< Halelu 105 >

1 E MILILANI aku ia Iehova, e kahea aku hoi i kona inoa: E hoike aku hoi i kana mau hana iwaena o na kanaka.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 E oli aku ia ia, e hoolea aku ia ia; E hookaulana aku i kana mau hana a pau.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 E kaena oukou ma kona inoa hoano, E lealea hoi ka naau o ka poe imi ia Iehova.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 E huli oukou ia Iehova, a me kona ikaika; E imi mau loa aku hoi i kona maka.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 E hoomanao i na hana mana ana i hana'i, A me kana mau mea kupanaha, A me ka hooponopono ana o kona waha:
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 E na pua a Aberahama, a kana kauwa, E na mamo a Iakoba, kona mea i wae ai.
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Oia no o Iehova, ko kakou Akua: Aia ma ka honua a pau kana hoopononono ana.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Ua hoomanao mau mai oia i kona berita, I ka olelo hoi ana i kauoha mai ai i na hanauna he tausani;
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 Ka mea ana i hana mai ai ia Aberahama, A me kana hoohiki ana ia Isaaka;
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 A hoopaa mai no hoi oia ia mea ia Iakoba i kanawai nona, A ia Iseraela hoi, i berita mau loa.
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 I mai la, E haawi aku no wau ia oe i ka aina o Kanaana, I moku no oukou e nobo hooilina ai;
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 I ko lakou noho kanaka ole ana, na uuku; A he poe uuku a malihini hoi malaila.
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 Ia lakou i hele ai, mai kekahi aina, a i kekahi aina, A mai kekahi aupuni aku, a i kekahi lahuikanaka e;
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Aole ia i kuu mai i kekahi kanaka a hana ino ia lakou; Papa mai no oia i na'lii no lakou:
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 Mai hoopa oukou i ko'u poe i poniia, A mai hana ino hoi i ko'u poe kaula.
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Kahea ae no hoi ia, i wi ma ia aina, Uhai no hoi oia i ko kookoo berena a pau.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 Hoouna ae la oia i ke kanaka mamua o lakou, A kuaiia o Iosepa i kauwa;
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 A hoeha lakou i kona mau wawae i ke kupee; A komo no hoi kona ola iloko o ka paahao;
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 A hiki i ka manawa o kana olelo ana; Alaila, hoao ae la ka olelo a Iehova ia ia.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 Hoouna ae la ke alii, a hookuu iho la ia ia; Na ka luna o na kanaka i wehe ae ia ia.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Hoonoho iho la oia ia ia i haku maluna o kona bale, A i luna hoi maluua o kona waiwai a pau;
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 E nakinaki i kona poo alii, ma kona manao iho, A e hoonaauao hoi i kana poe luna kahiko.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Hele ae la o Iseraela i Aigupita; Noho malihini iho la o Iakoba ma ka aina o Hama.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Hookawowo nui iho la kela i kona poe kanaka, A hoomahuahua ae la i ko lakou ikaika imua o ko lakou poe enemi.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 Hoohuli aku la oia i ko lakou naau, I inaina mai ai i kona poe kanaka, A e hana maalea hoi i kana poe kanwa,
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Hoouna mai la oia ia Mose, i kana kanwa, Ia Aarona hoi, ka mea ana i wae mai ai
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Hoike mai la laua i kona hoailona no lakou, A me kana mau hana kupanaha ma ka aina o Hama.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Hoouna mai la oia i ka pouli, a ua pouli iho la, Aole hoi laua i kipi aku i kana olelo.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Hoolilo mai la oia i ko lakou wai i koko, A hoopau hoi i ka lakou ia i ka make.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Hookawowo mai la ko lakou aina i na rana, Aia no iloko o na keena o ko lakou poe alii.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Olelo mai oia a hiki mai la na makika, O na uku hoi kekahi ma ko lakou mokuna a pau.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Haawi mai la oia i ko lakou ua, he huahekili, I ke ahi hoi, e lapalapa ana ma ko lakou aina,
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Hahau mai la oia i ko lakou mau kumu waina, a me na laau fiku, o lakou; A uhai mai la hoi i na laau o ko, lakou mokuna.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Olelo mai la oia, a hiki mai la na uhini, A me na enuhe huluhulu pau ole i ka helu.
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 A ai iho la lakou i na mea uliuli a pau o ko lakou aina, A hoopau no hoi i ka hua o ka lakou mahinaai.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Pepehi no hoi oia i na makahiapo a pau o ko lakou aina, I ke pookela hoi o ko lakou ikaika a pau.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Hoopuka mai la oia ia lakou iwaho, me ke kala a me ke gula; Aohe mea nawaliwali mawaena o ko lakou mau ohana.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Olioli no ko Aigupita i ko lakou puka ana iwaho; No ka mea, kau mai la ka makau ia lakou maluna o ia poe.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Hohola ae la oia i ke ao e uhi ai ia lakou, I ke ahi hoi, e hoomalamalama mai i ka po.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 Nonoi aku la lakou, a lawe mai la ia i na silo, A hoomaona mai la oia ia lakou i ka berena o ka lani.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Wahi ae la oia i ka pohaku, a poha mai la na wai; Kahe ae la lakou ma kahi maloo, he muliwai.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 No ka mea, hoomanao ae la ia i kana olelo hoano, A me Aberahama hoi, i kana kauwa.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Hoopuka mai oia i kona poe kanaka me ka olioli, A me kona poe i waeia me ka hauoli.
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 Haawi mai la oia i ka aina o ko na aina e no lakou, A loaa mai ia lakou ka mea a na kanaka i hooikaika'i:
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 I mea e malama'i lakou i kana mau kauoha, A e hana pono hoi i kona mau kanawai. E halelu aku oukou ia Iehova.
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Halelu 105 >