< 1 Sámuel 20 >

1 És elszökött Dávid Nájótból, Rámában; elment és szólt Jónátán előtt: Mit cselekedtem, mi a bűnöm és mi a vétkem atyád előtt, hogy életemre tör?
Nígbà náà ni Dafidi sá kúrò ní Naioti ti Rama ó sì lọ sọ́dọ̀ Jonatani ó sì béèrè pé, “Kí ni mo ṣe? Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Báwo ni mo ṣe ṣẹ baba rẹ, tí ó sì ń wá ọ̀nà láti gba ẹ̀mí mi?”
2 Mondta neki: Távol legyen, nem fogsz meghalni! Íme, nem tesz atyám sem nagy dolgot, sem kicsi dolgot, hogy ne nyilvánítaná előttem; miért rejtené tehát atyám el ezt a dolgot tőlem? Nincs úgy!
Jonatani dáhùn pé, “Kí a má rí i! Ìwọ kò ní kú! Wò ó baba mi kì í ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí tí ó kéré, láìfi lọ̀ mí. Èéṣe tí yóò fi fi èyí pamọ́ fún mi? Kò rí bẹ́ẹ̀.”
3 S újra esküdött Dávid és mondta: Jól tudja atyád, hogy kegyet találtam szemeidben, mondta tehát, ne tudja ezt Jónátán, nehogy megszomorodjék; azonban ahogy él az Örökkévaló és lelked életére, bizony, csak egy lépésnyi van köztem és a halál közt.
Ṣùgbọ́n Dafidi tún búra, ó sì wí pé, “Baba rẹ mọ̀ dáradára pé mo rí ojúrere ní ojú rẹ, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, ‘Jonatani kò gbọdọ̀ mọ èyí yóò sì bà á nínú jẹ́.’ Síbẹ̀ nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà láààyè, ìgbésẹ̀ kan ni ó wà láàrín ìyè àti ikú.”
4 Erre szólt Jónátán Dávidhoz: Mit kíván a lelked? Megteszem neked.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe, èmi yóò ṣe é fún ọ.”
5 Szólt Dávid Jónátánhoz: Íme, újhold van holnap, én pedig ülni szoktam a királynál, hogy egyem; bocsáss hát el engem és elrejtőzöm a mezőn a harmadik estig.
Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Wò ó, ọ̀la ni oṣù tuntun, mo sì gbọdọ̀ bá ọba jẹun, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó lọ láti fi ara pamọ́ lórí pápá títí di àṣálẹ́ ọjọ́ kẹta.
6 Ha majd fölemlít engem atyád, akkor mondjad: elkérezkedett tőlem Dávid, hogy futhasson Bét-Léchembe, az ő városába, mert évi áldozatja van ott az egész családnak.
Bí ó bá sì ṣe pé baba rẹ bá fẹ́ mi kù, kí o sì wí fún un pé, ‘Dafidi fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ béèrè ààyè láti sáré lọ sí Bẹtilẹhẹmu ìlú rẹ̀ nítorí wọ́n ń ṣe ẹbọ ọdọọdún ní ibẹ̀ fún gbogbo ìdílé rẹ̀.’
7 Ha így szól: jó – béke van szolgáddal; de ha haragjára lesz, tudd meg, hogy elhatározva van részéről a veszedelem.
Tí o bá wí pé, ‘Àlàáfíà ni,’ nígbà náà, ìránṣẹ́ rẹ wà láìléwu. Ṣùgbọ́n tí ó bá bínú gidigidi, ìwọ yóò mọ̀ dájú pé ó pinnu láti ṣe ìpalára mi.
8 És cselekedjél szeretetet szolgáddal, mert az Örökkévaló szövetségébe engedted jutni magaddal szolgádat; de ha bűn van rajtam, ölj meg te atyádhoz pedig minek is vinnél.
Ṣùgbọ́n ní tìrẹ ìwọ, fi ojúrere wo ìránṣẹ́ rẹ; nítorí tí ìwọ ti bá a dá májẹ̀mú pẹ̀lú rẹ níwájú Olúwa. Tí mo bá jẹ̀bi, pa mí fún ara rẹ! Èéṣe tí ìwọ yóò fi fi mí lé baba rẹ lọ́wọ́?”
9 Mondta Jónátán; Távol legyen tőled! Bizony ha megtudom, hogy atyám részéről el van határozva, a veszedelem, hogy rád jöjjön, nem adnám én azt tudtodra?
Jonatani wí pé, “Kí a má rí i! Ti mo bá ti gbọ́ tí baba mi ti pinnu láti pa ọ́ lára, ṣé èmi kò ní sọ fún ọ?”
10 És szolt Dávid Jónátánhoz: Ki adja majd tudtomra, ha talán atyád valami keményet felel neked?
Nígbà náà ni Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Ta ni yóò sọ fún mi tí baba rẹ̀ bá dá ọ lóhùn ní ohùn líle?”
11 Szólt Jónátán Dávidhoz: Gyere, menjünk ki a mezőre. És kimentek mind a ketten a mezőre.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Wá, jẹ́ kí a jáde lọ sórí pápá.” Nígbà náà wọ́n sì jáde lọ.
12 Ekkor szólt Jónátán Dávidhoz: Az Örökkévaló, Izrael Istene – midőn kifürkészem atyámat ilyenkor holnap vagy harmadnapra és íme, jól áll Dávid dolga, vajon akkor nem küldenék hozzád, hogy nyilvánítsam előtted?
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Mo fi Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli búra pé, èmi yóò rí i dájú pé mo gbọ́ ti ẹnu baba mi ní ìwòyí ọ̀la tàbí ní ọ̀túnla! Bí ó bá sì ní inú dídùn sí ọ, èmi yóò ránṣẹ́ sí ọ, èmi yóò sì jẹ́ kí o mọ̀?
13 Így tegyen az Örökkévaló Jónátánnal s így folytassa, ha jónak tetszik atyámnak rád hozni a veszedelmet, akkor nyilvánítom előtted és elbocsátlak, hogy menj békével; és legyen veled az Örökkévaló, amint atyámmal volt.
Ṣùgbọ́n tí baba mi bá fẹ́ pa ọ́ lára, kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí Jonatani; tí èmi kò bá jẹ́ kí o mọ̀, kí n sì jẹ́ kí o lọ ní àlàáfíà. Kí Olúwa kí ó wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pẹ̀lú baba mi.
14 S nemde, ha még élek, nem fogsz-e cselekedni velem az Örökkévaló szeretetével, hogy meg ne haljak?
Ṣùgbọ́n fi àìkùnà inú rere hàn mí bí inú rere Olúwa, níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè kí wọ́n má ba à pa mí.
15 S ne irtsd ki szeretetedet házamtól sohasem, akkor sem, mikor kiírtja az Örökkévaló Dávid ellenségeit, kit-kit a föld színéről –
Má ṣe ké àánú rẹ kúrò lórí ìdílé mi títí láé. Bí Olúwa tilẹ̀ ké gbogbo ọ̀tá Dafidi kúrò lórí ilẹ̀.”
16 így szövetséget kötött Jónátán Dávid házával és keresse az Örökkévaló Dávid ellenségeinek kezéből!
Nígbà náà ni Jonatani bá ilé Dafidi dá májẹ̀mú wí pé, “Olúwa yóò pe àwọn àti Dafidi láti ṣírò.”
17 Tovább is megeskette Jónátán Dávidot, mert szerette őt, mert lelke szeretetével szerette.
Jonatani mú kí Dafidi tún ìbúra ṣe nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí i, nítorí tí ó fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti fẹ́ràn ara rẹ̀.
18 Erre mondta neki Jónátán: Holnap újhold van; hiányozni fogsz, mert üres lesz az ülőhelyed.
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Lọ́la ní ibi àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun, a yóò fẹ́ ọ kù, nítorí ààyè rẹ yóò ṣófo.
19 Harmadnapon pedig menj le hamar, míg eljutsz azon helyre, ahol elrejtőztél az esemény napján, és maradj az Ézel köve mellett.
Ní ọ̀túnla lọ́wọ́ alẹ́ lọ sí ibi tí o sá pamọ́ sí nígbà tí ìṣòro yìí bẹ̀rẹ̀, kí o sì dúró níbi òkúta Eselu.
20 Én pedig – a három nyilat majd ellövöm, célba lőve magamnak.
Èmi yóò ta ọfà mẹ́ta sí ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀, gẹ́gẹ́ bí i pé mo ta á sí àmì ibìkan.
21 És íme elküldöm majd a legényt: menj, találd meg a nyilakat; ha azt fogom mondani a legénynek: íme a nyilak innen vannak tőled – akkor vedd és jöjj, mert béke van veled és nincs baj – él az Örökkévaló!
Èmi yóò rán ọmọdékùnrin kan èmi yóò wí fún un wí pé, ‘Lọ, kí o lọ wá ọfà náà.’ Tí mo bá sọ fún un wí pé, ‘Wò ó, ọfà wọ̀nyí wà ní ibi báyìí ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ rẹ; kó wọn wá síbí,’ kí o sì wá, nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wà ní ààyè, o wà ní àlàáfíà; kò sí ewu.
22 Ha pedig azt mondom a fiúnak: íme, a nyilak innen vannak tőled, akkor menj, mert elküldött téged az Örökkévaló.
Ṣùgbọ́n tí mo bá sọ fún ọmọdékùnrin náà pé, ‘Wò ó, àwọn ọfà náà ń bẹ níwájú rẹ,’ ǹjẹ́ máa bá tìrẹ lọ, nítorí Olúwa ni ó rán ọ lọ.
23 Azon szóra nézve pedig, melyet szóltunk én meg te – íme az Örökkévaló van köztem és közted örökké.
Nípa ọ̀rọ̀ tí èmi àti ìwọ jọ sọ, rántí Olúwa jẹ́ ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti èmi títí láéláé.”
24 Elrejtőzött tehát Dávid a mezőn. Volt pedig újholdkor, leült a király az ebédhez, hogy egyék.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sá pamọ́ sínú pápá. Nígbà tí àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun sì dé, ọba sì jókòó láti jẹun.
25 És leült a király az ülőhelyére, mint egyszer-másszor a fal melletti ülőhelyre; s fölkelt Jónátán és leült Abnér Sául oldalára; s üres maradt Dávid helye.
Ọba sì jókòó gẹ́gẹ́ bí ipò o rẹ̀ ní ibi tí ó máa ń jókòó lórí ìjókòó tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri, ní òdìkejì Jonatani, Abneri sì jókòó ti Saulu, ṣùgbọ́n ààyè Dafidi sì ṣófo.
26 De nem szólt Sául semmit aznap, mert mondta: véletlen az, nem tiszta ő, bizony nem tiszta.
Saulu kò sọ nǹkan kan ní ọjọ́ náà, nítorí ó rò pé, “Nǹkan kan ti ṣẹlẹ̀ sí Dafidi láti jẹ́ kí ó di aláìmọ́ lóòtítọ́ ó jẹ́ aláìmọ́.”
27 Volt pedig másnap, az újhold második napján, üres maradt Dávid helye; ekkor szólt Sául a fiához, Jonátánhoz: Miért nem jött Jísáj fia sem tegnap sem ma az ebédhez?
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì, ní ọjọ́ kejì oṣù, ààyè Dafidi sì tún ṣófo. Nígbà náà ni Saulu wí fún ọmọ rẹ̀ Jonatani pé, “Kí ni ó dé tí ọmọ Jese kò fi wá sí ibi oúnjẹ, lánàá àti lónìí?”
28 Felelt Jónátán Sáulnak: Elkérezkedett tőlem Dávid Bét-Léchembe.
Jonatani sì dáhùn pé, “Dafidi bẹ̀ mí tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ fún ààyè láti lọ sí Bẹtilẹhẹmu.
29 Mondta ugyanis: bocsáss el, kérlek, mert családi áldozatunk van a városban, és ő parancsolta meg nekem, a testvérem; most hát, ha kegyet találtam szemeidben, hadd siessek el, kérlek, hogy lássam testvéreimet. Azért nem jött a király asztalához.
Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí n lọ, nítorí pé ìdílé wa ń ṣe ìrúbọ ní ìlú, àwọn ẹ̀gbọ́n ọ̀n mi sì ti pàṣẹ fún mi láti wà níbẹ̀; tí èmi bá rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí n lọ láti lọ rí àwọn ẹ̀gbọ́n mi.’ Ìdí nìyìí tí kò fi wá sí orí tábìlì oúnjẹ ọba.”
30 Erre föllobbant Sául haragja Jónátán ellen és mondta neki: Te romlott és fenyíteni való anyának a fia! Hiszen tudom, hogy te kedveled Jísáj fiát, szégyenedre és anyád szemérmének szégyenére!
Ìbínú Saulu sì ru sí Jonatani ó sì wí fún un pé, “Ìwọ ọmọ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀ búburú yìí, ṣé èmi kò ti mọ̀ pé, ìwọ ti yan ọmọ Jese fún ìtìjú ti ara rẹ àti fún ìtìjú màmá rẹ tí ó bí ọ?
31 Mert mind azon időben, amíg Jísáj fia él a földön, nem fogsz megszilárdulni sem te, sem királyságod; most tehát küldj és hozasd őt hozzám, mert halál fia ő!
Níwọ́n ìgbà tí ọmọ Jese bá wà láààyè lórí ilẹ̀ ayé, a kì yóò fi ẹsẹ̀ ìwọ tàbí ti ìjọba rẹ múlẹ̀. Nísinsin yìí ránṣẹ́ kí o sì lọ mú un wá fún mi, nítorí ó gbọdọ̀ kú!”
32 Felelt Jónátán atyjának, Sáulnak és szólt hozzá: Mért ölessék meg, mit követett el?
Jonatani béèrè lọ́wọ́ baba rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwa yóò fi pa á? Kí ni ó ṣe?”
33 Ekkor Sául a dárdáját hajította feléje, hogy leüsse; így megtudta Jónátán, hogy el van határozva atyja részéről, hogy megöli Dávidot.
Ṣùgbọ́n Saulu ju ọ̀kọ̀ rẹ̀ sí Jonatani láti gún un pa. Nígbà náà ni Jonatani mọ̀ pé baba rẹ̀ mọ̀ ọ́n mọ̀ fẹ́ pa Dafidi ni.
34 S fölkelt Jónátán az asztaltól föllobbant haraggal; és nem evett az újhold második napján kenyeret, mert megszomorodott Dávid miatt, mert megszégyenítette az atyja.
Bẹ́ẹ̀ ni Jonatani sì fi ìbínú dìde kúrò ni ibi oúnjẹ, kò sì jẹun ni ọjọ́ kejì oṣù náà, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ gidigidi fún Dafidi, nítorí pé baba rẹ̀ dójútì í.
35 Volt pedig reggel, kiment Jónátán a mezőre Dávidhoz a meghatározott időre, és egy kisfiú vele.
Ó sì ṣe, ní òwúrọ̀ ni Jonatani jáde lọ sí oko ní àkókò tí òun àti Dafidi ti fi àdéhùn sí, ọmọdékùnrin kan sì wá pẹ̀lú rẹ̀.
36 És mondta legényének: Fuss, találd csak meg a nyilakat, melyeket ellövök. A fiú futott, ő pedig ellőtte a nyilat, túlhajítva rajta.
Ó si wí fún ọmọdékùnrin rẹ̀ pé, “Sáré, kí o si wá àwọn ọfà tí èmi ó ta.” Bí ọmọdé náà sì ti ń sáré, òun sì tafà rékọjá rẹ̀.
37 Mikor eljutott a legény a nyíl helyére, melyet ellőtt Jónátán, kiáltott Jónátán a legény után és mondta: Hiszen a nyíl túlnan van tőled!
Nígbà tí ọmọdékùnrin náà sì dé ibi ọfà tí Jonatani ta, Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà ó sì wí pé, “Ọfà náà kò ha wà níwájú rẹ bi?”
38 És kiáltott Jónátán a legény után: Gyorsan siess, meg ne állj! És fölszedte Jónátán legénye a nyilakat és odament urához.
Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà pé, “Sáré! Yára! Má ṣe dúró!” Ọmọdékùnrin Jonatani sì ṣa àwọn ọfà náà, ó sì tọ olúwa rẹ̀ wá.
39 A legény pedig nem tudott semmit; csupán Jónátán meg Dávid tudták a dolgot.
(Ọmọdékùnrin náà kò sì mọ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n Jonatani àti Dafidi ni ó mọ ọ̀ràn náà.)
40 Ekkor odaadta Jónátán a fegyvereit az ő legényének és mondta neki: Menj, vidd a városba.
Jonatani sì fi apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú.”
41 A legény elment, Dávid pedig fölkelt dél felől, levetette magát arcával a földre és leborult háromszor; megcsókolták egyik a másikát és sírtak egyik a másikával, mígnem Dávid nagyon sírt.
Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dafidi sì dìde láti ibi ìhà gúúsù òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jonatani, wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sọkún, èkínní pẹ̀lú èkejì rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi sọkún púpọ̀ jù.
42 És mondta Jónátán Dávidnak: Menj békével! Amit esküdtünk mi ketten az Örökkévaló nevében, mondván: az Örökkévaló legyen köztem és közted, magzatom és magzatod közt mindörökké! Fölkelt és elment; Jónátán pedig bement a városba.
Jonatani sì wí fún Dafidi pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí jùmọ̀ búra ni orúkọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrín èmi àti ìwọ, láàrín irú-ọmọ mi àti láàrín irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jonatani sì lọ sí ìlú.

< 1 Sámuel 20 >