< מִשְׁלֵי 2 >

בני אם תקח אמרי ומצותי תצפן אתך׃ 1
Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
להקשיב לחכמה אזנך תטה לבך לתבונה׃ 2
tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
כי אם לבינה תקרא לתבונה תתן קולך׃ 3
àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
אם תבקשנה ככסף וכמטמונים תחפשנה׃ 4
bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
אז תבין יראת יהוה ודעת אלהים תמצא׃ 5
Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
כי יהוה יתן חכמה מפיו דעת ותבונה׃ 6
Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
וצפן לישרים תושיה מגן להלכי תם׃ 7
Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
לנצר ארחות משפט ודרך חסידו ישמר׃ 8
Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
אז תבין צדק ומשפט ומישרים כל מעגל טוב׃ 9
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
כי תבוא חכמה בלבך ודעת לנפשך ינעם׃ 10
Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
מזמה תשמר עליך תבונה תנצרכה׃ 11
Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
להצילך מדרך רע מאיש מדבר תהפכות׃ 12
Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
העזבים ארחות ישר ללכת בדרכי חשך׃ 13
ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
השמחים לעשות רע יגילו בתהפכות רע׃ 14
ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
אשר ארחתיהם עקשים ונלוזים במעגלותם׃ 15
ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
להצילך מאשה זרה מנכריה אמריה החליקה׃ 16
Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
העזבת אלוף נעוריה ואת ברית אלהיה שכחה׃ 17
ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
כי שחה אל מות ביתה ואל רפאים מעגלתיה׃ 18
Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
כל באיה לא ישובון ולא ישיגו ארחות חיים׃ 19
Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
למען תלך בדרך טובים וארחות צדיקים תשמר׃ 20
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
כי ישרים ישכנו ארץ ותמימים יותרו בה׃ 21
Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
ורשעים מארץ יכרתו ובוגדים יסחו ממנה׃ 22
Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.

< מִשְׁלֵי 2 >