< Halelu 89 >
1 E HOOKANI mau loa aku au i ka lokomaikai o Iehova; Ma ko'u waha e hoike aku at au i kou oiaio i kela hanauna, i keia hanauna.
Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
2 No ka mea, ua olelo no wau, e hoopaa mau loa ia kou lokomaikai; A e hookumu no hoi oe i kou oiaio ma ka lani.
Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
3 Ua hana au i berita me kou poe i waeia, Ua hoohiki aku au no Davida, ka'u kauwa,
Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
4 E hoonoho paa loa wau i kau poe mamo, A e hana no hoi au i nohoalii nou no na hanauna a pau. (Sila)
‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
5 Na ka lani no e hoolea i kou mau mea mana, e Iehova, I kou oiaio kekahi, ma ke anaina o ka poe pono.
Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
6 No ka mea, owai la ka mea ma ke aonli e ku like me Iehova? Iwaena hoi o na keiki a ka poe kiekie, e hoohalikeia me Iehova?
Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
7 He Akua woliweli loa hoi ia ma ke anaina o ka poe pono; A he mea ia e hopohopo ai no ka poe a pau e noho hoopuni ana ia ia.
Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
8 E Iehova, ke Akua o na kaua, Owai la kekahi Iehova e like me oe? Me kou oiaio hoi e hoopuni ana ia oe?
Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
9 O oe no ka i hookouopono i ke kupikipikio ana o ke kai; A pii nui ae kona mau ale, nau ia e hoomalielie.
Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
10 Ua paopao no oe ia Rahaba, me he mea la i pepehiia; I ka ikaika o kou lima, na hooauhee oe i kou poe enemi.
Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
11 Nau no ka lani, nau no hoi ka honua; Ua hookumu no oe i ke ao, a me kona mau mea e piha'i.
Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
12 O ke kukulu akau, a me ke kukuluhema, nau no i hana ia mau mea; E olioli no o Tabora a me Heremona i kou inoa.
Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
13 He lima no kou i lako i ka ikaika: Ua ikaika no kou lima, ua kiekie hoi kou lima akau.
Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
14 O ka pono, a me ka hoopono, oia ke kumu o kou nohoalii: E hele ae no imua o kou maka ka lokomaikai, a me ka oiaio.
Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
15 Pomaikai ka poe kanaka ike ia leo hauoli: E Iehova, e hele no lakou ma ka malamalama o kou maka.
Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
16 E hauoli no lakou i kou inoa a po ka la; A ma kou pono hoi e hookiekieia'i lakou.
Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
17 No ka mea, o oe no ka nani o ko lakou ikaika; A ma kou lokomaikai e hookiekieia'i ko makou pepeiaohao.
Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
18 No ka mea, aia no ia Iehova ko makou paku, A i ka Mea Hemolele hoi o ka Iseraela, ko makou alii.
Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
19 Alaila, olelo iho no oe i kou mea hemolele ma ke akaku, I mai la. Ua kau aku au i ka mana maluna o ka mea ikaika; Ua hookiekie au i ka mea i waeia mai o na kanaka.
Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
20 Ua loaa ia'u o Davida, o ka'u kauwa; Ua poni aku no au ia ia me kuu aila laa.
Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
21 E paa mau no ko'u lima me ia, A e hooikaika aku no ko'u lima ia ia.
Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
22 Aole e kii mai ka enemi i kana, Aole hoi e hookaumaha ke keiki a ka hewa ia ia.
Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
23 Na'u no e hooauhee i kona poe enemi imua ona, A e luku aku hoi i ka poe inaina mai ia ia,
Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
24 E noho no ko'u oiaio a me ko'u lokomaikai me ia; A ma ko'u inoa e hookiekieia'i kona pepeiaohao.
Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
25 E hookau aku au i kona lima ma ke kai, A me kona lima akau hoi ma na muliwai.
Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
26 E hea mai no oia ia'u, O oe no ko'u Makua, O ko'u Akua hoi, a me ka Pohaku o ko'u hoolaia.
Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
27 E hoolilo no wau ia ia i ko'u makahiapo, I mea kiekie maluna o na'lii o ka honua.
Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
28 E malama mau loa no wau i ko'u lokomaikai ia ia, A e ku paa loa no ko'u berita me ia.
Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
29 E hoomau loa no wau i kona poe mamo, A me kona nohoalii hoi, e like me na la o ka lani.
Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
30 Ina haalele kana poe keiki i ko'u kanawai, Aole hoi e hele ma kou hoopono ana.
“Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
31 Ina kuu aku lakou i ka'u olelo pau, Aole hoi e malama i ka'u mau kauoha;
Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
32 Alaila e hoopai aku au i ko lakou hewa i ka laau hahau, A me ko lakou hala hoi i ke kaula.
nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
33 Aole nae o lawe loa aku au i ko'u lokomaikai mai ona aku. Aole hoi au e hoole i ko'u lokomaikai.
ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
34 Aole au e ae maluna o ka'u berita, Aole hoi e hoololi i ka olelo i puka aku ma ko'u lehelehe.
Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
35 Hookahi no ko'u hoohiki ana i ko'u hemolele, Aole au e wahahee aku ia Davida.
Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
36 E mau loa ana no kana poe mamo, A me kona nohoalii, e like me ka la imua o'u.
Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
37 E hoopaa mau loa ia no hoi ia, e like me ka mahina, Me he mea hoike oiaio la ma ke aouli. (Sila)
A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
38 Aka, ua hooki mai oe, a ua hoopailua mai, A ua huhu mai no hoi oe i kau mea i poni ai.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
39 Ua hoole mai no hoi oe i ka berita o kau kauwa: Ua hoolei oe i kona leialii i lalo i ka lepo.
Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
40 Ua wawahi no hoi oe i kona mau pa a pau, Ua haawi mai no hoi oe i kona mau pakaua i ka lukuia.
Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
41 Hao wale ia ia ka poe a pau e maalo ana ae malaila: He mea hoomaewaowa ia i kona poe hoalauna.
Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
42 Ua hookiekio oe i ka lima akau o kona poe enemi; Ua hoohauoli oe i ka poe a pau i inaina mai ia ia.
Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
43 Ua hoohuli ae no hoi oe i ka maka o kana pahikaua, Aole hoi oe i hookupaa ia ia ma ke kaua.
Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
44 Ua hooki mai oe i kona nani, A ua hoolei i kona nohoalii ilalo i ka lepo.
Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
45 Ua hoopokole mai oe i na la o kona wa opiopio; Ua uhi mai no hoi oe ia ia i ka hilahila. (Sila)
Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
46 Pehea la ka loihi o kou hoonalo ana ia oe iho, e Iehova? E mau loa anei? E a mai nei anei kou huhu me he ahi la?
Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
47 E hoomanao mai oe ia'u, pehea la ka loihi o ke ola ana? No ke aha la oe i hana makehewa ai i na kanaka a pau?
Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
48 Owai ke kanaka e ola nei, aole oia e ike i ka make? E hoopakele anei oia i kona ola, mai ka lima aku o ka mea make? (Sila) (Sheol )
Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol )
49 Auhea la kou lokomaikai o na manawa kahiko, e ka Haku? Ka mea au i hoohiki ai ia Davida ma ka oiaio?
Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
50 E hoomanao mai oe, e ka Haku, i ka hoinoia o kau kauwa; Ua lawe no wau ma kou umauma i na lehulehu a pau o kou poe kanaka.
Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
51 No ka mea, ua hoino wale mai kou poe enemi, e Iehova, Ua hoino wale mai hoi i na kapuwai o kou mea i poniia.
ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
52 E hoomaikaiia o Iehova, a i ka manawa pau ole. Amene, Amene.
Olùbùkún ní Olúwa títí láé.