< 2 Krónika 20 >

1 És történt ezután, jöttek Móáb fiai meg Ammón fiai és velük a Máónbeliek közül Jehósáfát ellen háborúra;
Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
2 jöttek s tudtára adták Jehósáfátnak, mondván: Jött ellened nagy tömeg a tengerentúlról, Arámból, s íme ők Chacecón-Támárban vannak, Én-Gédi az;
Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
3 akkor félt és arra irányította arcát Jehósáfát, hogy keresse az Örökkévalót; és böjtöt hirdetett egész Jehúdára.
Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
4 És gyülekeztek a Jehúdabeliek, hogy kérjék az Örökkévalót; mind a Jehúda városaiból is jöttek, hogy kérjék az Örökkévalót.
Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
5 És ott állt Jehósáfát Jehúda és Jeruzsálem gyülekezetében, az Örökkévaló házában, az új udvar előtt.
Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
6 És mondta: Örökkévaló, őseink Istene, nemde te vagy az Isten az égben s te uralkodsz mind a nemzetek királyságain, s a te kezedben van erő s hatalom, s nincs senki, hogy melletted megállhatna.
O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
7 Nemde te, oh istenünk, elűzted ennek ez országnak lakóit néped Izrael elől s odaadtad barátod Ábrahám magzatjának örökre,
Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
8 s ők megtelepedtek abban és építettek neked abban szentélyt neved számára, mondván:
Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
9 Ha jönne miránk baj, kard, büntetés, vagy dögvész, vagy éhség: hadd állunk eme ház elé és a te színed elé, mert a te neved van ebben a házban, s kiáltsunk tehozzád szorultságunkból, és te hallod és segítesz.
‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
10 És most, íme Ammón fiai és Móáb és a Széir hegybeliek, akik közé mennie Izraelnek nem engedted, midőn Egyiptom földjéről jöttek, hanem kitértek előlük és nem semmisítették meg őket-
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
11 íme ők viszonozzák minekünk, eljövén, hogy elűzzenek minket örökségedből, amelyet nekünk örökbe adtál –
Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
12 Istenünk, nemde ítéletet teszel rajtuk, mert bennünk nincs erő eme nagy tömeggel szemben, amely jön ellenünk; s mi nem tudjuk mit tegyünk, hanem csak te feléd fordulnak szemeink.
Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
13 És egész Jehúda ott állt az Örökkévaló színe előtt, kisdedeik is, nejeik s fiaik.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
14 És Jachazíél, Zekharjáhú fia, Benája fia, Jeíél fia, Mattanja fia, az Aszáf fiai közül való levita – volt rajta az Örökkévaló szelleme a gyülekezet közepette.
Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
15 És mondta: Figyeljetek egész Jehúda és Jeruzsálem lakói és te Jehósáfát király! Így szól nektek az Örökkévaló: ti ne féljetek s ne rettegjetek a nagy tömegtől, mert nem tietek a harc, hanem az Istené.
Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
16 Holnap szálljatok le ellenük; íme ők feljönnek a Czicz hágóján, s megtaláljátok őket a völgy végén, Jerúél pusztával szemben.
Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
17 Nem tinektek kell itt harcolnotok; állapodjatok meg, álljatok meg és lássátok az Örökkévalónak segítségét ti veletek. Jehúda és Jeruzsálem! Ne féljetek s ne rettegjetek, holnap vonuljatok ki ellenük, s az Örökkévaló veletek lesz.
Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
18 És meghajtotta magát Jehósáfát arccal a földre; egész Jehúda pedig és Jeruzsálem lakói levetették magukat az Örökkévaló előtt, leborulván az Örökkévaló előtt.
Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
19 És felkeltek a kehhátiak fiai közül és a kórachiak fiai közül való leviták, hogy dicsérjék az Örökkévalót, Izrael Istenét, felette nagy hangon.
Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
20 És felkeltek reggel s kimentek Tekóa pusztájába; s midőn kivonultak, odaállt Jehósáfát s mondta: Hallgassatok meg engem, Jehúda és Jeruzsálem lakói, bízzatok az Örökkévalóban, a ti Istenetekben és biztosságtok lesz, bízzatok prófétáiban s szerencsések lesztek.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
21 És tanácskozott a néppel s felállított énekeseket az Örökkévalónak, akik ugyanis dicsérték szent díszben, midőn vonultak a fegyveres csapat előtt s mondták: Adjatok hálát az Örökkévalónak, mert örökké tart az ő kegyelme.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
22 És amidőn elkezdettek fohászkodással és dicsérő dallal, akkor az Örökkévaló lesbenállókat szerzett Ammón fiai meg Móáb és a Széir hegybeliek ellen, akik Jehúda ellen jöttek volt, és sújtva lettek.
Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
23 És felkeltek Ammón fiai és Móáb Széir hegyének lakói ellen, hogy kiirtsák és megsemmisítsék és midőn végeztek Széir lakóival, akkor egyike a másikát segítette elpusztításra.
Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
24 Jehúda pedig odament a pusztára tekintő magaslatra, s a tömeg felé fordultak, és íme azok földre terült hullák, menekülés nélkül.
Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
25 És odament Jehósáfát s népe, hogy elprédálják zsákmányukat, s találtak közöttük tömegesen vagyont is, ruhákat is, meg drága edényeket, és elvitték maguknak, úgy hogy elhordani nem bírták; s így három napig prédálták el a zsákmányt, mert sok volt.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
26 A negyedik napon pedig gyülekeztek Berákha völgyében, mert ott áldották az Örökkévalót; azért így nevezték el azt a helyet: Berákha völgye, mind a mai napig.
Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
27 És visszafordultak mind Jehúda és Jeruzsálem emberei és Jehósáfát az élükön, hogy visszatérjenek Jeruzsálembe örömmel, mert megörvendeztette őket az Örökkévaló ellenségeik fölött.
Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
28 És megérkeztek Jeruzsálembe lantokkal, hárfákkal és trombitákkal, az Örökkévaló házához.
Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
29 És volt az Isten rettegése mind az országok királyságain, midőn meghallották, hogy az Örökkévaló harcolt Izrael ellenségeivel.
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
30 És nyugodt volt Jehósáfát uralma, s nyugalmat szerzett neki Istene köröskörül.
Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
31 És uralkodott Jehósáfát Jehúda fölött; harmincöt éves volt, midőn király lett, és huszonöt évig uralkodott Jeruzsálemben; anyjának neve pedig Azúba, Silchi leánya.
Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
32 És járt atyjának, Ászának útján, nem tért le arról, tévén azt, ami helyes az Örökkévaló szemeiben.
Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
33 Csak a magaslatok nem szűntek meg, és a nép még nem irányította szívét ősei Istene felé.
Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
34 Jehósáfát egyéb dolgai pedig, az előbbiek és utóbbiak, íme meg vannak írva Jéhúnak, Chanáni fiának beszédei között, amelyek fölvétettek Izrael királyainak könyvébe.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
35 És azután szövetkezett Jehósáfát, Jehúda királya, Achazjával, Izrael királyával, aki gonoszul cselekedett.
Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
36 És szövetségesévé tette őt, hogy készítsenek hajókat, melyek Tarsisba menjenek; és készítettek hajókat Ecjón-Géberben.
Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
37 És prófétált Eliézer, Dódáváhú fia, Márésából, Jehósáfát ellen, mondván: Mivelhogy szövetkeztél Achazjáhúval, rést tört az Örökkévaló a te műveden. És a hajók összetörtek és nem bírtak Tarsisba menni.
Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.

< 2 Krónika 20 >