< Halelu 77 >

1 KAHEA aku la au i ke Akua ma ko'u leo, Ma ko'u leo i ke Akua, a hoolohe mai la ia ia'u.
Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu. Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́; mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
2 I ko'u la i popilikia ai, nonoi aku la au i ka Haku: Kikoo aku la kuu lima i ka po, aole i haule: Hoole iho la kuu naau, aole ia e hoomahaia.
Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú, mo wá Olúwa; ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀ ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
3 Hoomanao aku la au i ke Akua, a kupikipikio iho la; Noonoo aku la au, a maule iho la kuu naau. (Sila)
Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run, mo sì kẹ́dùn; mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. (Sela)
4 Ua paa ia oe na alu o ko'u mau maka: Ua lauwiliia hoi au, aole hiki ke olelo aku.
Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun, mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
5 Noonoo no au i na la kahiko, I na makahiki hoi o ka wa mamua loa aku.
Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì; ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
6 Hoomanao iho la au i kuu mele i ka po: Me kuu naau wau i kukakuka iho ai; Huli ikaika hoi ko'u manao.
mo rántí orin mi ní òru. Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀, ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
7 E kipaku anei ka Haku i ka manawa pau ole? Aole anei ia e maliu hou mai?
“Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé? Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
8 Ua pauhia anei kona lokomaikai? Ua hala mau loa aku anei kana olelo?
Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé? Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
9 Ua hoopoina anei ke Akua i ka lokomaikai? Ua puliki anei oia i kona aloha iloko o ka huhu? (Sila)
Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú? Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” (Sela)
10 I aku la au, o ko'u nawaliwali keia, O na makahiki o ka lima akau o ka Mea kiekie loa.
Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi, pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
11 E hoomanao aku au i na hana mana a Iehova: E hoomanaoio no hoi au i na mea kupanaha au, i ka wa kahiko.
Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
12 E noonoo aku au i kau hana a pau, A e manao nui hoi i kau mau haua mana.
Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo, pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
13 Aia kou aoao, e ke Akua, ma kahi hoano, Owai la ke Akua nui e like me ke Akua?
Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
14 O oe ke Akua nana i hana na mea mana: Ua hoike mai no hoi oe i kou ikaika mawaena o na kanaka.
Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu; ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
15 I kou lima iho no oe i panai ai i kou poe kanaka, I na mamo a Iseraela, a me Iosepa. (Sila)
Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà, àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. (Sela)
16 Ike aku la na wai ia oe, e ke Akua; Ike aku la na wai ia oe, a haalulu iho la: Kupikipikio no hoi na hohonu.
Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run, nígbà tí àwọn omi rí ọ, ẹ̀rù bà wọ́n, nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
17 Ninini mai la hoi na ao i ka wai: Hoohekili mai la hoi na ao; Hoholo ae la na uila ou.
Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀, àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn; ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
18 Maloko o ka puahiohio ka leo o kou hekili: Hoomalamalama mai la na uila i ka honua: Naue iho la ka honua me ka haalulu.
Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé; ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
19 Aia kou kuamoo ma ka moana, A o kou alanui hoi ma na wai nui; Aole i ikeia kou mau kapuwai.
Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun, ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá, nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
20 Alakai aku no oe i kou poe me he ohana hipa la, Ma ka lima o Mose, ma laua o Aarona.
Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.

< Halelu 77 >