< איוב 40 >

ויען יהוה את איוב ויאמר׃ 1
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
הרב עם שדי יסור מוכיח אלוה יעננה׃ 2
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
ויען איוב את יהוה ויאמר׃ 3
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
הן קלתי מה אשיבך ידי שמתי למו פי׃ 4
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
אחת דברתי ולא אענה ושתים ולא אוסיף׃ 5
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
ויען יהוה את איוב מן סערה ויאמר׃ 6
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
אזר נא כגבר חלציך אשאלך והודיעני׃ 7
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
האף תפר משפטי תרשיעני למען תצדק׃ 8
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
ואם זרוע כאל לך ובקול כמהו תרעם׃ 9
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
עדה נא גאון וגבה והוד והדר תלבש׃ 10
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
הפץ עברות אפך וראה כל גאה והשפילהו׃ 11
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
ראה כל גאה הכניעהו והדך רשעים תחתם׃ 12
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
טמנם בעפר יחד פניהם חבש בטמון׃ 13
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
וגם אני אודך כי תושע לך ימינך׃ 14
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
הנה נא בהמות אשר עשיתי עמך חציר כבקר יאכל׃ 15
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
הנה נא כחו במתניו ואנו בשרירי בטנו׃ 16
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
יחפץ זנבו כמו ארז גידי פחדו ישרגו׃ 17
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
עצמיו אפיקי נחושה גרמיו כמטיל ברזל׃ 18
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
הוא ראשית דרכי אל העשו יגש חרבו׃ 19
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
כי בול הרים ישאו לו וכל חית השדה ישחקו שם׃ 20
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
תחת צאלים ישכב בסתר קנה ובצה׃ 21
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
יסכהו צאלים צללו יסבוהו ערבי נחל׃ 22
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
הן יעשק נהר לא יחפוז יבטח כי יגיח ירדן אל פיהו׃ 23
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
בעיניו יקחנו במוקשים ינקב אף׃ 24
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

< איוב 40 >