< תהילים 102 >
תפלה לעני כי-יעטף-- ולפני יהוה ישפך שיחו ב יהוה שמעה תפלתי ושועתי אליך תבוא | 1 |
Àdúrà olùpọ́njú tí àárẹ̀ mú, tí ó sí ọkàn rẹ̀ payá níwájú Olúwa. Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa, jẹ́ kí igbe ẹ̀bẹ̀ mi kí ó wá sí ọ̀dọ̀ rẹ.
אל-תסתר פניך ממני-- ביום צר-לי הטה-אלי אזנך ביום אקרא מהר ענני | 2 |
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ tí èmi wà nínú ìpọ́njú. Dẹ etí rẹ sí mi; nígbà tí mo bá pè, dá mi lóhùn kíákíá.
כי-כלו בעשן ימי ועצמותי כמוקד נחרו | 3 |
Nítorí tí ọjọ́ mi run bí èéfín; egungun mi sì jóná bí ààrò.
הוכה-כעשב ויבש לבי כי-שכחתי מאכל לחמי | 4 |
Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko; mo gbàgbé láti jẹ oúnjẹ mi.
מקול אנחתי-- דבקה עצמי לבשרי | 5 |
Nítorí ohùn ìkérora mi, egungun mi lẹ̀ mọ́ ẹran-ara mi.
דמיתי לקאת מדבר הייתי ככוס חרבות | 6 |
Èmi dàbí ẹyẹ igún ní ijù: èmi dàbí òwìwí ibi ahoro.
שקדתי ואהיה-- כצפור בודד על-גג | 7 |
Èmi dìde; èmi dàbí ẹyẹ lórí ilé.
כל-היום חרפוני אויבי מהוללי בי נשבעו | 8 |
Ní ọjọ́ gbogbo, àwọn ọ̀tá ológoṣẹ́ mi ń gàn mí; àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.
כי-אפר כלחם אכלתי ושקוי בבכי מסכתי | 9 |
Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi sì da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omijé.
מפני-זעמך וקצפך-- כי נשאתני ותשליכני | 10 |
Nítorí ìbínú ríru rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.
ימי כצל נטוי ואני כעשב איבש | 11 |
Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́ èmi sì rọ bí koríko.
ואתה יהוה לעולם תשב וזכרך לדר ודר | 12 |
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, ni yóò dúró láéláé; ìrántí rẹ láti ìran dé ìran.
אתה תקום תרחם ציון כי-עת לחננה כי-בא מועד | 13 |
Ìwọ ó dìde ìwọ ó sì ṣàánú fún Sioni, nítorí ìgbà àti ṣe ojúrere sí i; àkókò náà ti dé.
כי-רצו עבדיך את-אבניה ואת-עפרה יחננו | 14 |
Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ; wọ́n sì káàánú erùpẹ̀ rẹ.
וייראו גוים את-שם יהוה וכל-מלכי הארץ את-כבודך | 15 |
Àwọn kèfèrí yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, gbogbo ọba ayé yóò máa bẹ̀rù ògo rẹ.
כי-בנה יהוה ציון-- נראה בכבודו | 16 |
Torí tí Olúwa yóò gbé Sioni ró, yóò farahàn nínú ògo rẹ̀.
פנה אל-תפלת הערער ולא-בזה את-תפלתם | 17 |
Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní; kì yóò sì gan ẹ̀bẹ̀ wọn.
תכתב זאת לדור אחרון ועם נברא יהלל-יה | 18 |
Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀, àwọn ènìyàn tí a kò tí ì dá yóò yin Olúwa:
כי-השקיף ממרום קדשו יהוה משמים אל-ארץ הביט | 19 |
“Olúwa wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀run wá ni ó bojú wo ayé,
לשמע אנקת אסיר לפתח בני תמותה | 20 |
láti gbọ́ ìrora ará túbú, láti tú àwọn tí a yàn sí ikú sílẹ̀.”
לספר בציון שם יהוה ותהלתו בירושלם | 21 |
Kí a lè sọ orúkọ Olúwa ní Sioni àti ìyìn rẹ̀ ní Jerusalẹmu.
בהקבץ עמים יחדו וממלכות לעבד את-יהוה | 22 |
Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àti ìjọba pọ̀ láti máa sìn Olúwa.
ענה בדרך כחו (כחי) קצר ימי | 23 |
Ní ipa ọ̀nà mi, ó rẹ agbára mi sílẹ̀, ó gé ọjọ́ mi kúrú.
אמר--אלי אל תעלני בחצי ימי בדור דורים שנותיך | 24 |
Èmi sì wí pé: “Ọlọ́run mi, má ṣe mú mi kúrò ní agbede-méjì ọjọ́ mi; ọdún rẹ̀ ń lọ láti ìran dé ìran.
לפנים הארץ יסדת ומעשה ידיך שמים | 25 |
Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
המה יאבדו-- ואתה תעמד וכלם כבגד יבלו כלבוש תחליפם ויחלפו | 26 |
Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà; gbogbo wọn ni yóò gbó bí aṣọ. Bí ẹ̀wù ni ìwọ yóò pààrọ̀ wọn wọn yóò sì di àpatì.
ואתה-הוא ושנותיך לא יתמו | 27 |
Ṣùgbọ́n ìwọ wà digbí síbẹ̀, ọdún rẹ kò sì ní òpin.
בני-עבדיך ישכונו וזרעם לפניך יכון | 28 |
Àwọn ọmọ ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò dúró ní iwájú rẹ pẹ́; a ó sì fi ẹsẹ̀ irú-ọmọ wọn sọlẹ̀ ní iwájú rẹ.”