlá àti ọ̀wọ̀, irú èyí tí ọba ti ó wà ṣáájú rẹ kò ní, tí àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ kò sì ní ní irú rẹ̀.”
13 És eljött Salamon Jeruzsálembe a Gibeónban levő magaslatról, a találkozás sátra elől, és király volt Izrael felett.
Nígbà náà ni Solomoni sì ti ibi gíga Gibeoni lọ sí Jerusalẹmu láti iwájú àgọ́ ìpàdé. Ó sì jẹ ọba lórí Israẹli.
14 És gyűjtött Salamon szekereket és lovakat: volt neki ezer négyszáz szekere és tizenkétezer lovasa; és elhelyezte a szekérvárosokban s a király mellett Jeruzsálemben.
Solomoni kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ, ó sì ní ẹgbàáje kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin, tí ó kó pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ ogun àti pẹ̀lú rẹ̀ ni Jerusalẹmu.
15 S olyanná tette a király az ezüstöt és az aranyat Jeruzsálemben, mintha kő volna; s a cédrusfákat annyivá tette, mint az alföldön levő vad fügefákat sokaságra.
Ọba náà ṣe fàdákà àti wúrà gẹ́gẹ́ bí ó ti wọ́pọ̀ ní Jerusalẹmu bí òkúta, àti kedari ó pọ̀ bí igi sikamore ní àwọn ẹsẹ̀ òkè.
16 A Salamon számára való lovaknak kivitele Egyiptomból történt; csapatban vették a király kereskedői, csapatonként bizonyos áron:
Àwọn ẹṣin Solomoni ní a gbà láti ìlú òkèrè Ejibiti àti láti kún ọ̀gbọ̀ oníṣòwò ti ọba ni gba okun náà ní iye kan.
17 fölhoztak és kivittek Egyiptomból egy szekeret hatszáz ezüstön, egy lovat pedig százötvenen. Így mind a hittiták királyai és Arám királyai számára is általuk történt a kivitel.
Wọ́n ra kẹ̀kẹ́ kan láti Ejibiti. Fún ẹgbẹ̀ta ṣékélì fàdákà àti ẹṣin kan fún ọgọ́rin méjìdínláàádọ́ta. Wọ́n ko wọn lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba mìíràn ti Hiti àti ti àwọn ará Aramu.