< איוב 8 >

ויען בלדד השוחי ויאמר 1
Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
עד-אן תמלל-אלה ורוח כביר אמרי-פיך 2
“Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
האל יעות משפט ואם-שדי יעות-צדק 3
Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
אם-בניך חטאו-לו וישלחם ביד-פשעם 4
Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
אם-אתה תשחר אל-אל ואל-שדי תתחנן 5
Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
אם-זך וישר אתה כי-עתה יעיר עליך ושלם נות צדקך 6
Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
והיה ראשיתך מצער ואחריתך ישגה מאד 7
Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
כי-שאל-נא לדר רישון וכונן לחקר אבותם 8
“Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
כי-תמול אנחנו ולא נדע כי צל ימינו עלי-ארץ 9
Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
הלא-הם יורוך יאמרו לך ומלבם יוצאו מלים 10
Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
היגאה-גמא בלא בצה ישגה-אחו בלי-מים 11
Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
עדנו באבו לא יקטף ולפני כל-חציר ייבש 12
Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
כן--ארחות כל-שכחי אל ותקות חנף תאבד 13
Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
אשר-יקוט כסלו ובית עכביש מבטחו 14
Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
ישען על-ביתו ולא יעמד יחזיק בו ולא יקום 15
Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
רטב הוא לפני-שמש ועל גנתו ינקתו תצא 16
Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
על-גל שרשיו יסבכו בית אבנים יחזה 17
Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
אם-יבלענו ממקמו וכחש בו לא ראיתיך 18
Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
הן-הוא משוש דרכו ומעפר אחר יצמחו 19
Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
הן-אל לא ימאס-תם ולא-יחזיק ביד-מרעים 20
“Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
עד-ימלה שחוק פיך ושפתיך תרועה 21
títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
שנאיך ילבשו-בשת ואהל רשעים איננו 22
ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”

< איוב 8 >