< 1 Krónika 29 >

1 És mondta Dávid király az egész gyülekezetnek: Az én fiam Salamon, az az egy, akit kiválasztott Isten, fiatal és gyönge; a munka pedig nagy, mert nem ember számára lesz a vár, hanem az Örökkévaló az Isten számára.
Nígbà náà, ọba Dafidi sọ fún gbogbo àpéjọ pé, “Ọmọ mi Solomoni, èyí tí Ọlọ́run ti yàn, sì kéré ó sì jẹ́ aláìmòye. Iṣẹ́ náà tóbi, nítorí ìkọ́lé bí ti ààfin kì í ṣe fún ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa Ọlọ́run.
2 Én minden erőmhöz képest előkészítettem Istenem háza számára az aranyat az arany, az ezüstöt az ezüst, a rezet a réz, a vasat a vas s fát a fatárgyak számára, sóhám és befoglaló köveket, fényes és tarka követ s mindenféle drágakövet és márványköveket bőségesen.
Pẹ̀lú gbogbo ìrànlọ́wọ́ mi èmi ti pèsè fún ilé Ọlọ́run mi wúrà fún iṣẹ́ wúrà, fàdákà fún ti fàdákà, idẹ fún ti idẹ, irin fún ti irin àti igi fún ti igi àti òkúta oníyebíye fún títọ́ rẹ̀, òkúta lóríṣìíríṣìí, àwọ̀ àti oríṣìíríṣìí ẹ̀yà òkúta àti òkúta dáradára kan gbogbo wọ̀nyí ní iye púpọ̀.
3 És továbbá, mivel kedvelem Istenem házát, amim van, tulajdonomat aranyat és ezüstöt adtam Istenem háza számára, mindazon felül, amit előkészítettem a szent ház számára:
Yàtọ̀ fún èyí, nínú ìfọkànsìn mi sí ilé Ọlọ́run mi, èmí fi ìṣúra mi tìkára mi ti wúrà àti fàdákà fún ilé Ọlọ́run mi. Jù gbogbo rẹ̀ lọ, èmi ti pèsè fún ilé mímọ́ ti Olúwa yìí,
4 háromezer kikkár aranyat, Ófir-aranyból, meg hétezer kikkár tisztított ezüstöt a házak falainak bevonására,
ẹgbẹ̀rún mẹ́ta tálẹ́ǹtì wúrà, ti wúrà Ofiri àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin tálẹ́ǹtì fàdákà dídára, fún bíbo àwọn ògiri ilé náà.
5 aranyat az arany- és ezüstöt az ezüst tárgyak számára s minden munkára a művészek által. És ki akar adakozni, megtöltve kezét, ma az Örökkévalónak?
Fún iṣẹ́ wúrà àti fàdákà náà, àti fún oríṣìí iṣẹ́ ti ó yẹ ní ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn tí ó ní òye oríṣìíríṣìí iṣẹ́. Nísinsin yìí, ta ni ó ní ìfẹ́ sí yíya ará rẹ̀ sọ́tọ̀ lónìí sí Olúwa?”
6 Ekkor adakoztak az atyai házak nagyjai és Izrael törzseinek nagyjai, az ezrek és százak nagyjai és a király munkájának nagyjai.
Nígbà náà àwọn aṣáájú àwọn ìdílé, àwọn ìjòyè àwọn ẹ̀yà Israẹli, àwọn alákòóso ẹgbẹgbẹ̀wàá àti alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn oníṣẹ́ tí ó wà ní ìdí iṣẹ́ ọba ní ìfẹ́ sí i.
7 És adtak az Isten házának szolgálatára aranyat ötezer kikkárt és tízezer adarkónt, ezüstöt tízezer kikkárt, rezet tizennyolcezer kikkárt és vasat százezer kikkárt.
Wọ́n fi sílẹ̀ fún iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run, ẹgbẹ̀rún márùn-ún tálẹ́ǹtì àti ẹgbẹ̀rin mẹ́wàá wúrà, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì fàdákà, ẹgbàá mẹ́sàn tálẹ́ǹtì idẹ àti ọgọ́rin ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì irin.
8 És akiknél találtattak kövek, odaadták az Örökkévaló háza kincstárának, a gérsóni Jechiél kezéhez.
Ẹnikẹ́ni tí ó ní òkúta iyebíye fi wọn sí ilé ìṣúra ilé Olúwa ní abẹ́ ìtọ́jú Jehieli ará Gerṣoni.
9 És örült a nép adakozásuk miatt, mert teljes szívvel adakoztak az Örökkévalónak, és Dávid király is örült nagy örömmel.
Àwọn ènìyàn láyọ̀ nínú ìṣesí àtọkànwá fi sílẹ̀ àwọn olórí wọn, nítorí tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ọ̀fẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn sí Olúwa. Dafidi ọba pẹ̀lú yọ̀ gidigidi.
10 Ekkor áldotta Dávid az Örökkévalót az egész gyülekezet szeme előtt, és mondta Dávid: Áldva legyél Örökkévaló, oh Izrael atyánk Istene, öröktől örökké.
Dafidi yin Olúwa níwájú gbogbo àwọn tí ó péjọ, wí pé, “Ìyìn ni fún Ọ, Olúwa, Ọlọ́run baba a wa Israẹli, láé àti láéláé.
11 Tied, oh Örökkévaló, a nagyság és a hatalom és az ékesség és a győzelem és a fenség, bizony minden az égen s a földön; tiéd oh Örökkévaló, a királyság, aki fölülemelkedik mindenek fölé fejül.
Tìrẹ Olúwa ni títóbi àti agbára pẹ̀lú ìyìn àti ọláńlá àti dídán, nítorí tí gbogbo nǹkan ní ọ̀run àti ayé jẹ́ tìrẹ. Tìrẹ Olúwa ni ìjọba; a gbé ọ ga gẹ́gẹ́ bí orí lórí ohun gbogbo.
12 És a gazdagság s a dicsőség tőled vannak a te uralkodsz mindeneken s a te kezedben van erő és hatalom, és kezedben van, naggyá és erőssé tenni mindent.
Ọlá àti ọ̀wọ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Rẹ; ìwọ ni alákòóso gbogbo nǹkan. Ní ọwọ́ rẹ ni ipá àti agbára wà láti gbéga àti láti fi agbára fún ohun gbogbo.
13 És most, oh Istenünk, hálát adunk neked és dicséretet mondunk a te dicsőséges nevednek.
Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, àwa fi ọpẹ́ fún Ọ, a sì fi ìyìn fún orúkọ rẹ̀ tí ó lógo.
14 Hiszen ki vagyok én s ki az én népem, hogy erővel bírnánk, ilyképpen adakozni, mert tőled van minden és kezedből adtunk te neked.
“Ṣùgbọ́n ta ni èmi, àti ta ni àwọn ènìyàn mi, tí a fi lè ṣe ìrànlọ́wọ́ tinútinú bí irú èyí? Gbogbo nǹkan wá láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ti wá, àwa sì ti fífún ọ láti ara ohun tí ó wá láti ọwọ́ rẹ.
15 Mert jövevények vagyunk előtted és zsellérek, mint őseink mind, mint az árnyék napjaink a földön és nincs reménység.
Àwa jẹ́ àjèjì àti àlejò ní ojú rẹ gẹ́gẹ́ bí baba ńlá a wa, àwọn ọjọ́ wa lórí ilẹ̀ ayé rí bí òjìji láìsí ìrètí.
16 Oh Örökkévaló, Istenünk, ez az egész gazdagság, amelyet előkészítettünk, hogy neked házat építsünk a te szent nevednek, a te kezedből való s tied minden.
Olúwa Ọlọ́run wa tí fi gbogbo púpọ̀ yìí tí àwa ti pèsè fún kíkọ́ ilé Olúwa fun orúkọ, mímọ́ rẹ̀, ó wá láti ọwọ́ ọ̀ rẹ, gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ tirẹ̀.
17 És tudom én, oh Istenem, hogy te vizsgálod a szívet s az egyenességet kedveled; én a szívem egyenességében adakoztam mindezeket és most a népedet, azokat, kik itt találtatnak, láttam örömmel adakozni neked.
Èmi mọ̀ Ọlọ́run mi, wí pé ìwọ̀ dán ọkàn wò, ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn pẹ̀lú òtítọ́ inú. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti fi sílẹ̀ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́ pẹ̀lú òtítọ́. Nísinsin yìí èmi ti rí i pẹ̀lú ayọ̀ bí àwọn ènìyàn yìí tí ó wà níbí ti fi fún ọ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́.
18 Oh Örökkévaló, Ábrahám, Izsák és Izrael őseink Istene, őrizd ezt meg örökre, mint néped szíve gondolatainak hajlamát és szilárdítsd szívüket magadhoz.
Olúwa Ọlọ́run àwọn baba a wa Abrahamu, Isaaki àti Israẹli pa ìfẹ́ yìí mọ́ nínú ọkàn àwọn ènìyàn rẹ títí láé pẹ̀lú pípa ọkàn mọ́ lóòtítọ́ sí ọ.
19 Fiamnak Salamonnak pedig adj teljes szívet, hogy megőrizze parancsolataidat, bizonyságaidat és törvényeidet, és hogy mindent megtegyen és hogy fölépítse a várat, melyet előkészítettem.
Àti fún ọmọ mi Solomoni ní ìfọkànsìn tòótọ́ láti pa àṣẹ rẹ mọ́ àwọn ohun tí ó nílò àti òfin àti láti ṣe ohun gbogbo láti kọ́ ààfin bí ti ọba fún èyí tí mo ti pèsè.”
20 Erre mondta Dávid az egész gyülekezetnek: Áldjátok csak az Örökkévalót, a ti Istenteket! És áldotta az egész gyülekezet az Örökkévalót, az ő Istenüket s meghajoltak s leborultak az Örökkévaló előtt és a király előtt.
Dafidi sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn pé, “Nísinsin yìí, ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín.” Gbogbo ènìyàn sì fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì tẹ orí wọn ba, wọ́n wólẹ̀ fún Olúwa àti ọba.
21 És vágtak az Örökkévalónak vágóáldozatokat és hoztak égőáldozatokat az Örökkévalónak annak a napnak másnapján: ezer tulkot, ezer kost, ezer juhot és öntőáldozataikat, és vágóáldozatokat bőségesen egész Izrael számára.
Ni ọjọ́ kejì, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì rú ẹbọ sísun sí i: ẹgbẹ̀rún kan akọ màlúù, ẹgbẹ̀rin kan àgbò, àti ẹgbẹ̀rin kan akọ ọ̀dọ́-àgùntàn. Lápapọ̀ pẹ̀lú ọrẹ mímu àti àwọn ẹbọ mìíràn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún gbogbo Israẹli.
22 Ettek és ittak az Örökkévaló előtt ama napon nagy örömben, és királlyá tették másodszor Salamont, Dávid fiát és fölkenték az Örökkévalónak fejedelmül, Cádókot pedig papul.
Wọ́n jẹ wọ́n sì mu pẹ̀lú ayọ̀ kíkún ní iwájú Olúwa ní ọjọ́ náà. Nígbà náà wọ́n yan Solomoni ọmọ Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba lẹ́ẹ̀kejì wọ́n fi àmì òróró yàn án níwájú Olúwa láti ṣe olórí àti Sadoku láti ṣe àlùfáà.
23 És ült Salamon az Örökkévaló trónján királyul atyja Dávid helyett és szerencsés volt; és rá hallgatott egész Izrael.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọba ní ipò baba a rẹ̀ Dafidi. O ṣe àṣeyọrí, gbogbo Israẹli sì gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
24 És mind a nagyok és a vitézek és Dávid királynak mind a fiai is kezet adtak Salamon király alá.
Gbogbo àwọn ìjòyè àti àwọn ọkùnrin alágbára, pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọba Dafidi tẹrí ara wọn ba fún ọba Solomoni.
25 És naggyá tette az Örökkévaló Salamont, felette naggyá egész Izrael szemei előtt; és ráadta a királyság fenségét, amely nem volt egy királyon sem előtte Izrael fölött.
Olúwa gbé Solomoni ga púpọ̀ ní ojú gbogbo Israẹli, ó sì kẹ́ ẹ ní ìkẹ́ ọláńlá, ní irú èyí tí a kò kẹ́ ọba kankan ṣáájú rẹ̀ tí ó jẹ lórí Israẹli.
26 És Dávid, Jisáj fia uralkodott egész Izrael felett.
Dafidi ọmọ Jese jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli.
27 A napok pedig, melyeken át uralkodott Izrael felett: negyven év; Chebrónban uralkodott hét évig és Jeruzsálemben uralkodott harmincháromig.
Ó jẹ ọba lórí Israẹli fún ogójì ọdún; ọdún méje ni ó jẹ ọba ní Hebroni, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu.
28 És meghalt jó vénségben, megtelten napokkal, gazdagsággal és dicsőséggel és király lett fia Salamon helyette.
Òun sì darúgbó, ó sì kú ikú rere, ó gbádùn ẹ̀mí gígùn, ọlá àti ọrọ̀. Solomoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
29 És Dávid király dolgai, az előbbiek és az utóbbiak meg vannak írva Sámuelnek, a látónak szavaiban meg Nátánnak, a prófétának szavaiban és Gádnak, a jósnak szavaiban:
Ní ti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba ọba Dafidi, láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin, a kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Samuẹli aríran, ìwé ìrántí ti Natani wòlíì àti ìwé ìrántí ti Gadi aríran,
30 egész uralkodásával és hatalmával együtt, meg az időkkel, melyek elhaladtak felette és Izrael felett és mind az országok királyságai felett.
lápapọ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti agbára rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìgbà tí ó kọjá lórí rẹ̀, àti lórí Israẹli, àti lórí gbogbo àwọn ìjọba gbogbo ilẹ̀ náà.

< 1 Krónika 29 >