< תהילים 118 >
הודו ליהוה כי טוב כי לעולם חסדו׃ | 1 |
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
יאמר נא ישראל כי לעולם חסדו׃ | 2 |
Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
יאמרו נא בית אהרן כי לעולם חסדו׃ | 3 |
Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
יאמרו נא יראי יהוה כי לעולם חסדו׃ | 4 |
Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
מן המצר קראתי יה ענני במרחב יה׃ | 5 |
Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
יהוה לי לא אירא מה יעשה לי אדם׃ | 6 |
Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
יהוה לי בעזרי ואני אראה בשנאי׃ | 7 |
Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
טוב לחסות ביהוה מבטח באדם׃ | 8 |
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
טוב לחסות ביהוה מבטח בנדיבים׃ | 9 |
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
כל גוים סבבוני בשם יהוה כי אמילם׃ | 10 |
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
סבוני גם סבבוני בשם יהוה כי אמילם׃ | 11 |
Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
סבוני כדבורים דעכו כאש קוצים בשם יהוה כי אמילם׃ | 12 |
Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
דחה דחיתני לנפל ויהוה עזרני׃ | 13 |
Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
עזי וזמרת יה ויהי לי לישועה׃ | 14 |
Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
קול רנה וישועה באהלי צדיקים ימין יהוה עשה חיל׃ | 15 |
Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
ימין יהוה רוממה ימין יהוה עשה חיל׃ | 16 |
Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
לא אמות כי אחיה ואספר מעשי יה׃ | 17 |
Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
יסר יסרני יה ולמות לא נתנני׃ | 18 |
Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
פתחו לי שערי צדק אבא בם אודה יה׃ | 19 |
Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
זה השער ליהוה צדיקים יבאו בו׃ | 20 |
Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
אודך כי עניתני ותהי לי לישועה׃ | 21 |
Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
אבן מאסו הבונים היתה לראש פנה׃ | 22 |
Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
מאת יהוה היתה זאת היא נפלאת בעינינו׃ | 23 |
Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
זה היום עשה יהוה נגילה ונשמחה בו׃ | 24 |
Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
אנא יהוה הושיעה נא אנא יהוה הצליחה נא׃ | 25 |
Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
ברוך הבא בשם יהוה ברכנוכם מבית יהוה׃ | 26 |
Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
אל יהוה ויאר לנו אסרו חג בעבתים עד קרנות המזבח׃ | 27 |
Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
אלי אתה ואודך אלהי ארוממך׃ | 28 |
Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
הודו ליהוה כי טוב כי לעולם חסדו׃ | 29 |
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.