< תהילים 139 >
למנצח לדוד מזמור יהוה חקרתני ותדע׃ | 1 |
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Olúwa, ìwọ tí wádìí mi, ìwọ sì ti mọ̀ mí.
אתה ידעת שבתי וקומי בנתה לרעי מרחוק׃ | 2 |
Ìwọ mọ̀ ìjókòó mi àti ìdìde mi, ìwọ mọ̀ èrò mi ní ọ̀nà jíjìn réré.
ארחי ורבעי זרית וכל דרכי הסכנתה׃ | 3 |
Ìwọ yí ipa ọ̀nà mi ká àti ìdùbúlẹ̀ mi, gbogbo ọ̀nà mi sì di mí mọ̀ fún ọ.
כי אין מלה בלשוני הן יהוה ידעת כלה׃ | 4 |
Nítorí tí kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ahọ́n mi, kíyèsi i, Olúwa, ìwọ mọ̀ ọ́n pátápátá.
אחור וקדם צרתני ותשת עלי כפכה׃ | 5 |
Ìwọ sé mi mọ́ lẹ́yìn àti níwájú, ìwọ sì fi ọwọ́ rẹ lé mi.
פלאיה דעת ממני נשגבה לא אוכל לה׃ | 6 |
Irú ìmọ̀ yìí jẹ ohun ìyanu fún mi jù; ó ga, èmi kò le mọ̀ ọ́n.
אנה אלך מרוחך ואנה מפניך אברח׃ | 7 |
Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ni ọwọ́ ẹ̀mí rẹ? Tàbí níbo ni èmi yóò sáré kúrò níwájú rẹ?
אם אסק שמים שם אתה ואציעה שאול הנך׃ (Sheol ) | 8 |
Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀; bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú, kíyèsi i, ìwọ wà níbẹ̀ pẹ̀lú. (Sheol )
אשא כנפי שחר אשכנה באחרית ים׃ | 9 |
Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀, kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin Òkun,
גם שם ידך תנחני ותאחזני ימינך׃ | 10 |
àní, níbẹ̀ náà ni ọwọ́ rẹ̀ yóò fà mí ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì dì mímú.
ואמר אך חשך ישופני ולילה אור בעדני׃ | 11 |
Bí mo bá wí pé, “Ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀; kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.”
גם חשך לא יחשיך ממך ולילה כיום יאיר כחשיכה כאורה׃ | 12 |
Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọ́dọ̀ rẹ; ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán; àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjì bákan náà ní fún ọ.
כי אתה קנית כליתי תסכני בבטן אמי׃ | 13 |
Nítorí ìwọ ni ó dá ọkàn mi; ìwọ ni ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.
אודך על כי נוראות נפליתי נפלאים מעשיך ונפשי ידעת מאד׃ | 14 |
Èmi yóò yìn ọ, nítorí tẹ̀rù tẹ̀rù àti tìyanu tìyanu ní a dá mi; ìyanu ní iṣẹ́ rẹ; èyí nì ni ọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú.
לא נכחד עצמי ממך אשר עשיתי בסתר רקמתי בתחתיות ארץ׃ | 15 |
Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ, nígbà tí a dá mi ní ìkọ̀kọ̀. Tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà ní ìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
גלמי ראו עיניך ועל ספרך כלם יכתבו ימים יצרו ולא אחד בהם׃ | 16 |
ojú rẹ ti rí ohun ara mi nígbà tí a kò tí ì ṣe mí pé, àti nínú ìwé rẹ ni a ti kọ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sí, ní ọjọ́ tí a dá wọn, nígbà tí wọn kò tilẹ̀ tí ì sí.
ולי מה יקרו רעיך אל מה עצמו ראשיהם׃ | 17 |
Ọlọ́run, èrò inú rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi, iye wọn ti pọ̀ tó!
אספרם מחול ירבון הקיצתי ועודי עמך׃ | 18 |
Èmi ìbá kà wọ́n, wọ́n ju iyanrìn lọ ní iye: nígbà tí mo bá jí, èmi yóò wà lọ́dọ̀ rẹ síbẹ̀.
אם תקטל אלוה רשע ואנשי דמים סורו מני׃ | 19 |
Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa àwọn ènìyàn búburú nítòótọ́; nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹlẹ́jẹ̀.
אשר יאמרך למזמה נשא לשוא עריך׃ | 20 |
Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ, àwọn ọ̀tá rẹ ń pe orúkọ rẹ ní asán!
הלוא משנאיך יהוה אשנא ובתקוממיך אתקוטט׃ | 21 |
Olúwa, ǹjẹ́ èmi kò kórìíra àwọn tó kórìíra rẹ? Ǹjẹ́ inú mi kò a sì bàjẹ́ sí àwọn tí ó dìde sí ọ?
תכלית שנאה שנאתים לאויבים היו לי׃ | 22 |
Èmi kórìíra wọn ní àkótán; èmi kà wọ́n sí ọ̀tá mi.
חקרני אל ודע לבבי בחנני ודע שרעפי׃ | 23 |
Ọlọ́run, wádìí mi, kí o sì mọ ọkàn mí; dán mi wò, kí o sì mọ ìrò inú mi.
וראה אם דרך עצב בי ונחני בדרך עולם׃ | 24 |
Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburú kan bá wà nínú mi kí ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé ọ̀nà àìnípẹ̀kun.