< תהילים 104 >
ברכי נפשי את יהוה יהוה אלהי גדלת מאד הוד והדר לבשת׃ | 1 |
Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi. Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ tóbi jọjọ; ọlá àti ọláńlá ni ìwọ wọ̀ ní aṣọ.
עטה אור כשלמה נוטה שמים כיריעה׃ | 2 |
Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ; ó tẹ ọ̀run bí títẹ́ ẹní,
המקרה במים עליותיו השם עבים רכובו המהלך על כנפי רוח׃ | 3 |
ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ. Ìwọ tí o ṣe àwọsánmọ̀ ní kẹ̀kẹ́ ogun rẹ ìwọ tí ó ń rìn lórí apá ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
עשה מלאכיו רוחות משרתיו אש להט׃ | 4 |
Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ọ̀wọ́-iná ni àwọn olùránṣẹ́ rẹ.
יסד ארץ על מכוניה בל תמוט עולם ועד׃ | 5 |
O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀; tí a kò le è mì láéláé.
תהום כלבוש כסיתו על הרים יעמדו מים׃ | 6 |
Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ; àwọn omi sì dúró lórí àwọn òkè ńlá.
מן גערתך ינוסון מן קול רעמך יחפזון׃ | 7 |
Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ, nípa ohùn àrá rẹ ni wọ́n sálọ.
יעלו הרים ירדו בקעות אל מקום זה יסדת להם׃ | 8 |
wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀, sí ibi tí ìwọ ti yàn fún wọn.
גבול שמת בל יעברון בל ישובון לכסות הארץ׃ | 9 |
Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀; láéláé ni wọ́n kò ní lè bo ayé mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
המשלח מעינים בנחלים בין הרים יהלכון׃ | 10 |
Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn àfonífojì; tí ó ń sàn láàrín àwọn òkè.
ישקו כל חיתו שדי ישברו פראים צמאם׃ | 11 |
Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ń pa òǹgbẹ wọn.
עליהם עוף השמים ישכון מבין עפאים יתנו קול׃ | 12 |
Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi wọ́n ń kọrin láàrín àwọn ẹ̀ka.
משקה הרים מעליותיו מפרי מעשיך תשבע הארץ׃ | 13 |
Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá; a tẹ́ ayé lọ́rùn nípa èso iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
מצמיח חציר לבהמה ועשב לעבדת האדם להוציא לחם מן הארץ׃ | 14 |
Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ àti àwọn ewébẹ̀ fún ènìyàn láti lò, kí ó lè mú oúnjẹ jáde láti ilẹ̀ wá.
ויין ישמח לבב אנוש להצהיל פנים משמן ולחם לבב אנוש יסעד׃ | 15 |
Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀, òróró láti mú ojú rẹ̀ tan, àti àkàrà láti ra ọkàn rẹ̀ padà.
ישבעו עצי יהוה ארזי לבנון אשר נטע׃ | 16 |
Àwọn igi Olúwa ni a bu omi rin dáradára, kedari ti Lebanoni tí ó gbìn.
אשר שם צפרים יקננו חסידה ברושים ביתה׃ | 17 |
Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn bí ó ṣe tí àkọ̀ ni, orí igi gíga ni ilé rẹ̀.
הרים הגבהים ליעלים סלעים מחסה לשפנים׃ | 18 |
Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó; àti àwọn àlàpà jẹ́ ààbò fún àwọn ehoro.
עשה ירח למועדים שמש ידע מבואו׃ | 19 |
Òṣùpá jẹ́ àmì fún àkókò oòrùn sì mọ ìgbà tí yóò wọ̀.
תשת חשך ויהי לילה בו תרמש כל חיתו יער׃ | 20 |
Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru, nínú èyí tí gbogbo ẹranko igbó ń rìn kiri.
הכפירים שאגים לטרף ולבקש מאל אכלם׃ | 21 |
Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn wọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
תזרח השמש יאספון ואל מעונתם ירבצון׃ | 22 |
Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọn padà lọ dùbúlẹ̀ sí ihò wọn.
יצא אדם לפעלו ולעבדתו עדי ערב׃ | 23 |
Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn, àti sí làálàá rẹ̀ títí di àṣálẹ́.
מה רבו מעשיך יהוה כלם בחכמה עשית מלאה הארץ קנינך׃ | 24 |
Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa! Nínú ọgbọ́n ni ìwọ ṣe gbogbo wọn: ayé kún fún àwọn ìṣẹ̀dá á rẹ.
זה הים גדול ורחב ידים שם רמש ואין מספר חיות קטנות עם גדלות׃ | 25 |
Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú, tí ó kún fún àwọn ẹ̀dá alààyè ní ìsàlẹ̀ láìníye ohun alààyè tí tóbi àti kékeré.
שם אניות יהלכון לויתן זה יצרת לשחק בו׃ | 26 |
Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn, àti Lefitani, tí ìwọ dá láti ṣe àríyá nínú rẹ̀.
כלם אליך ישברון לתת אכלם בעתו׃ | 27 |
Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́ láti fún wọn ní oúnjẹ wọn lákòókò rẹ̀.
תתן להם ילקטון תפתח ידך ישבעון טוב׃ | 28 |
Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn, wọn yóò kó jọ; nígbà tí ìwọ bá la ọwọ́ rẹ̀, a tẹ́ wọn lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere.
תסתיר פניך יבהלון תסף רוחם יגועון ואל עפרם ישובון׃ | 29 |
Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́ ara kò rọ̀ wọ́n nígbà tí ìwọ bá mú ẹ̀mí wọn lọ, wọn ó kú, wọn ó sì padà sí erùpẹ̀.
תשלח רוחך יבראון ותחדש פני אדמה׃ | 30 |
Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ, ni a dá wọn, ìwọ sì tún ojú ayé ṣe.
יהי כבוד יהוה לעולם ישמח יהוה במעשיו׃ | 31 |
Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé; kí inú Olúwa kí ó dùn ní ti iṣẹ́ rẹ̀,
המביט לארץ ותרעד יגע בהרים ויעשנו׃ | 32 |
ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì, ẹni tí ó fọwọ́ tọ́ àwọn òkè, tí wọ́n yọ èéfín.
אשירה ליהוה בחיי אזמרה לאלהי בעודי׃ | 33 |
Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí Olúwa: èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè.
יערב עליו שיחי אנכי אשמח ביהוה׃ | 34 |
Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn bí mo ti ń yọ̀ nínú Olúwa.
יתמו חטאים מן הארץ ורשעים עוד אינם ברכי נפשי את יהוה הללו יה׃ | 35 |
Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé kí ènìyàn búburú má sì sí mọ́. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi. Yin Olúwa.