< Zekaria 6 >

1 NANA hou ae la au iluna, ike aku la, aia hoi, puka mai la na halekaa eha mai waena mai o na mauna elua, a he mau mauna keleawe melemele laua.
Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
2 Ma ka halekaa mua he mau lio ulaula; ma ka lua o ka halekaa he mau lio eleele;
Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
3 I ke kolu o ka halekaa, he mau lio keokeo, a i ka ha o ka halekaa he mau lio kaliko a he makue.
Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
4 Alaila, ninau aku laau, i aku la i ka anela i kamailio me au, E ka haku, heaha keia mau mea?
Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
5 Olelo mai la ka anela, i mai la ia'u, Eia na uhane eha o ka lani, e hele ae ana mai kahi a lakou i ku aku ai imua o ka Haku o ka honua a pau.
Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
6 A hele aku no ko laila mau lio eleele i ka aina kukulu akau; a hele aku na mea keokeo mamuli o laua; a hele aku hoi na mea kaliko ma ka aina kukulu hema.
Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
7 Aka, hele iho la na mea makue e imi e holoholo maluna o ka honua: i aku la kela ia lakou, Ou haele, e holoholo ae oukou mai o a o, ma ka honua. A holoholo ae la lakou mai o a o, ma ka honua.
Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
8 Alaila kahea mai la kela ia'u, i mai la ia'u, Aia hoi, o ka poe i hele ma ka aina kukuluakau, ua hoomalielie lakou i kuu inaina ma ka aina kukuluakau.
Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
9 Hiki hou mai la ka olelo a Iehova ia'u, i mai la,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
10 E kono oe i kekahi poe i lawe pio, i ko Heledai, i ko Tobiia, a i ko Iedaia, i ko ka poe i hoi mai, mai Babulona mai, a hele oe a e komo ia la iloko o ka hale o Iosia o ke keiki a Zepania;
“Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
11 E lawe hoi oe i ke kala a me ke gula, a e hana i k na papale alii, a e kau ia mau mea maluna o ke poo o Iosua o ke keiki a Iosedeka ke kahuna nui;
Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
12 Penei hoi e olelo aku ai ia ia, Ke olelo mai nei o Iehova o na kaua, penei, Aia hoi ke kanaka ua kapaia kona inoa, o ka LALA; e kupu auanei oia mailoko ae o kona wahi, nana no e hana ka luakini o Iehova;
Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
13 Nana no e hana ka luakini o Iehova; a nana hoi e lawe ka hanohano, a e alii mai no oia e noho ana maluna o kona nohoalii; a e kahuna no auanei oia maluna o kona nohoalii; a mawaena o laua auanei ka mea e malu ai.
Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
14 A e lilo na papale alii no Helema, no Tobiia, no Iedaia, a no Hena ke keiki a Zepania, i mea hoomanao ai iloko o ka luakini o Iehova.
Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
15 A e hele mai auanei ka poe mamao, a e hana lakou i ka luakini o Iehova, a e ike auanei oukou, ua hoouna mai o Iehova o na kaua ia'u io oukou la: a e ko auanei keia, ke hoolohe pono oukou i ka leo o Iehova ko oukou Akua.
Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”

< Zekaria 6 >