< תהילים 73 >
מזמור לאסף אך טוב לישראל אלהים לברי לבב׃ | 1 |
Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
ואני כמעט נטוי רגלי כאין שפכה אשרי׃ | 2 |
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
כי קנאתי בהוללים שלום רשעים אראה׃ | 3 |
Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
כי אין חרצבות למותם ובריא אולם׃ | 4 |
Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
בעמל אנוש אינמו ועם אדם לא ינגעו׃ | 5 |
Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
לכן ענקתמו גאוה יעטף שית חמס למו׃ | 6 |
Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
יצא מחלב עינמו עברו משכיות לבב׃ | 7 |
Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
ימיקו וידברו ברע עשק ממרום ידברו׃ | 8 |
Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
שתו בשמים פיהם ולשונם תהלך בארץ׃ | 9 |
Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
לכן ישיב עמו הלם ומי מלא ימצו למו׃ | 10 |
Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
ואמרו איכה ידע אל ויש דעה בעליון׃ | 11 |
Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
הנה אלה רשעים ושלוי עולם השגו חיל׃ | 12 |
Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
אך ריק זכיתי לבבי וארחץ בנקיון כפי׃ | 13 |
Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
ואהי נגוע כל היום ותוכחתי לבקרים׃ | 14 |
Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
אם אמרתי אספרה כמו הנה דור בניך בגדתי׃ | 15 |
Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
ואחשבה לדעת זאת עמל היא בעיני׃ | 16 |
Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
עד אבוא אל מקדשי אל אבינה לאחריתם׃ | 17 |
títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
אך בחלקות תשית למו הפלתם למשואות׃ | 18 |
Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
איך היו לשמה כרגע ספו תמו מן בלהות׃ | 19 |
Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
כחלום מהקיץ אדני בעיר צלמם תבזה׃ | 20 |
Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
כי יתחמץ לבבי וכליותי אשתונן׃ | 21 |
Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
ואני בער ולא אדע בהמות הייתי עמך׃ | 22 |
mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
ואני תמיד עמך אחזת ביד ימיני׃ | 23 |
Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
בעצתך תנחני ואחר כבוד תקחני׃ | 24 |
Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
מי לי בשמים ועמך לא חפצתי בארץ׃ | 25 |
Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
כלה שארי ולבבי צור לבבי וחלקי אלהים לעולם׃ | 26 |
Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
כי הנה רחקיך יאבדו הצמתה כל זונה ממך׃ | 27 |
Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
ואני קרבת אלהים לי טוב שתי באדני יהוה מחסי לספר כל מלאכותיך׃ | 28 |
Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.