< Na Helu 20 >

1 A LAILA hele mai la ka poe mamo a Iseraela, o ke anaina kanaka a pau i ka waonahele o Zina, i ka malama mua: a noho iho la na kanaka ma Kadesa; malaila i make ai o Miriama, a ua kanuia iho la ia ma ia wahi.
Ní oṣù kìn-ín-ní, gbogbo àgbájọ ọmọ Israẹli gúnlẹ̀ sí pápá Sini, wọ́n sì dúró ní Kadeṣi. Níbẹ̀ ni Miriamu kú, wọ́n sì sin ín.
2 Aohe wai ilaila no ke anaina kanaka: a hoakoakoa ae la lakou ia lakou iho, a ku e ia Mose laua me Aarona.
Omi kò sí fún ìjọ ènìyàn, àwọn ènìyàn sì kó ara wọn jọ pọ̀ sí Mose àti Aaroni,
3 Hakaka ae la na kanaka me Mose, olelo ae la lakou penei, E aho ko makou make, i ka manawa i make ai na hoahanau o makou imua o Iehova!
wọ́n bá Mose jà wọ́n sì wí pé, “Ìbá kúkú sàn kí a kú nígbà tí àwọn arákùnrin ti kú níwájú Olúwa!
4 No ke aha hoi olua i alakai mai nei i ke anaina kanaka o Iehova iloko o keia waonahele i make ai makou me na holoholona a makou?
Kí ni ó dé tí o sì kó gbogbo ìjọ ènìyàn Olúwa wá sí aginjù yìí, kí àwa àti àwọn ẹran ọ̀sìn wa bá à kú síbí?
5 No ke aha la olua i hoohele mai nei ia makou mai Aigupita mai, e hookomo ai ia makou iloko o keia wahi ino? Aole keia he wahi no na anoano, aohe fiku, aole kumu waina, aole pomeraite, aole hoi wai e inu ai.
Kí ni ó dé tí o fi mú wa gòkè kúrò ní Ejibiti wá sí ibi búburú yìí? Ibi tí kò ní oúnjẹ tàbí igi ọ̀pọ̀tọ́, èso àjàrà tàbí pomegiranate. Bẹ́ẹ̀ ni kò sí omi tí a ó mu níhìn-ín!”
6 Hele aku la o Mose laua o Aarona mai ke alo o ke anaina kanaka aku a ka puka o ka halelewa o ke anaina, a moe iho la laua ilalo ke alo; a ikea mai la ka nani o Iehova ia laua.
Mose àti Aaroni kúrò ní ibi àpéjọ, wọ́n sì lọ dojúbolẹ̀ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahàn wọ́n.
7 Olelo mai la o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pé,
8 E lawe oe i ke kookoo, a e hoakoakoa oe i ke anaina kanaka, o oe a me Aarona kou kaikuaana, a e olelo aku olua i ka pohaku imua o na maka o lakou; a e haawi mai ia i kona wai, a e lawe mai oe i ka wai no lakou mailoko mai o ka pohaku: a pela no oe e hooinu ai i ke anaina kanaka, a me ka lakou poe holoholona.
“Mú ọ̀pá, náà kí o sì pe ìjọ àwọn ènìyàn jọ, ìwọ àti Aaroni arákùnrin rẹ, kí ẹ sọ̀rọ̀ sí àpáta náà ní ojú wọn, yóò sì tú omi rẹ̀ jáde, ìwọ ó sì fún ìjọ àti ẹran wọn mu.”
9 Lawe aku la o Mose i ke kookoo mai ke alo o Iehova aku, e like me kana i kauoha mai ai ia ia.
Báyìí ni Mose mú ọ̀pá láti iwájú Olúwa wá, gẹ́gẹ́ bí ó ti pàṣẹ fún un.
10 Houluulu ae la o Mose laua o Aarona i ke anaina kanaka imua o ka pohaku, i aku la oia ia lakou, E hoolohe mai oukou, e ka poe kipi; pono anei no maua e hookahe iho i ka wai mailoko mai o keia pohaku?
Òun àti Aaroni pe àwọn ènìyàn jọ sí ojú kan níwájú àpáta, Mose sì sọ fún wọn, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀, àwa kì yóò lè mú omi jáde láti inú àpáta yìí wá bí?”
11 Kaikai ae la o Mose i kona lima iluna, hahau iho la i ka pohaku, me kona kookoo, elua hahau ana; a kahe nui mai la ka wai: inu iho la ke anaina kanaka a me ko lakou poe holoholona.
Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ó sì fi ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ lu àpáta lẹ́ẹ̀méjì. Omi sì tú jáde, gbogbo ìjọ ènìyàn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sì mu.
12 Olelo mai la o Iehova ia Mose a me Aarona, No ko olua manaoio ole mai ia'u, e hoauo mai ia'u imua o na mamo a Iseraela, nelaila, aole olua e kai aku i keia anaina kanaka i ka aina a'u i haawi aku ai no lakou.
Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Nítorí pé ẹ̀yin kò gbà mí gbọ́ tó láti bu ọlá fún mi níwájú àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ kò ní kó àwọn ìjọ ènìyàn yìí dé ilẹ̀ tí mo fún wọn.”
13 O keia ka wai no Meriba; no ka mea, ua aaka mai na mamo a Iseraela me Iehova, a ua hoanoia oia ia lakou.
Èyí ni omi ti Meriba, níbi tí àwọn ọmọ Israẹli ti bá Olúwa jà àti ibi tí O ti fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni mímọ́ láàrín wọn.
14 Hoouna aku la o Mose i na elele mai Kadesa aku i ke alii o Edoma, Penei ka ka hoahanau ou, ka Iseraela e olelo aku nei, Ua ike no oe i ka luhi a pau i loaa ia makou;
Mose sì ránṣẹ́ láti Kadeṣi sí ọba Edomu, wí pé, “Èyí ni nǹkan tí arákùnrin rẹ Israẹli sọ, ìwọ ti mọ̀ nípa gbogbo ìnira, tí ó wá sí orí wa.
15 I ka iho ana o ko makou poe kupuna ilalo i Aigupita, a he liuliu ko makou noho ana i Aigupita; a hoopilikia mai ko Aigupita ia makou a me ko makou poe kupuna.
Àwọn baba ńlá wa sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti, a sì gbé ibẹ̀ fún ọ̀pọ̀ ọdún. Àwọn ará Ejibiti ni wá lára àti àwọn baba wa,
16 A i a wa i hea aku ai makou ia Iehova, hoolohe mai la oia i ko makou leo, a hoouna mai la i anela, a ua hoopuka mai ia makou iwaho o Aigupita: eia hoi makou ma Kadesa nei, he kulanakauhale ma ke kihi loa o kou palena.
ṣùgbọ́n nígbà tí a sọkún sí Olúwa, ó gbọ́ ẹkún wa, ó sì rán angẹli kan sí wa, ó sì mú wa jáde láti Ejibiti. “Báyìí àwa wà ní Kadeṣi, ìlú tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ.
17 Ke noi aku nei au ia oe, e ae mai oe ia makou e hele aku mawaena o kou aina: aole makou e hele mawaena o na mahinaai, aole hoi mawaena o na pawaina, aole hoi makou e inu i ka wai o na punawai; e hele no makou ma ke alaloa o ke alii, aole makou e kipa ma ka akau, aole hoi ma ka hema, a hala aku makou i na palena ou.
Jọ̀wọ́ jẹ́ kí a gba orílẹ̀-èdè rẹ kọjá, àwa kì yóò gba inú oko tàbí ọgbà àjàrà rẹ kọjá, tàbí mu omi láti inú kànga. A ó ma kọjá ní òpópónà ọba, àwa kì yóò yà sí ọ̀tún tàbí sí òsì títí àwa yóò fi kọjá ní ilẹ̀ rẹ.”
18 I mai la o Edoma ia ia, Mai hele ae oe ma o'u nei o hele aku au e ku e ia oe me ka pahikaua.
Ṣùgbọ́n Edomu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò le gba ibí kọjá; bí ẹ bá dán an wò, a ó dìde ogun sí yín, a ó sì bá yín jà pẹ̀lú idà.”
19 I aku la ka poe mamo a Iseraela ia ia, E hele no makou ma ke alaloa, a iua e inu au a me ko'u poe holoholona i kou wai, alaila e uku aku no au ia mea: e hele wale no makou ma ko makou mau wawae, aole e hana i kekahi mea e ae.
Àwọn ọmọ Israẹli dáhùn pé, “A ó gba ọ̀nà tóóró, bí àwa tàbí ẹran ọ̀sìn wa bá sì mú lára omi rẹ, a ó san owó rẹ̀. A kàn fẹ́ rìn kọjá lórí ilẹ̀ rẹ ni kò sí nǹkan kan mìíràn tí a fẹ́ ṣe.”
20 I mai la kela, Aole loa oe e hele mawaena mai. A puka mai la ko Edoma e ku e mai ia ia, me na kanaka he nui loa, a me ka lima ikaika.
Wọ́n tún dáhùn wí pé, “Ẹ kò lè kọjá.” Nígbà náà ni Edomu jáde wá láti kọjú ìjà sí wọn pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àti alágbára ọmọ-ogun.
21 Pela no o Edoma i hoole mai ai i ka haawi ana i alanui no ka Iseraela mawaena o kona palena: no ia mea, haliu ae la ka Iseraela mai ona aku la.
Nígbà tí Edomu sì kọ̀ jálẹ̀ láti jẹ́ kí wọn kọjá ní ilẹ̀ wọn, Israẹli yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
22 Hele aku la na mamo a Iseraela, o ke anaina kanaka a pau, mai Kadesa aku a hiki i ke kuahiwi o Hora.
Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì jáde láti Kadeṣi wọ́n sì wá sí orí òkè Hori.
23 Olelo mai la o Iehova ia Mose a me Aarona ma ke kuahiwi o Hora, ma ka palena aina o Edoma, i mai la,
Ní orí òkè Hori, ní ẹ̀gbẹ́ ààlà Edomu Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
24 E hui pu ia'ku o Aarona me kona poe kanaka: aole ia e komo i ka aina a'u i haawi aku ai no na mamo a Iseraela, no ka mea, ua ku e mai olua i ka'u olelo ma ka wai Meriba.
“Aaroni yóò kú. Kò ní wọ ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn ọmọ Israẹli, nítorí ẹ̀yin méjèèjì ṣe àìgbọ́ràn sí òfin mi níbi omi Meriba.
25 E lawe oe ia Aarona a me kana keiki o Eleazara, e kai aku ia laua maluna ma ko kuahiwi o Hora.
Mú Aaroni àti ọmọ rẹ̀ Eleasari lọ sí orí òkè Hori.
26 E wehe ae i ka aahu o Aarona, a e hookomo i kana keiki ia Eleazara: a e hui pu ia'ku o Aarona, a e make no ia malaila.
Bọ́ aṣọ Aaroni kí o sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, nítorí pé Aaroni yóò kú síbẹ̀.”
27 Hana iho la o Mose e like me ka Iehova i kauoha mai ai: a pii aku la laua ma ke kuahiwi o Hora imua o ke anaina kanaka a pau.
Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n lọ sí orí òkè Hori ní ojú gbogbo ìjọ ènìyàn.
28 Wehe ae la o Mose i na aahu o Aarona, a hoaahu ae la maluna o kana keiki o Eleazara: a make iho la o Aarona malaila ma kahi oi o ke kuahiwi: a iho iho la o Mose laua o Eleazara mai ke kuahiwi mai.
Mose bọ́ aṣọ Aaroni ó sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, Aaroni sì kú sí orí òkè. Nígbà náà Mose àti Eleasari sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè,
29 A ike aku la ke anaina kanaka a pau, na make o Aarona, kanikau iho la ka Iseraela a pau ia Aarona i na la he kanakolu.
nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbọ́ pé Aaroni ti kú, gbogbo ilé Israẹli ṣe ìdárò rẹ̀ fún ọgbọ̀n ọjọ́.

< Na Helu 20 >