< איוב 40 >
ויען יהוה את איוב ויאמר׃ | 1 |
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
הרב עם שדי יסור מוכיח אלוה יעננה׃ | 2 |
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
ויען איוב את יהוה ויאמר׃ | 3 |
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
הן קלתי מה אשיבך ידי שמתי למו פי׃ | 4 |
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
אחת דברתי ולא אענה ושתים ולא אוסיף׃ | 5 |
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
ויען יהוה את איוב מן סערה ויאמר׃ | 6 |
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
אזר נא כגבר חלציך אשאלך והודיעני׃ | 7 |
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
האף תפר משפטי תרשיעני למען תצדק׃ | 8 |
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
ואם זרוע כאל לך ובקול כמהו תרעם׃ | 9 |
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
עדה נא גאון וגבה והוד והדר תלבש׃ | 10 |
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
הפץ עברות אפך וראה כל גאה והשפילהו׃ | 11 |
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
ראה כל גאה הכניעהו והדך רשעים תחתם׃ | 12 |
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
טמנם בעפר יחד פניהם חבש בטמון׃ | 13 |
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
וגם אני אודך כי תושע לך ימינך׃ | 14 |
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
הנה נא בהמות אשר עשיתי עמך חציר כבקר יאכל׃ | 15 |
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
הנה נא כחו במתניו ואנו בשרירי בטנו׃ | 16 |
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
יחפץ זנבו כמו ארז גידי פחדו ישרגו׃ | 17 |
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
עצמיו אפיקי נחושה גרמיו כמטיל ברזל׃ | 18 |
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
הוא ראשית דרכי אל העשו יגש חרבו׃ | 19 |
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
כי בול הרים ישאו לו וכל חית השדה ישחקו שם׃ | 20 |
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
תחת צאלים ישכב בסתר קנה ובצה׃ | 21 |
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
יסכהו צאלים צללו יסבוהו ערבי נחל׃ | 22 |
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
הן יעשק נהר לא יחפוז יבטח כי יגיח ירדן אל פיהו׃ | 23 |
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
בעיניו יקחנו במוקשים ינקב אף׃ | 24 |
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?