< 1 Királyok 5 >

1 És küldte Chírám, Cór királya az ő szolgáit Salamonhoz, mert meghallotta, hogy őt kenték föl királynak atyja helyébe; mert barátja volt Chírám Dávidnak minden időben.
Nígbà tí Hiramu ọba Tire sì gbọ́ pé, a ti fi òróró yan Solomoni ní ọba ní ipò Dafidi baba rẹ̀, ó sì rán àwọn ikọ̀ rẹ̀ sí Solomoni, nítorí ó ti fẹ́ràn Dafidi ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
2 Erre küldött Salamon Chírámhoz, mondván:
Solomoni sì ránṣẹ́ yìí padà sí Hiramu pé,
3 Te tudod, hogy Dávid atyám nem építhetett házat az Örökkévalónak, Istenének nevére a háború miatt, mellyel őt körülvették, míg nem adta őket az Örökkévaló lábai talpa alá.
“Ìwọ mọ̀ pé Dafidi baba mi kò le kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, nítorí ogun tí ó wà yí i káàkiri, títí Olúwa fi fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
4 De most nyugalmat szerzett nekem az Örökkévaló, Istenem köröskörül; nincs sem háborító, sem rossz esemény.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run mi ti fún mi ní ìsinmi ní ibi gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni kò sì sí ọ̀tá tàbí ìjàǹbá kan tí ó ṣe.
5 S íme, én arra gondolok, hogy házat építsek az Örökkévalónak, Istenemnek nevére, ahogy szólt az Örökkévaló Dávid atyámhoz, mondván: fiad, kit helyedbe teszek trónodra – ő építi majd a házat nevemre.
Nítorí náà mo gbèrò láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi, bí Olúwa ti sọ fún Dafidi baba mi, nígbà tí ó wí pé, ‘Ọmọ rẹ tí èmi yóò gbé ka orí ìtẹ́ rẹ ní ipò rẹ ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
6 Most tehát parancsold meg, hogy vágjanak számomra cédrusokat a Libánonból, szolgáim is a te szolgáiddal lesznek, a szolgáidnak bérét pedig megadom neked, mind a szerint, ahogy mondod; mert te tudod, hogy nincs közöttünk senki, ki úgy tudna fákat vágni, mint a Cídónbeliek.
“Nítorí náà ni kí o pàṣẹ pé kí wọn kí ó gé igi kedari Lebanoni fún mi wá. Àwọn ènìyàn mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú tìrẹ, Èmi yóò sì san owó ọ̀yà tí ìwọ bá ránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn rẹ. Ìwọ mọ̀ pé, a kò ní ẹnìkan nínú wa tí ó mọ bí a ti ń gé igi bí àwọn ará Sidoni.”
7 És volt, midőn hallotta Chírám Salamon szavait, igen megörült; mondta: Áldva legyen az Örökkévaló e napon, hogy adott bölcs fiút Dávidnak e számos nép fölé.
Nígbà tí Hiramu sì gbọ́ iṣẹ́ Solomoni, inú rẹ̀ sì dùn gidigidi, ó sì wí pé, “Ògo ni fún Olúwa lónìí, nítorí tí ó ti fún Dafidi ní ọlọ́gbọ́n ọmọ láti ṣàkóso àwọn ìlú ńlá yìí.”
8 Ekkor küldött Chírám Salamonhoz, mondván: Hallottam, mifelől küldöttél hozzám: én megteszem minden kívánságodat a cédrusfák iránt és ciprusfák iránt.
Hiramu sì ránṣẹ́ sí Solomoni pé, “Èmi ti gbọ́ iṣẹ́ tí ìwọ rán sí mi, èmi yóò sì ṣe gbogbo èyí tí o fẹ́ ní pípèsè igi kedari àti ní ti igi firi.
9 Szolgáim majd leszállítják a Libánonról a tengerre és tutajokként a tengerre teszem addig a helyig, melyet megizensz nekem, hogy ott szétbontsam és te elvigyed; te pedig megteszed az én kívánságomat, megadván házam kenyerét.
Àwọn ènìyàn mi yóò mú igi náà sọ̀kalẹ̀ láti Lebanoni wá sí Òkun, èmi ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí ọ ní fífò lójú omi Òkun Ńlá títí dé ibi tí ìwọ ó na ìka sí fún mi. Níbẹ̀ ni èmi yóò ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ìwọ yóò sì kó wọn lọ. Ìwọ yóò sì gba ìfẹ́ mi nípa pípèsè oúnjẹ fún ilé mi.”
10 Így adott Chírám Salamonnak cédrusfákat és ciprusfákat minden kivánsága szerint.
Báyìí ni Hiramu sì pèsè igi kedari àti igi firi tí Solomoni ń fẹ́ fún un,
11 Salamon pedig adott Chírámnak húszezer kór búzát házának az élelmezésére, meg húsz kór törött olajat; így szokott adni Salamon Chírámnak évről évre.
Solomoni sì fún Hiramu ní ogún ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n ọkà oúnjẹ fún ilé rẹ̀, àti ogún òsùwọ̀n òróró dáradára. Solomoni sì ń tẹ̀síwájú láti ṣe èyí fún Hiramu lọ́dọọdún.
12 Az Örökkévaló pedig adott bölcsséget Salamonnak, amint megígérte neki. És béke volt Chírám és Salamon közt, és ők ketten szövetséget kötöttek.
Olúwa sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún un. Ìrẹ́pọ̀ àlàáfíà sì wà láàrín Hiramu àti Solomoni, àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn.
13 És kiemelt Salamon király robotnépet egész Izraélből; és volt a robotnép harmincezer ember.
Solomoni ọba sì ṣa asìnrú ènìyàn jọ ní gbogbo Israẹli; àwọn tí ń sìnrú náà jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ènìyàn.
14 És küldte őket a Libánonba: tízezret havonkint fölváltva; egy hónapig a Libánonban voltak, két hónapig otthon. Adónírám pedig a robot fölött volt.
Ó sì rán wọn lọ sí Lebanoni, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lóṣooṣù, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n lo oṣù kan ní Lebanoni, wọn a sì gbé ilé ní oṣù méjì. Adoniramu ni ó ṣe olórí àwọn asìnrú náà.
15 És volt Salamonnak hetvenezer teherhordója, meg nyolcvanezer kővágója a hegyben.
Solomoni sì ní ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn tí ń ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin gbẹ́nàgbẹ́nà lórí òkè,
16 Azonkívül Salamonnak a munkára felügyelő tisztjei háromezerháromszázan, akik uralmat vittek a munkát végző nép fölött.
àti àwọn ìjòyè nínú àwọn tí a fi ṣe olórí iṣẹ́ Solomoni jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún ó lé ọgọ́rùn-ún ènìyàn, tí ó ń ṣe aláṣẹ àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ náà.
17 Megparancsolta a király és fejtettek nagy köveket, becses köveket, hogy alapozzák a házat faragott kövekkel.
Ọba sì pàṣẹ, wọ́n sì mú òkúta wá, òkúta iyebíye, àti òkúta gbígbẹ́ láti fi ìpìlẹ̀ ilé náà lé ilẹ̀.
18 És faragták Salamonnak építői és Chíróm építői, meg a Gebálbeliek; és készítették a fákat meg a köveket a ház építésére.
Àwọn oníṣọ̀nà Solomoni àti Hiramu àti àwọn òṣìṣẹ́ láti Gebali sì gbẹ́ wọn, wọ́n sì pèsè igi àti òkúta láti fi kọ́ ilé náà.

< 1 Királyok 5 >