< 1 Krónika 20 >
1 És volt az évnek fordultakor, mikor hadba vonulnak a királyok, vezette Jóáb a hadsereget és elpusztította Ammón fiainak országát, elment s ostrom alá vette Rabbát, Dávid pedig Jeruzsálemben maradt. És megverte Jóáb Rabbát és lerombolta azt.
Ní àkókò àkọ́rọ̀ òjò, ni ìgbà tí àwọn ọba lọ sí ogun, Joabu ṣamọ̀nà àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun. Ó fi ilẹ̀ àwọn ará Ammoni ṣòfò. Ó lọ sí ọ̀dọ̀ Rabba. Ó sì fi ogun dúró tì í. Ṣùgbọ́n Dafidi dúró sí Jerusalẹmu Joabu kọlu Rabba, ó sì fi sílẹ̀ ní ìparun.
2 És Dávid levette királyuk koronáját a fejéről és találta azt egy kikkar aranysúlyúnak, és rajta drágakő volt és Dávid fejére került; a városnak igen sok zsákmányát pedig elvitte.
Dafidi mú adé kúrò lórí àwọn ọba wọn ìwọ̀n rẹ̀ dàbí i tálẹ́ǹtì wúrà, a sì tò ó jọ pẹ̀lú àwọn òkúta iyebíye. A sì gbé e ka orí Dafidi. Ó kó ọ̀pọ̀ ìkógun láti ìlú ńlá náà.
3 És a népet, mely benne volt, kivezette s átfűrészelte fűrésszel meg vasboronával és fejszékkel; és így tett Dávid mind az Ammón fiainak városaival. Erre visszatért Dávid meg az egész nép Jeruzsálembe.
Ó sì kó gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ jáde, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ayùn àti ìtulẹ̀ onírin àti àáké. Dafidi ṣe eléyìí sí gbogbo àwọn ará ìlú Ammoni. Nígbà náà, Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ padà sí Jerusalẹmu.
4 Történt ennekután, háború támadt Gézerben a filiszteusokkal, akkor megverte Szibbekháj a Chúsabeli Szippájt, a Ráfa szülöttjei közül valót; s megaláztattak.
Ní ẹ̀yìn èyí ni ogun bẹ́ sílẹ̀ ní Geseri pẹ̀lú àwọn ará Filistini, ní àkókò yìí ni Sibekai ará Huṣati pa Sipai, ọ̀kan lára àwọn ọmọ Refaimu, àti àwọn ará Filistini ni a ṣẹ́gun.
5 És újra volt háború a filiszteusokkal és megverte Élchánán, Jáir fia, Lachmit, a Gátbeli Golját testvérét, az ő dárdájának nyele pedig olyan volt, mint a takácsok zugolyfája.
Nínú ogun mìíràn pẹ̀lú àwọn ará Filistini, Elhanani ọmọ Jairi pa Lahmi arákùnrin Goliati ará Gitti, ẹni ti ó ní ọ̀kọ̀ kan tí ó dàbí ọ̀pá ahunṣọ.
6 És újra volt háború Gátban; és volt egy termetes férfi, ujjai hat meg hat: huszonnégy, ő is Ráfától született;
Síbẹ̀síbẹ̀ nínú ogun mìíràn, tí ó wáyé ní Gati, ọkùnrin títóbi kan wà tí ó ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ìka mẹ́fà ní ẹsẹ̀ rẹ̀ mẹ́rìnlélógún lápapọ̀. Òun pẹ̀lú wá láti Rafa.
7 gyalázta Izraelt, de megverte őt Jehónátán, Simeának, Dávid testvérének fia.
Nígbà tí ó fi Israẹli ṣẹ̀sín, Jonatani ọmọ Ṣimea, arákùnrin Dafidi sì pa á.
8 Ezek születtek Ráfától Gátban; és elestek Dávid keze által és szolgáinak keze által.
Wọ̀nyí ni ìran ọmọ Rafa ní Gati, wọ́n sì ṣubú sí ọwọ́ Dafidi àti àwọn ọkùnrin rẹ̀.