< Halelu 60 >

1 E KE Akua, ua haalele mai oe ia makou; Ua hooanhee liilii oe ia makou; Ua huhu ae nei oe; e maliu hou mai ia makou.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀. Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká, ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
2 Ua hoonauweuwe mai oe i ka honua, a wawahi hoi ia; E hoola i kona nahaha ana, no ka mea, ke nauweuwe nei no ia.
Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
3 Ua hoike mai oe i kou poe kanaka i na mea paakiki; Ua hoohainu mai oe ia makou i ka waina o ka haalulu.
Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ; ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
4 Ua haawi mai oe i ka hae i ka poe weliweli ia oe, I hookiekieia'e no ia no ka oiaio. (Sila)
Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. (Sela)
5 I hoopakeleia kou mea aloha; E hoola mai me kou lima akau, a e hooloho mai ia'u.
Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
6 Olelo iho la ke Akua ma kona hoano; E hauoli au, e puunane au ia Sekema; A o ke awawa o Sukota ka'u e ana aku ai.
Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
7 No'u no Gileada; no'u no hoi o Manase; O Eperaima ka ikaika o kuu poo; O Iuda ko'u hoailona moi;
Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efraimu ni àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
8 O Moaba ko'u ipu holoi; Maluna o Edoma e hoohemo aku ai au i kuu kamaa: E hauoli oe, e Pilisetia maluna o'u.
Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
9 Owai la ka mea nana wau e lawe i ke kulanakauhale pakaua? Owai la ka mea nana wau e alakai i Edoma?
Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
10 Aole anei o oe, ke Akua, ka mea i haalele mai ia makou? A o oe, e ke Akua, ka i hele pu ole me ko makou poe kaua?
Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
11 E kokua mai oe ia makou i ka popilikia; No ka mea, he lapuwale ke kokua ana o ke kanaka.
Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
12 Iloko o ke Akua e koa aku ai kakou; Oia ke hehi iho i ko kakou poe enemi.
Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.

< Halelu 60 >