< איכה 3 >

אני הגבר ראה עני בשבט עברתו 1
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
אותי נהג וילך חשך ולא אור 2
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
אך בי ישב יהפך ידו כל היום 3
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
בלה בשרי ועורי שבר עצמותי 4
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
בנה עלי ויקף ראש ותלאה 5
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
במחשכים הושיבני כמתי עולם 6
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
גדר בעדי ולא אצא הכביד נחשתי 7
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
גם כי אזעק ואשוע שתם תפלתי 8
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
גדר דרכי בגזית נתיבתי עוה 9
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
דב ארב הוא לי אריה (ארי) במסתרים 10
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
דרכי סורר ויפשחני שמני שמם 11
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
דרך קשתו ויציבני כמטרא לחץ 12
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
הביא בכליתי בני אשפתו 13
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
הייתי שחק לכל עמי נגינתם כל היום 14
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
השביעני במרורים הרוני לענה 15
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
ויגרס בחצץ שני הכפישני באפר 16
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
ותזנח משלום נפשי נשיתי טובה 17
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
ואמר אבד נצחי ותוחלתי מיהוה 18
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
זכר עניי ומרודי לענה וראש 19
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
זכור תזכור ותשיח (ותשוח) עלי נפשי 20
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
זאת אשיב אל לבי על כן אוחיל 21
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
חסדי יהוה כי לא תמנו כי לא כלו רחמיו 22
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
חדשים לבקרים רבה אמונתך 23
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
חלקי יהוה אמרה נפשי על כן אוחיל לו 24
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
טוב יהוה לקוו לנפש תדרשנו 25
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
טוב ויחיל ודומם לתשועת יהוה 26
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
טוב לגבר כי ישא על בנעוריו 27
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
ישב בדד וידם כי נטל עליו 28
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
יתן בעפר פיהו אולי יש תקוה 29
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
יתן למכהו לחי ישבע בחרפה 30
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
כי לא יזנח לעולם אדני 31
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
כי אם הוגה ורחם כרב חסדיו 32
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
כי לא ענה מלבו ויגה בני איש 33
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
לדכא תחת רגליו כל אסירי ארץ 34
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
להטות משפט גבר נגד פני עליון 35
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
לעות אדם בריבו אדני לא ראה 36
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
מי זה אמר ותהי אדני לא צוה 37
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
מפי עליון לא תצא הרעות והטוב 38
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
מה יתאונן אדם חי גבר על חטאו 39
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
נחפשה דרכינו ונחקרה ונשובה עד יהוה 40
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
נשא לבבנו אל כפים אל אל בשמים 41
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
נחנו פשענו ומרינו אתה לא סלחת 42
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
סכותה באף ותרדפנו הרגת לא חמלת 43
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
סכותה בענן לך מעבור תפלה 44
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
סחי ומאוס תשימנו בקרב העמים 45
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
פצו עלינו פיהם כל איבינו 46
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
פחד ופחת היה לנו השאת והשבר 47
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
פלגי מים תרד עיני על שבר בת עמי 48
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
עיני נגרה ולא תדמה מאין הפגות 49
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
עד ישקיף וירא יהוה משמים 50
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
עיני עוללה לנפשי מכל בנות עירי 51
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
צוד צדוני כצפור איבי חנם 52
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
צמתו בבור חיי וידו אבן בי 53
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
צפו מים על ראשי אמרתי נגזרתי 54
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
קראתי שמך יהוה מבור תחתיות 55
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
קולי שמעת אל תעלם אזנך לרוחתי לשועתי 56
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
קרבת ביום אקראך אמרת אל תירא 57
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
רבת אדני ריבי נפשי גאלת חיי 58
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
ראיתה יהוה עותתי שפטה משפטי 59
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
ראיתה כל נקמתם--כל מחשבתם לי 60
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
שמעת חרפתם יהוה כל מחשבתם עלי 61
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
שפתי קמי והגיונם עלי כל היום 62
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
שבתם וקימתם הביטה אני מנגינתם 63
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
תשיב להם גמול יהוה כמעשה ידיהם 64
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
תתן להם מגנת לב תאלתך להם 65
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
תרדף באף ותשמידם מתחת שמי יהוה 66
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

< איכה 3 >