< איוב 27 >

ויסף איוב שאת משלו ויאמר׃ 1
Pẹ̀lúpẹ̀lú Jobu sì tún sọkún ọ̀rọ̀ òwe rẹ̀, ó sì wí pé,
חי אל הסיר משפטי ושדי המר נפשי׃ 2
“Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, ẹni tí ó gba ìdájọ́ mi lọ, àti Olódùmarè tí ó bà mi ní ọkàn jẹ́,
כי כל עוד נשמתי בי ורוח אלוה באפי׃ 3
níwọ́n ìgbà tí ẹ̀mí mi ń bẹ nínú mi, àti tí ẹ̀mí Ọlọ́run ń bẹ nínú ihò imú mi.
אם תדברנה שפתי עולה ולשוני אם יהגה רמיה׃ 4
Ètè mi kì yóò sọ̀rọ̀ èké, bẹ́ẹ̀ ni ahọ́n mi kì yóò sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
חלילה לי אם אצדיק אתכם עד אגוע לא אסיר תמתי ממני׃ 5
Kí a má rí i pé èmi ń dá yín láre; títí èmi ó fi kú, èmi kì yóò ṣí ìwà òtítọ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi.
בצדקתי החזקתי ולא ארפה לא יחרף לבבי מימי׃ 6
Òdodo mi ni èmi dìímú ṣinṣin, èmi kì yóò sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́; àyà mi kì yóò sì gan ọjọ́ kan nínú ọjọ́ ayé mi.
יהי כרשע איבי ומתקוממי כעול׃ 7
“Kí ọ̀tá mi kí ó dàbí ènìyàn búburú, àti ẹni tí ń dìde sí mi kí ó dàbí ẹni aláìṣòdodo.
כי מה תקות חנף כי יבצע כי ישל אלוה נפשו׃ 8
Nítorí kí ni ìrètí àgàbàgebè, nígbà tí Ọlọ́run bá ké ẹ̀mí rẹ̀ kúrò, nígbà tí ó sì fà á jáde?
הצעקתו ישמע אל כי תבוא עליו צרה׃ 9
Ọlọ́run yóò ha gbọ́ àdúrà rẹ̀, nígbà tí ìpọ́njú bá dé sí i?
אם על שדי יתענג יקרא אלוה בכל עת׃ 10
Òun ha le ní inú dídùn sí Olódùmarè? Òun ha lé máa ké pe Ọlọ́run nígbà gbogbo?
אורה אתכם ביד אל אשר עם שדי לא אכחד׃ 11
“Èmi ó kọ́ yín ní ẹ̀kọ́ ní ti ọwọ́ Ọlọ́run: ọ̀nà tí ń bẹ lọ́dọ̀ Olódùmarè ni èmi kì yóò fi pamọ́.
הן אתם כלכם חזיתם ולמה זה הבל תהבלו׃ 12
Kíyèsi i, gbogbo yín ni ó ti rí i; kín ni ìdí ọ̀rọ̀ asán yín?
זה חלק אדם רשע עם אל ונחלת עריצים משדי יקחו׃ 13
“Ẹ̀yin ni ìpín ènìyàn búburú lọ́dọ̀ Ọlọ́run, àti ogún àwọn aninilára, tí wọ́n ó gbà lọ́wọ́ Olódùmarè.
אם ירבו בניו למו חרב וצאצאיו לא ישבעו לחם׃ 14
Bí àwọn ọmọ rẹ bá di púpọ̀, fún idà ni; àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ kì yóò yó fún oúnjẹ.
שרידו במות יקברו ואלמנתיו לא תבכינה׃ 15
Àwọn tí ó kù nínú tirẹ̀ ni a ó sìnkú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn: àwọn opó rẹ̀ kì yóò sì sọkún fún wọn.
אם יצבר כעפר כסף וכחמר יכין מלבוש׃ 16
Bí ó tilẹ̀ kó fàdákà jọ bí erùpẹ̀, tí ó sì dá aṣọ jọ bí amọ̀;
יכין וצדיק ילבש וכסף נקי יחלק׃ 17
àwọn ohun tí ó tò jọ àwọn olóòtítọ́ ni yóò lò ó; àwọn aláìṣẹ̀ ni yóò sì pín fàdákà rẹ̀.
בנה כעש ביתו וכסכה עשה נצר׃ 18
Òun kọ́ ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí kòkòrò aṣọ, àti bí ahéré tí olùṣọ́ kọ́.
עשיר ישכב ולא יאסף עיניו פקח ואיננו׃ 19
Ọlọ́rọ̀ yóò dùbúlẹ̀, ṣùgbọ́n òun kì yóò túnṣe bẹ́ẹ̀ mọ́, nígbà tí ó bá la ojú rẹ̀, gbogbo rẹ̀ a lọ.
תשיגהו כמים בלהות לילה גנבתו סופה׃ 20
Ẹ̀rù ńlá bà á bí omi ṣíṣàn; ẹ̀fúùfù ńlá jí gbé lọ ní òru.
ישאהו קדים וילך וישערהו ממקמו׃ 21
Ẹ̀fúùfù ìlà-oòrùn gbé e lọ, òun sì lọ; àti bí ìjì ńlá ó sì fà á kúrò ní ipò rẹ̀.
וישלך עליו ולא יחמל מידו ברוח יברח׃ 22
Nítorí pé Olódùmarè yóò kọlù ú, kì yóò sì dá sí; òun ìbá yọ̀ láti sá kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
ישפק עלימו כפימו וישרק עליו ממקמו׃ 23
Àwọn ènìyàn yóò sì ṣápẹ́ sí i lórí, wọn yóò sì ṣe síọ̀ sí i kúrò ní ipò rẹ̀.”

< איוב 27 >