< Halelu 2 >
1 NO ke aha la e kupikipikio ai ko ka aina e? A e noonoo ai ka poe kanaka i ka mea lapuwale?
Èéṣe tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń dìtẹ̀, àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkíṣí asán?
2 Ua ku e aku na'lii o ka honua, Ua ohumu pu aku no hoi na luna, Ia Iehova, a i kona Mea i poniia,
Àwọn ọba ayé péjọpọ̀ àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀ sí Olúwa àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.
3 E moku aku kakou i ka laua mau mea paa, A e hoolei aku hoi mai o kakou aku nei i ka laua mau kaula.
Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já, kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”
4 O ka Mea e noho ana ma ka lani, e aka mai no ia: A e hoomahua mai no hoi o ka Haku ia lakou.
Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín; Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
5 Alaila e olelo mai oia ia lakou i kona inaina, A e hoomakaua mai hoi ia lakou i kona huhu nui.
Nígbà náà ni yóò bá wọn wí ní ìbínú rẹ̀ yóò sì dẹ́rùbà wọ́n ní ìrunú rẹ̀, ó wí pé,
6 Ua poni ae nei au i ka'u Alii maluna o Ziona, Maluna iho o ko'u mauna hoano.
“Èmi ti fi ọba mi sí ipò lórí Sioni, òkè mímọ́ mi.”
7 E hai aku au i ke kauoha: Ua olelo mai la o Iehova ia'u, O oe no ka'u Keiki; I keia la no, ua hoohanau aku wau ia oe.
Èmi yóò sì kéde ìpinnu Olúwa: Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí, èmi ti di baba rẹ.
8 E noi mai oe ia'u, a e haawi aku au ia oe I na lahuikanaka i hooilina nou, A i waiwai hoi nou na welelau o ka honua.
Béèrè lọ́wọ́ mi, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè di ìní rẹ, òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún rẹ.
9 E uhai oe ia lakou me ke kookoo hao: E ulupa hoi oe ia lakou me he ipulepo la.
Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn ìwọ yóò sì rún wọn wómúwómú bí ìkòkò amọ̀.”
10 No ia hoi, e hoonaauao oukou, e na alii; E aoia'ku no hoi oukou, e na lunakanawai o ka honua.
Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n; ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.
11 E malama ia Iehova me ka weliweli, E hauoli hoi oukou me ka haalulu.
Ẹ sin Olúwa pẹ̀lú ìbẹ̀rù ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.
12 E honi aku i ke Keiki, o huhu mai ia, O make hoi oukou ia aoao, ke hoa iki ia mai kona inaina. Pomaikai wale ka poe a pau i hilinai aku ia ia.
Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú, kí ó má ba à pa yín run ní ọ̀nà yín, nítorí ìbínú rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi í ṣe ibi ìsádi wọn.