< איכה 3 >
אני הגבר ראה עני בשבט עברתו | 1 |
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
אותי נהג וילך חשך ולא אור | 2 |
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
אך בי ישב יהפך ידו כל היום | 3 |
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
בלה בשרי ועורי שבר עצמותי | 4 |
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
במחשכים הושיבני כמתי עולם | 6 |
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
גדר בעדי ולא אצא הכביד נחשתי | 7 |
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
גם כי אזעק ואשוע שתם תפלתי | 8 |
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
גדר דרכי בגזית נתיבתי עוה | 9 |
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
דב ארב הוא לי אריה (ארי) במסתרים | 10 |
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
דרכי סורר ויפשחני שמני שמם | 11 |
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
דרך קשתו ויציבני כמטרא לחץ | 12 |
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
הייתי שחק לכל עמי נגינתם כל היום | 14 |
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
השביעני במרורים הרוני לענה | 15 |
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
ויגרס בחצץ שני הכפישני באפר | 16 |
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
ותזנח משלום נפשי נשיתי טובה | 17 |
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
ואמר אבד נצחי ותוחלתי מיהוה | 18 |
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
זכר עניי ומרודי לענה וראש | 19 |
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
זכור תזכור ותשיח (ותשוח) עלי נפשי | 20 |
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
זאת אשיב אל לבי על כן אוחיל | 21 |
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
חסדי יהוה כי לא תמנו כי לא כלו רחמיו | 22 |
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
חדשים לבקרים רבה אמונתך | 23 |
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
חלקי יהוה אמרה נפשי על כן אוחיל לו | 24 |
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
טוב יהוה לקוו לנפש תדרשנו | 25 |
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
טוב ויחיל ודומם לתשועת יהוה | 26 |
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
טוב לגבר כי ישא על בנעוריו | 27 |
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
ישב בדד וידם כי נטל עליו | 28 |
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
יתן בעפר פיהו אולי יש תקוה | 29 |
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
יתן למכהו לחי ישבע בחרפה | 30 |
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
כי אם הוגה ורחם כרב חסדיו | 32 |
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
כי לא ענה מלבו ויגה בני איש | 33 |
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
לדכא תחת רגליו כל אסירי ארץ | 34 |
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
להטות משפט גבר נגד פני עליון | 35 |
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
לעות אדם בריבו אדני לא ראה | 36 |
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
מי זה אמר ותהי אדני לא צוה | 37 |
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
מפי עליון לא תצא הרעות והטוב | 38 |
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
מה יתאונן אדם חי גבר על חטאו | 39 |
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
נחפשה דרכינו ונחקרה ונשובה עד יהוה | 40 |
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
נשא לבבנו אל כפים אל אל בשמים | 41 |
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
נחנו פשענו ומרינו אתה לא סלחת | 42 |
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
סכותה באף ותרדפנו הרגת לא חמלת | 43 |
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
סכותה בענן לך מעבור תפלה | 44 |
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
סחי ומאוס תשימנו בקרב העמים | 45 |
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
פצו עלינו פיהם כל איבינו | 46 |
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
פחד ופחת היה לנו השאת והשבר | 47 |
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
פלגי מים תרד עיני על שבר בת עמי | 48 |
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
עיני נגרה ולא תדמה מאין הפגות | 49 |
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
עד ישקיף וירא יהוה משמים | 50 |
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
עיני עוללה לנפשי מכל בנות עירי | 51 |
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
צוד צדוני כצפור איבי חנם | 52 |
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
צמתו בבור חיי וידו אבן בי | 53 |
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
צפו מים על ראשי אמרתי נגזרתי | 54 |
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
קראתי שמך יהוה מבור תחתיות | 55 |
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
קולי שמעת אל תעלם אזנך לרוחתי לשועתי | 56 |
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
קרבת ביום אקראך אמרת אל תירא | 57 |
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
רבת אדני ריבי נפשי גאלת חיי | 58 |
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
ראיתה יהוה עותתי שפטה משפטי | 59 |
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
ראיתה כל נקמתם--כל מחשבתם לי | 60 |
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
שמעת חרפתם יהוה כל מחשבתם עלי | 61 |
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
שפתי קמי והגיונם עלי כל היום | 62 |
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
שבתם וקימתם הביטה אני מנגינתם | 63 |
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
תשיב להם גמול יהוה כמעשה ידיהם | 64 |
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
תתן להם מגנת לב תאלתך להם | 65 |
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
תרדף באף ותשמידם מתחת שמי יהוה | 66 |
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.