< Na Helu 24 >

1 A IKE iho la o Balaama, ua lealea o Iehova i ka hoomaikai aku i ka Iseraela, aole ia i hele hou aku e like mamua e imi i na kilokilo ana; aka, haliu ae la ia i kona maka ma ka waonahele.
Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.
2 Alawa ae la na maka o Balaama iluna, ike ae la i ka Iseraela e hoomoana ana ma ko lakou mau ohana; a kau mai la ka Uhane o ke Akua maluna ona.
Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
3 Hapai ae la ia i kana olelonane, i aku la, O ka wanana a Balaama a ke keiki a Beora, O ka wanana a ke kanaka i hookaakaaia kona mau maka:
ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, “Àsọtẹ́lẹ̀ tí Balaamu ọmọ Beori, àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
4 Ka wanana a ka mea i lohe i na olelo a ke Akua, A ka mea i ike i ka Mea mana ma ka hihio; E moe ana ilalo, a e kaakaa ana kona mau maka:
àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ là kedere.
5 Nani ka maikai o na halelole ou, e Iakoba! O kou mau halelewa hoi, e Iseraela!
“Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu, àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
6 E like me na awawa ko lakou palahalaha ana, E like hoi me na mahinaai ma kapa muliwai, Me na laau aloe hoi a Iehova i kanu ai, A me na laau kedera ma kapa o na wai.
“Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde, gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá, gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn, gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
7 E kahe ana ka wai mailoko ae o kona mau bakeke, A ma na wai he nui kona hua kanu; E kiekie ae hoi kona alii maluna o Agaga, A e hookiekieia'e kona aupuni.
Omi yóò sàn láti inú garawa: èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi. “Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
8 Na ke Akua ia i kai mai nei, mai Aigupita mai; Ia ia hoi ka ikaika me he reema la; E ai iho oia i na lahuikanaka i kona poe enemi, A e uhai ia i ko lakou mau iwi, E houia hoi lakou i kana mau pua.
“Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá; wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré. Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run, wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú; wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
9 Ua kukuli iho ia, ua moe iho me he lionakane la, A me ka lionawahine; nawai la ia e hoala'e? E pomaikai ka mea hoomaikai ia oe, A e poino ka mea hoino aku ia oe.
Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún, bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn? “Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
10 Ua hoaia ka inaina o Balaka ia Balaama, a pai pu na lima ona: i mai la o Balaka ia Balaama, Ua kii aku no wau ia oe no ka hoino aku i kuu poe enemi; aia hoi, eia ke kolu o kou hoomaikai wale ana aku.
Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
11 Nolaila, e holo aku oe i kou wahi: i manao iho la au e hoohanohano loa aku ia oe; aka hoi, o Iehova ka i keakea mai ia oe i loaa ole ai ka hanohano.
Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
12 Olelo mai la o Balaama ia Balaka, Aole anei au i olelo aku i ka poe elele au i hoouna at io'u la, i ka i ana aku,
Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
13 Ina e haawi mai o Balaka i ko kala a me ke gula a piha kona hale, ina aole e hiki ia'u ke hoohala i ka olelo a Iehova, e hana i ka maikai, aole hoi i ka hewa ma kuu manao iho: o ka Iehova e olelo mai ai, oia ka'u e hai aku ai?
‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?
14 Ano hoi, ke hoi aku nei au i ko'u poe kanaka: ea, e hai e aku no au ia oe i ka mea a keia poe kanaka e hana mai ai i kou poe kanaka i na la mahope.
Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
15 Hapai ae la ia i kana olelonane, i aku la, O ka wanana a Balaama ke keiki a Beora, Ka wanana a ke kanaka i hookaakaaia'e kona maka;
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Balaamu ọmọ Beori, òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
16 Ka wanana a ka mea i lohe i ka olelo a ke Akua, A ka mea ike i ka mea ikea o ka Mea kiekie, A ka mea nana i ka mea ikea o ka Mea mana loa, E moe iho ana, a e kaakaa ana kona mau maka:
ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí, tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo, tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
17 E ike auanei au ia ia, aole hoi ano, E nana auanei au ia ia, aole hoi e kokoke: E puka mai auanei he Hoku mai o Iakoba mai, E ku mai ana no hoi he Kookoo mai o Iseraela mai; A e luku aku no ia i na kihi o Moaba, A e pepehi iho ia i na keiki hoohaunaele a pau.
“Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí. Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́. Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu; yóò yọ jáde láti Israẹli. Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu, yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
18 E lilo o Edoma i wahi E noho ai, A e lilo o Seira i wahi e noho ai no kona poe enemi: A e hana ikaika no o ka Iseraela.
Wọn yóò borí Edomu; yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
19 Na Iakoba e puka mai auanei ka mea e alii ana, A e luku iho oia i ke koena o ke kulanakanhale.
Olórí yóò jáde láti Jakọbu yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
20 Nana aku la hoi oia i ka Ameleka, hai mai la ia i kana olelonane, i mai la, O Ameleka, ke pookela o na lahuikanaka, Aka o kona hope, e make mau loa no oia.
Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
21 Nana aku la hoi ia i ka Keni, hapai ae la ia i kana olelonane, i mai la, Ua paa kou wahi i noho ai, Ua kau aku oe i kou punana maluna o ka pohaku:
Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ibùgbé rẹ ní ààbò, ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
22 Aka, e laweia'ku ka Keni, ahea la E lawe pio aku o Asuria ia oe?
síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
23 Hai aku la ia i kana olelonane, i aku la, Auwe! owai la uanei ke ola i ka wa e hana mai ai ke Akua i keia?
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
24 Mai kauwahi mai o Kitima mai, na moku, A e hoopilikia lakou i ko Asuria, A e hoopilikia hoi i ka Hebera, A e luku loa ia'ku oia.
Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu; wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi, ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
25 Ku ae la o Balaama, hele aku la ia, a hoi aku la i kona wahi; a hele aku la hoi o Balaka i kona aoao.
Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.

< Na Helu 24 >