< Halelu 63 >

1 E KE Akua, o oe no ko'u Akua, e imi koke no au ia oe; Ke makewai nei no hoi ko'u uhane nou, Ke iini nei ko'u kino ia oe i ka aina maloo, Me ka makewai, ma kahi wai ole;
Saamu ti Dafidi. Nígbà tí ó wà nínú aginjù Juda. Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi, nígbà gbogbo ni mo ń ṣàfẹ́rí rẹ, òǹgbẹ rẹ ń gbẹ ọkàn mi, ara mi fà sí ọ, ní ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tí ń ṣàárẹ̀ níbi tí kò sí omi.
2 I ike au i kou mana a me kou nani, Me a'u i ike ai ia oe maloko o kahi hoano.
Èmi ti rí ọ ní ibi mímọ́, mo rí agbára àti ògo rẹ.
3 No ka mea, ua oi aku ka pono o kou lokomaikai mamua o ke ola nei, E hoolea aku ko'u mau lehelehe ia oe.
Nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ayé lọ, ètè mi yóò fògo fún ọ.
4 Pela e hoomaikai aku ai au ia oe i ko'u ola nei; I kou inoa, e hapai ai au i ko'u mau lima.
Èmi ó yìn ọ́ níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè, èmi ó gbé ọwọ́ sókè, èmi ó sì pe orúkọ rẹ.
5 E maona auanei ko'u uhane me he mea la he ono loa a me ka momona; Me na lehelehe olioli e hoolea aku ai ko'u waha;
A ó tẹ́ ọkàn mi lọ́rùn bí ọlọ́ràá oúnjẹ; pẹ̀lú ètè ìyìn, ẹnu mi yóò yìn ọ́.
6 I ko'u hoomanao ana ia oe ma kuu wahi moe, Me ka manaonao ia oe i na wati o ka po.
Nígbà tí mo rántí rẹ lórí ibùsùn mi; èmi ń ronú rẹ títí ìṣọ́ òru.
7 No ka mea, ua lilo oe i kokua no'u; Nolaila, ma ka malu o kou mau eheu, e hauoli aku ai au.
Nítorí ìwọ ni ìrànlọ́wọ́ mi, mo kọrin níbi òjìji ìyẹ́ apá rẹ.
8 Ke hahai ikaika nei ko'u uhane mamuli ou; Ke kokua paa mai nei kou lima akau ia'u.
Ọkàn mí fà sí ọ: ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbé mi ró.
9 Aka, o ka poe imi mai i kuu uhane e pepehi mai, E komo lakou i ko lalo mau wahi o ka honua.
Àwọn tí ó ń wá ọkàn mí ni a ó parun; wọn ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.
10 E haule lakou i ka pahikaua; E lilo lakou i waiwai kaili no na alopeke.
Wọn ó ti ọwọ́ idà ṣubú wọn ó sì di jíjẹ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.
11 Aka, e olioli ke alii ike Akua; E hauoli hoi na mea a pau i hoohiki ma o na la, Aka, e hoopaaia ka waha o ka poe olelo wahahee.
Ṣùgbọ́n ọba yóò yọ̀ nínú Ọlọ́run ẹni tí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra yóò ṣògo ṣùgbọ́n ẹnu àwọn òpùrọ́ la ó pamọ́.

< Halelu 63 >