< Obadia 1 >

1 KA wanana a Obadia. Peneia ka Iehova ka Haku i olelo mai ai no Edoma; Ua lohe kakou i ka lohe ana mai Iehova mai, Ua hoounaia'ku ka elele iwaena o na lahuikanaka; E ku oukou iluna, a e ala ku e kakou ia ia i ke kaua.
Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
2 Aia hoi, ua hoolilo au ia oe i mea uuku iwaena o na lahuikanaka; Ua lilo oe i mea hoowahawaha loa ia.
“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
3 Ua hoopunipuni ka haaheo o kou naau ia oe, E ka mea e noho ana ma na ana o ka pohaku, He wahi kiekie kou noho ana; E olelo ana ma kou naau, Na wai la au e lawe iho ilalo i ka honua?
Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
4 Ina e hookiekie oe ia oe iho e like me ka aeto, Ina e hoonoho i kou punana iwaena o na hoku, Malaila mai e lawe iho ai au ia oe ilalo, wahi a Iehova.
Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
5 Ina i hele mai na aihue i ou la, ina he poe powa i ka po, (Nani kou lukuia!) aole anei lakou e aihue, a pau ko lakou makemake? Ina i hele mai na ohi waina i ou la, aole anei lakou e waiho aku i ke koena?
“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
6 Nani ka imiia o ka Esau! I huliia hoi kona mau wahi huna!
Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
7 O na kanaka a pau o kau berita, ua hoouna aku lakou ia oe a i ka palena; O na kanaka e kuikahi ana me oe, ua wahahee lakou ia oe, a ua lanakila lakou maluna ou; O ka poe e ai ana i kau berena, ua waiho lakou i ka hei malalo iho ou; Aohe naauao iloko ona.
Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
8 Aole anei au e luku aku i ka poe ike, mai Edoma aku ia la, wahi a Iehova, A me ka naauao mai ka mauna o Esau aku?
Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
9 A e weliweli kou poe kanaka ikaika, e Temana, I okiiak'u kela kanaka keia kanaka, mai ka mauna o Esau aku.
A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
10 No ka luku ana a no ka hana ino i kou hoahanau ia Iakoba, e uhi mai ka hilahila ia oe, A e luku loa ia'ku oe.
Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
11 I ka la i ku ai oe ma kela aoao, I ka la i lawe pio aku ai na malihini i kona ikaika, A komo ko na aina e iloko o kona mau pukapa, A hailona lakou no Ierusalema, Ua like hoi oe me kekahi o lakou.
Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
12 Aole nae i pono kou nana ana i ka la o kou hoahanau, I ka la o kona malihini ana; Aole hoi he pono kou hauoli ana maluna o na mamo a Iuda, I ka la i lukuia'i lakou; Aole pono kau olelo hookiekie ana i ka wa i pilikia'i lakou.
Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
13 Aole pono kou komo ana iloko o ka puka o ko'u poe kanaka, i ka la o ko lakou make; Aohe pono kou nana ana i ko lakou poino i ka la i make ai lakou, A me kou kau ana i kou lima maluna o kona waiwai i ka la o kona lukuia ana.
Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
14 Aohe pono kou ku ana ma ka huina alanui e oki aku i kona poe i pakele; Aohe pono kou haawi lilo ana i kona poe i koe, i ka la pilikia.
Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
15 No ka mea, ua kokoke mai ka la o Iehova maluna o na lahuikanaka a pau: Like me kau i hana aku ai, pela e hanaia mai ai oe: O kau hoopai ana, e hoihoiia mai ia maluna o kou poo.
“Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
16 No ka mea, like me oukou i inu ai maluna o ko'u mauna hoano, Pela e inu mau ai na lahuikanaka a pau; A e inu lakou, a e moni iho, A e like auanei lakou me na mea ole.
Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
17 Aka, ma ka mauna o Ziona he mea e pakele ai, a he mea laa; A e loaa i ko ka hale o Iakoba ko lakou noho ana.
Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
18 A lilo ko ka hale o Iakoba i ahi, A o ko ka hale o Iosepa i lapalapa; A o ko ka hale o Esau i opala, A e hoaa iwaena o lakou, a e hoopau ia lakou; Aohe mea e koe ana o ko ka hale o Esau; No ka mea, o Iehova ka i olelo mai.
Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
19 A e loaa i ko ke kukuluhema ka mauna o Esau, A i ko ka papu ko Pilisetia: A e lilo no lakou ka aina o Eperaima, a me ka aina o Samaria; A e lilo o Gileada no Beniamina.
Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
20 A o ka poe pio o keia poe kaua o na mamo a Iseraela, e lilo no lakou ko Kanaana a hiki i Zarepata; A o ka poe pio no Ierusalema ma Separada, e lilo no lakou na kulanakauhale o ke kukuluhema.
Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
21 A e pii mai na mea hoola ma ka mauna Ziona, e hoopai i ka mauna o Esau; A e lilo ke aupuni no Iehova.
Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

< Obadia 1 >