< 1 Sámuel 21 >
1 És eljutott Dávid Nóbba Achímélekh paphoz; és elésietett Achímélekh Dávidnak és mondta neki: Mért vagy te egyedül és senki sincs veled?
Dafidi sì wá sí Nobu sọ́dọ̀ Ahimeleki àlùfáà, Ahimeleki sì bẹ̀rù láti pàdé Dafidi, ó sì wí fún un pé, “Èéha ti rí tí o fi ṣe ìwọ nìkan, àti tí kò sì sí ọkùnrin kan tí ó pẹ̀lú rẹ?”
2 Mondta Dávid Achímélekh papnak: A király parancsolt nekem valamit és szólt hozzám: senki ne tudja semmiképpen a dolgot, melyben küldelek és melyet neked parancsoltam; a legényeket pedig odarendeltem egy bizonyos helyre.
Dafidi sì wí fún Ahimeleki àlùfáà pé, “Ọba pàṣẹ iṣẹ́ kan fún mi, ó sì wí fún mi pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ìdí iṣẹ́ náà ti mo rán ọ, àti èyí tí èmi ti pàṣẹ fún ọ.’ Èmi sì yan àwọn ìránṣẹ́ mi sí ibí báyìí.
3 Most pedig, mi van kezed alatt, öt kenyér-e, add a kezembe, vagy ami található.
Ǹjẹ́ kín ni ó wà ní ọwọ́ rẹ̀? Fún mi ni ìṣù àkàrà márùn-ún tàbí ohunkóhun tí o bá rí.”
4 Felelt a pap Dávidnak és mondta: Nincs közönséges kenyér kezem alatt, hanem szentkenyér van – hacsak asszonytól óvakodtak a legények.
Àlùfáà náà sí dá Dafidi lóhùn ó sì wí pé, “Kò sí àkàrà mìíràn lọ́wọ́ mi bí kò ṣe àkàrà mímọ́. Kìkì pé bi àwọn ọmọkùnrin bá ti pa ara wọn mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin!”
5 És felelt Dávid a papnak és mondta neki: Sőt inkább, asszony tiltva van nekünk, mint tegnap; tegnapelőtt; amikor elindultam, szentek voltak a legények edényei – pedig ez közönséges út – hát még ma, hogy szentség lesz az edényben!
Dafidi sì dá àlùfáà náà lóhùn, ó sì wí fún un pé, “Nítòótọ́ ni a tí ń pa ara wá mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin láti ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta wá, tí èmí ti jáde. Gbogbo nǹkan àwọn ọmọkùnrin náà ni ó mọ́, àti àkàrà náà sì wá dàbí àkàrà mìíràn, pàápàá nígbà tí ó jẹ́ pé òmíràn wà tí a yà sí mímọ́ lónìí nínú ohun èlò náà!”
6 És adott neki a pap szentséget, mert nem volt ott kenyér, csak a színkenyér, mely eltávolíttatott az Örökkévaló színe elől, hogy oda tegyenek meleg kenyeret, amely napon elvétetett.
Bẹ́ẹ̀ ni àlùfáà náà sì fi àkàrà mímọ́ fún un; nítorí tí kò sí àkàrà mìíràn níbẹ̀ bí kò ṣe àkàrà ìfihàn tí a ti kó kúrò níwájú Olúwa, láti fi àkàrà gbígbóná síbẹ̀ ní ọjọ́ tí a kó o kúrò.
7 De volt ott ama napon egy ember Sául szolgái közül, elzárva az Örökkévaló színe előtt; neve Dóég, az edómi, Sául pásztorainak legfőbbje. –
Ọkùnrin kan nínú àwọn ìránṣẹ́ Saulu sì ń bẹ níbẹ̀ lọ́jọ́ náà, tí a tí dádúró síwájú Olúwa; orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Doegi, ará Edomu olórí nínú àwọn darandaran Saulu.
8 Ekkor mondta Dávid Achímélekhnek: Hát nincs itt kezed alatt dárda vagy kard? Mert sem kardomat, sem fegyvereimet nem vettem kezemhez, mert sürgős volt a király dolga.
Dafidi sì tún wí fún Ahimeleki pé, “Kò sí ọ̀kọ̀ tàbí idà lọ́wọ́ rẹ níhìn-ín? Nítorí tí èmi kò mú idà mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mú nǹkan ìjà mi lọ́wọ́, nítorí pé iṣẹ́ ọba náà jẹ́ iṣẹ́ ìkánjú.”
9 Mondta a pap: Góliátnak, a filiszteusnak kardja, kit megvertél a tölgy völgyében, itt van beburkolva a ruhába az éfód mögött; ha azt vennéd magadhoz, vedd, mert nincs más rajta kívül e helyütt. Erre mondta Dávid: Nincs olyan mint az, adjad nekem!
Àlùfáà náà sì wí pé, “Idà Goliati ará Filistini tí ó pa ní àfonífojì Ela ní ń bẹ, wò ó, a fi aṣọ kan wé e lẹ́yìn efodu; bí ìwọ yóò bá mú èyí, mú un; kò sì sí òmíràn níhìn-ín mọ́ bí kò ṣe ọ̀kan náà.” Dafidi sì wí pé, “Kò sí èyí tí ó dàbí rẹ̀ fún mi.”
10 Fölkelt Dávid és elszökött aznap Sául elől; és eljött Ákhíshoz, Gát királyához.
Dafidi sì dìde, o sì sá ni ọjọ́ náà níwájú Saulu, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi, ọba Gati.
11 Ekkor szóltak Ákhís szolgái hozzá: Nem Dávid-e ez, az ország királya? nemde erről énekelnek körtáncban, mondván: megverte Sául az ő ezreit, Dávid pedig a tízezreit?
Àwọn ìránṣẹ́ Akiṣi sì wí fún un pé, “Èyí ha kọ́ ní Dafidi ọba ilẹ̀ náà? Ǹjẹ́ wọn kò ha ti dárin ti wọ́n sì gbe orin nítorí rẹ̀, tí wọ́n sì jó pé, “‘Saulu pa ẹgbẹ̀rún tirẹ̀. Dafidi sì pa ẹgbàárùn-ún tirẹ̀’?”
12 Szívére vette Dávid e szavakat és nagyon félt Ákhístól, Gát királyától.
Dafidi sì pa ọ̀rọ̀ wọ̀nyí í mọ́ ni ọkàn rẹ̀, ó sì bẹ̀rù Akiṣi ọba Gati gidigidi.
13 Elváltoztatta tehát eszét szemük előtt és eszelősködött kezeik közt; rajzolt a kapu ajtóira és lefolyatta nyálát szakállára.
Òun sì pa ìṣe rẹ̀ dà níwájú wọn, ó sì sọ ara rẹ̀ di aṣiwèrè ní ọwọ́ wọn, ó sì ń fi ọwọ́ rẹ̀ ha ìlẹ̀kùn ojú ọ̀nà, ó sì ń wá itọ́ sí irùngbọ̀n rẹ̀.
14 Ekkor szólt Akhís a szolgáihoz: Íme, látjátok, őrült ember! Minek hozzátok őt hozzám?
Nígbà náà ni Akiṣi wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wó o, nítorí kín ni ẹ̀yin ṣe mú un tọ̀ mí wá.
15 Híjával vagyok-e én az őrülteknek, hogy hoztátok ezt, hogy bolondozzon előttem? Vajon ez jöjjön-e be házamba?
Mo ha ni un fi aṣiwèrè ṣe? Tí ẹ̀yin fi mú èyí tọ̀ mí wá láti hu ìwà aṣiwèrè níwájú mi? Eléyìí yóò ha wọ inú ilé mi?”