< Halelu 10 >

1 NO ke aha la oe e ku ai i kahi loihi aku, e Iehova? A e huna ai ia oe iho i ka manawa popilikia?
Èéha ti ṣe, Olúwa, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré? Èéha ti ṣe, tí ìwọ fi ara rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?
2 O ka mea hewa, i kona hookano, Ua hoomaau mai oia i ka mea ilihune: E puni lakou i ka manao a lakou i noonoo ai.
Nínú àrékérekè ni ènìyàn búburú tí mu aláìlera, ẹni ti ó mú nínú ìdẹ̀kùn àrékérekè rẹ̀.
3 No ka mea, ua hookelakela ka mea hewa i ka makemake o kona naau, A i ke ko ana, ua hoomaikai, a ua hoowahawaha aku ia Iehova.
Nítorí ènìyàn búburú ń ṣògo ìfẹ́ inú ọkàn rẹ̀; Ó bùkún olójúkòkòrò, ó sì ń kẹ́gàn Olúwa.
4 O ka mea hewa, aole ia e pule, no ka haaheo o kona maka; Aole ke Akua i kona manao a pau.
Ènìyàn búburú kò lè rí nínú ìgbéraga rẹ̀; kò sí ààyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò rẹ̀.
5 Ua hewa mau kona mau aoao; O kau mau oihana, maluna lilo no ia aole ikea ia ia; A o kona mau enemi, ua puhi aku oia ia lakou.
Ọ̀nà rẹ̀ ń gún régé nígbà gbogbo; òun ń gbéraga, òfin rẹ̀ sì jìnnà sí i; òun kẹ́gàn àwọn ọ̀tá rẹ̀.
6 Ua olelo oia iloko o kona naau, Aole loa au e hoonaueia; Aole au e popilikia ia hanauna aku ia hanauna aku.
O wí fún ara rẹ̀, “Kò sí ohun tí ó lè mì mí. Inú mi yóò máa dùn nígbà gbogbo, èmi kò sì ní ní wàhálà.”
7 Ua piha kona waha i ke amuamu, ka wahahee, a me ka hoopunipuni; Malalo ae o kona alelo ke kolohe a me ka mea lapuwale.
Ẹnu rẹ̀ kún fún ègún àti irọ́ àti ìtànjẹ; wàhálà àti ohun búburú wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.
8 Ua noho ia ma kahi hoomakaakiu o na kauhale; A i kahi nalowale i pepehi wale ai ia i ka mea hala ole; Ua haka malu aku kona mau maka i ka mea ilihune.
Ó lúgọ ní bùba nítòsí ìletò. Ò gọ níbi ìkọ̀kọ̀ láti pa aláìṣẹ̀. Ojú rẹ̀ ń ṣọ́ àwọn tálákà ní ìkọ̀kọ̀.
9 Kali malu iho la ia me he liona la iloko o kona lua: Moemoe malu ia e hopu i ka mea ilihune: Ua hoohei no oia ia ia i kona alakai ana ia ia iloko o kana upena.
Ó ba ní ní bùba bí i kìnnìún nínú pàǹtí; Ó ba ní bùba láti mú àwọn aláìní ìrànwọ́; ó mú àwọn aláìlólùrànlọ́wọ́, ó sì wọ́ wọn lọ sínú àwọ̀n rẹ̀.
10 Ua kolo iho la ia, ua hoohaahaa ia ia iho, I haule iho ka poe ilihune i kona mea ikaika.
Ó ba, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀; kí tálákà ba à le bọ́ sí ọwọ́ agbára rẹ̀.
11 Ua olelo iho la ia iloko o kona naau, Ua hoopoina ke Akua; Ua huna oia i kona maka, aole loa ia e ike mai.
Ó wí fún ara rẹ̀, “Ọlọ́run ti gbàgbé; Ó pa ojú rẹ̀ mọ́, òun kì yóò rí i láéláé.”
12 E ku mai oe, e Iehova; E hapai oe i kou lima, e ke Akua; Mai hoopoina mai i ka poe haahaa.
Dìde, Olúwa! Gbé ọwọ́ rẹ sókè, Ọlọ́run. Má ṣe gbàgbé àwọn olùpọ́njú.
13 No ke aha la ka mea ino i hoowahawaha ai i ke Akua? Ua olelo no oia iloko o kona naau, Aole oe e hoopai mai.
Èéṣe tí ènìyàn búburú ṣe ń kẹ́gàn Ọlọ́run? Èéṣe tí o fi wí nínú ọkàn ara rẹ̀, “Kò ní pè mí láti ṣe ìṣirò”?
14 Ua ike mai no oe, ua nana mai i ke kolohe a me ka huhu, I hoopai mai ia mea me kou lima; O ka mea ilihune ua waiho aku oia ia ia iho ia oe; O oe no ka mea nana ka mea makua ole i kokua mai.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni ó rí wàhálà àti ìrora; Ìwọ rò láti fi sí ọwọ́ rẹ. Tálákà fi ara rẹ̀ jì fún ọ; Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìní baba.
15 E uhai oe i ka lima o ke kanaka hewa ke kolohe; E hoopai i kona hewa a pau ia i ka nalo ia oe.
Ṣẹ́ apá àwọn ènìyàn búburú àti ènìyàn ibi; pè é láti wá ṣírò fún ìwà ìkà rẹ̀ tí a kò le è rí.
16 O Iehova, oia ke Alii mau loa: Ua make aku ko na aina e mailoko aku o kona aina.
Olúwa ń jẹ ọba láé àti láéláé; àwọn orílẹ̀-èdè yóò ṣègbé lórí ilé rẹ.
17 E Iehova, ua lohe oe i ka makemake o ka poe haahaa: E hoomakaukau ana oe i ko lakou naau, E hoolohe mai ana no kou pepeiao;
Ìwọ́ gbọ́, Olúwa, ìfẹ́ àwọn tí a ni lára; Ìwọ gbà wọ́n níyànjú, ó sì gbọ́ igbe wọn,
18 E hoopono mai i ka mea makua ole a me ka mea i hooluhihewaia, I hooluhihewa hou ole mai ke kauaka o ka honua.
láti ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní baba àti àwọn ti a ni lára, kí ọkùnrin, tí ó wà ní ayé, kí ó má ṣe dẹ́rùbà ni mọ́.

< Halelu 10 >