< Na Helu 2 >
1 OLELO mai la o Iehova ia Mose a ia Aarona, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 E noho kela kanaka keia kanaka o na mamo a Iseraela ma kona hae iho, me ka hae o ka hale o ko lakou kupuna; e noho kupono ana lakou i ka halelewa o ke anaina.
“Kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn yí àgọ́ ìpàdé ká, kí wọ́n jẹ́ kí àgọ́ wọn jìnnà sí i díẹ̀, oníkálùkù lábẹ́ ọ̀págun pẹ̀lú àsíá ìdílé wọn.”
3 Ma ka aoao hikina, ma ka puka ana o ka la e noho ai ka poe no ka hae o ka Iuda hoomoana ana, ma ko lakou poe kaua: a o Nahesona ke keiki a Aminadaba, oia ka luna no na mamo a Iuda.
Ní ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ àtiyọ oòrùn: ni kí ìpín ti Juda pa ibùdó wọn sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Juda ni Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
4 A o kona poe kaua, a o na mea o lakou i heluia, he kanahikukumamaha tausani, me na haneri ken eono.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
5 A o ka poe e noho kokoke ia ia, oia ka ohana a Isakara; a o Netaneela ke keiki a Zuara, oia ka luna o na mamo a Isakara.
Ẹ̀yà Isakari ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Isakari ni Netaneli ọmọ Suari.
6 A o kona poe kaua, a o ka poe o lakou i heluia, he kanalimakumamaha tausani, me na haneri keu eha.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
7 O ka ohana hoi a Zebuluna; a o ka luna o na mamo a Zebuluna, oia o Eliaba ke keiki a Helona.
Ẹ̀yà Sebuluni ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Sebuluni ni Eliabu ọmọ Heloni.
8 A o kona poe kana, a o ka poe o lakou i heluia, he kanalimakumamahiku tausani, a me na haneri keu eha.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
9 O na mea a pau i heluia, ma kahi hoomoana o ka Iuda, hookahi ia haneri a me kanawalukumamaono tausani, a me na haneri keu eha, ma ko lakou poe kaua; o keia poe ke hele mamua.
Gbogbo àwọn tí a yàn sí ibùdó Juda, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàléláàdọ́rùn-ún ó lé irinwó. Àwọn ni yóò kọ́kọ́ ṣáájú.
10 Ma ka aoao hema ka hae o kahi hoomoana o ka Reubena, ma ko lakou poe kaua; a o ka luna o na mamo a Reubena, oia o Elizura ke keiki a Sedeura.
Ní ìhà gúúsù: ni ìpín ti Reubeni pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Reubeni ni Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
11 A o kona poe kaua, a o na mea o lakou i heluia, he kanahakumamaono tausani, a me na haneri elima.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
12 A o ka poe e noho kokoke ia ia, o ka ohana a Simeona: a o ka luna o na mamo a Simeona, oia o Selumiela ke keiki a Zurisadai.
Ẹ̀yà Simeoni ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Simoni ni Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
13 A o kona poe kaua, a o na mea o lakou i heluia, he kanalimakumamaiwa tausani, me na haneri keu ekolu.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbéje.
14 Alaila o ka ohana a Gada; a o Eliasapa ke keiki a Reuela, oia ka luna o na mamo a Gada.
Ẹ̀yà Gadi ló tẹ̀lé wọn. Olórí Gadi ni Eliasafu ọmọ Deueli.
15 A o kona poe kaua, a o na mea o lakou i heluia, he kanahakumamalima tausani me na haneri eono, a me ke kanalima.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
16 O ka poe a pau i heluia ma kahi hoomoana o ka Reubena, hookahi ia haneri me kanalimakumamakahi tausani, eha haneri a me kanalima keu, ma ko lakou poe kaua: a o lakou ke hele ma ka lua o ka huakai.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Reubeni, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá márùndínlọ́gọ́rin ó lé àádọ́talélégbèje. Àwọn ni yóò jáde sìkéjì.
17 Alaila e neenee aku ka halelowa o ke anaina, me ka poo hoomoana o na Levi, iwaenakonu o ka poe hoomoana: e like me ko lakou hoomoana ana, pela no lakou e neenee aku ai, o kela kanaka keia kanaka ma kona wahi ma ko lakou hae.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi àti àgọ́ ìpàdé yóò tẹ̀síwájú láàrín ibùdó àwọn ènìyàn, wọn yóò tẹ̀síwájú ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe pa ibùdó, olúkúlùkù láààyè rẹ̀, àti lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀.
18 Ma ka aoao komohaua ka hae o ka poe hoomoana o ka Eperaima, ma ko lakou poe kana: a o ka luna o na mamo a Eperaima, oia o Elisama ke keiki a Amihuda,
Ní ìhà ìlà-oòrùn: ni ìpín Efraimu yóò pa ibùdó rẹ̀ sí lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀. Olórí Efraimu ni Eliṣama ọmọ Ammihudu.
19 A o kona poe kaua, a me na mea o lakou i heluia, he kanaha tausani a me na haneri keu elima.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì lé ó lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
20 A e pili ia ia ka ohana a Manage: a o ka luna o na mamo a Manase, oia o Gamaliela ke keiki a Pedazura.
Ẹ̀yà Manase ni yóò tẹ̀lé wọn. Olórí Manase ni Gamalieli ọmọ Pedasuri.
21 A o kona poe kaua, a me na mea o lakou i heluia, he kanakolukumamalua tausani a me na haneri keu elua.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé igba.
22 Alaila o ka ohana a Beniamina: a o ka luna o na mamo a Beniamina, oia o Abidana ke keiki a Gideoni.
Ẹ̀yà Benjamini ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Benjamini ni Abidani ọmọ Gideoni.
23 A o kona poe kaua, a me ka poe o lakou i heluia, he kanakolukumamalima tausani a me na haneri ken eha.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
24 O ka poe a pau i heluia no kahi hoomoana o ka Eperaima, hookahi ia haneri me kumamawalu tausani me ka haneri hookahi, ma ko lakou mau poe kaua: a e hele aku hoi lakou ma ke kolu o ka huakai.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Efraimu, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnléláàádọ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún. Àwọn ni yóò jáde sìkẹ́ta.
25 Ma ka aoao akau ka hae o ka poe hoomoana o ka Dana ma ko lakou poe kaua: a o ka luna o na mamo a Dana, oia o Ahiezera ke keiki a Amisadai.
Ní ìhà àríwá: ni ìpín Dani yóò pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Dani ni Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
26 A o kona poe kaua, a o na mea o lakou i heluia, he kanaonokumamalua tausani me na haneri keu ehiku.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
27 A o ka poe hoomoana me ia, oia ka ohana a Asera: a o ka luna o na mamo a Asera, oia o Pagiela ke keiki a Okerana.
Ẹ̀yà Aṣeri ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Aṣeri ni Pagieli ọmọ Okanri.
28 O kona poe kaua, a me na mea o lakou i heluia, he kanahakumamakahi tausani a me na haneri keu elima.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
29 Alaila ka ohana a Napetali: a o ka luna o na mamo a Napetali, oia o Ahira ke keiki a Enana.
Ẹ̀yà Naftali ni yóò kàn lẹ́yìn wọn. Olórí Naftali ni Ahira ọmọ Enani.
30 O kona poe kaua, a me na mea o lakou i heluia, he kanalimakumamakolu tausani a me na haneri keu eha.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé egbèje.
31 O ka poe a pau i heluia ma kahi hoomoana o Dana, hookahi haneri me kanalimakumamahiku tausani a me na haneri keu eono: a o lakou nei ke hele mahope me ko lakou mau hae.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Dani jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gọ̀rin ó lé ẹgbẹ̀jọ. Àwọn ni yóò jáde kẹ́yìn lábẹ́ ọ̀págun wọn.
32 O keia ka poe i heluia o na mamo a Iseraela, ma ko ka hale o ko lakou poe kupuna: o na mea a pau i heluia o na wahi hoomoana, ma ko lakou mau poe kaua, he aono haneri me ke kumamakolu tausani, me na haneri keu elima a me ke kanalima.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n kà nípa ìdílé wọn. Gbogbo àwọn tó wà ní ibùdó, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, wọ́n jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
33 Aka, aole i heluia na Levi me na mamo a Iseraela; e like me ka Iehova i kauoha mai ai ia Mose.
Ṣùgbọ́n a kò ka àwọn ọmọ Lefi papọ̀ mọ́ àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
34 A hana iho la na mamo a Iseraela e like me na mea a pau a Iehova i kauoha mai ai ia Mose: pela lakou i hoomoana ai ma ko lakou mau hae, a pela hoi lakou i hele aku ai, o kela mea keia mea mamu tili o ko lakou mau ohana, e like me ko ka hale o ko lakou poe kupuna.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose, báyìí ni wọ́n ṣe pa ibùdó lábẹ́ ọ̀págun wọn, bẹ́ẹ̀ náà sì ni wọ́n ṣe jáde, oníkálùkù pẹ̀lú ẹbí àti ìdílé rẹ̀.