< איוב 6 >

ויען איוב ויאמר׃ 1
Jobu sì dáhùn ó si wí pé,
לו שקול ישקל כעשי והיתי במאזנים ישאו יחד׃ 2
“Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òsùwọ̀n, kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òsùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!
כי עתה מחול ימים יכבד על כן דברי לעו׃ 3
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn òkun lọ, nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé.
כי חצי שדי עמדי אשר חמתם שתה רוחי בעותי אלוה יערכוני׃ 4
Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú, oró èyí tí ọkàn mi mú; ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.
הינהק פרא עלי דשא אם יגעה שור על בלילו׃ 5
Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko, tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?
היאכל תפל מבלי מלח אם יש טעם בריר חלמות׃ 6
A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀, tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?
מאנה לנגוע נפשי המה כדוי לחמי׃ 7
Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò, òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.
מי יתן תבוא שאלתי ותקותי יתן אלוה׃ 8
“Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà; àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.
ויאל אלוה וידכאני יתר ידו ויבצעני׃ 9
Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run, tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.
ותהי עוד נחמתי ואסלדה בחילה לא יחמול כי לא כחדתי אמרי קדוש׃ 10
Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀, àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí: nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.
מה כחי כי איחל ומה קצי כי אאריך נפשי׃ 11
“Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí? Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?
אם כח אבנים כחי אם בשרי נחוש׃ 12
Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí? Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?
האם אין עזרתי בי ותשיה נדחה ממני׃ 13
Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi: ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?
למס מרעהו חסד ויראת שדי יעזוב׃ 14
“Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá, kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?
אחי בגדו כמו נחל כאפיק נחלים יעברו׃ 15
Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.
הקדרים מני קרח עלימו יתעלם שלג׃ 16
Tí ó dúdú nítorí omi dídì, àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.
בעת יזרבו נצמתו בחמו נדעכו ממקומם׃ 17
Nígbàkígbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ, nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.
ילפתו ארחות דרכם יעלו בתהו ויאבדו׃ 18
Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.
הביטו ארחות תמא הליכת שבא קוו למו׃ 19
Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi, àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.
בשו כי בטח באו עדיה ויחפרו׃ 20
Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e; wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.
כי עתה הייתם לא תראו חתת ותיראו׃ 21
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn; ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.
הכי אמרתי הבו לי ומכחכם שחדו בעדי׃ 22
Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá, tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?
ומלטוני מיד צר ומיד עריצים תפדוני׃ 23
Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni, tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?
הורוני ואני אחריש ומה שגיתי הבינו לי׃ 24
“Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́ kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.
מה נמרצו אמרי ישר ומה יוכיח הוכח מכם׃ 25
Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?
הלהוכח מלים תחשבו ולרוח אמרי נאש׃ 26
Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.
אף על יתום תפילו ותכרו על ריעכם׃ 27
Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba, ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.
ועתה הואילו פנו בי ועל פניכם אם אכזב׃ 28
“Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín. Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé, ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.
שבו נא אל תהי עולה ושבי עוד צדקי בה׃ 29
Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀; àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.
היש בלשוני עולה אם חכי לא יבין הוות׃ 30
Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi? Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?

< איוב 6 >