< מִשְׁלֵי 2 >
בני אם תקח אמרי ומצותי תצפן אתך׃ | 1 |
Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
להקשיב לחכמה אזנך תטה לבך לתבונה׃ | 2 |
tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
כי אם לבינה תקרא לתבונה תתן קולך׃ | 3 |
àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
אם תבקשנה ככסף וכמטמונים תחפשנה׃ | 4 |
bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
אז תבין יראת יהוה ודעת אלהים תמצא׃ | 5 |
Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
כי יהוה יתן חכמה מפיו דעת ותבונה׃ | 6 |
Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
וצפן לישרים תושיה מגן להלכי תם׃ | 7 |
Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
לנצר ארחות משפט ודרך חסידו ישמר׃ | 8 |
Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
אז תבין צדק ומשפט ומישרים כל מעגל טוב׃ | 9 |
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
כי תבוא חכמה בלבך ודעת לנפשך ינעם׃ | 10 |
Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
מזמה תשמר עליך תבונה תנצרכה׃ | 11 |
Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
להצילך מדרך רע מאיש מדבר תהפכות׃ | 12 |
Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
העזבים ארחות ישר ללכת בדרכי חשך׃ | 13 |
ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
השמחים לעשות רע יגילו בתהפכות רע׃ | 14 |
ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
אשר ארחתיהם עקשים ונלוזים במעגלותם׃ | 15 |
ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
להצילך מאשה זרה מנכריה אמריה החליקה׃ | 16 |
Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
העזבת אלוף נעוריה ואת ברית אלהיה שכחה׃ | 17 |
ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
כי שחה אל מות ביתה ואל רפאים מעגלתיה׃ | 18 |
Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
כל באיה לא ישובון ולא ישיגו ארחות חיים׃ | 19 |
Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
למען תלך בדרך טובים וארחות צדיקים תשמר׃ | 20 |
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
כי ישרים ישכנו ארץ ותמימים יותרו בה׃ | 21 |
Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
ורשעים מארץ יכרתו ובוגדים יסחו ממנה׃ | 22 |
Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.