< מִשְׁלֵי 24 >

אל-תקנא באנשי רעה ואל-תתאו להיות אתם 1
Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
כי-שד יהגה לבם ועמל שפתיהם תדברנה 2
nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
בחכמה יבנה בית ובתבונה יתכונן 3
Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
ובדעת חדרים ימלאו-- כל-הון יקר ונעים 4
nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
גבר-חכם בעוז ואיש-דעת מאמץ-כח 5
Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
כי בתחבלות תעשה-לך מלחמה ותשועה ברב יועץ 6
Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
ראמות לאויל חכמות בשער לא יפתח-פיהו 7
Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
מחשב להרע-- לו בעל-מזמות יקראו 8
Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
זמת אולת חטאת ותועבת לאדם לץ 9
Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
התרפית ביום צרה-- צר כחכה 10
Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
הצל לקחים למות ומטים להרג אם-תחשוך 11
Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
כי-תאמר-- הן לא-ידענו-זה הלא-תכן לבות הוא-יבין ונצר נפשך הוא ידע והשיב לאדם כפעלו 12
Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
אכל-בני דבש כי-טוב ונפת מתוק על-חכך 13
Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
כן דעה חכמה--לנפשך אם-מצאת ויש אחרית ותקותך לא תכרת 14
Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
אל-תארב רשע לנוה צדיק אל-תשדד רבצו 15
Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
כי שבע יפול צדיק וקם ורשעים יכשלו ברעה 16
nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
בנפל אויביך (אויבך) אל-תשמח ובכשלו אל-יגל לבך 17
Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
פן-יראה יהוה ורע בעיניו והשיב מעליו אפו 18
Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
אל-תתחר במרעים אל-תקנא ברשעים 19
Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
כי לא-תהיה אחרית לרע נר רשעים ידעך 20
nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
ירא-את-יהוה בני ומלך עם-שונים אל-תתערב 21
Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
כי-פתאם יקום אידם ופיד שניהם מי יודע 22
Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
גם-אלה לחכמים הכר-פנים במשפט בל-טוב 23
Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
אמר לרשע--צדיק אתה יקבהו עמים יזעמוהו לאמים 24
Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
ולמוכיחים ינעם ועליהם תבוא ברכת-טוב 25
Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
שפתים ישק משיב דברים נכחים 26
Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
הכן בחוץ מלאכתך--ועתדה בשדה לך אחר ובנית ביתך 27
Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
אל-תהי עד-חנם ברעך והפתית בשפתיך 28
Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
אל-תאמר--כאשר עשה-לי כן אעשה-לו אשיב לאיש כפעלו 29
Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
על-שדה איש-עצל עברתי ועל-כרם אדם חסר-לב 30
Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
והנה עלה כלו קמשנים--כסו פניו חרלים וגדר אבניו נהרסה 31
ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
ואחזה אנכי אשית לבי ראיתי לקחתי מוסר 32
Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
מעט שנות מעט תנומות מעט חבק ידים לשכב 33
oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
ובא-מתהלך רישך ומחסריך כאיש מגן 34
òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.

< מִשְׁלֵי 24 >