< Na Helu 14 >
1 HOOKIEKIE ae la ke anaina kanaka a pau i ko lakou leo, a hooho ae la; a uwe iho la na kanaka ia po.
Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
2 Ohumu ae la na mamo a pau a Iseraela ia Mose a me Aarona: i aku la ke anaina kanaka a pau ia laua, E aho ko makou make ma ka aina o Aigupita! E aho ko makou make ma keia waonahele!
Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
3 No ke aha la hoi i lawe mai nei o Iehova ia kakou i keia aina, e make i ka pahikaua, a e lilo at ka kakou mau wahine a me na keiki i i pio? E aho paha e hoi kakou i Aigupita.
Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
4 I ae la lakou i kekahi i kekahi, E hoonoho kakou i luna no kakou, a e hoi aku i Aigupita.
Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
5 Alaila moe iho la o Mose laua o Aarona ilalo ke alo imua o ke anaina kanaka a pau i akoakoa o na mamo a Iseraela.
Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
6 A o Iosua ke keiki a Nuna, a o Kaleba ke keiki a Iepune, o laua kekahi o na mea i makaikai i ka aina, haehae ae la laua i ko laua kapa.
Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
7 Olelo aku la laua i ka poe mamo a pau a Iseraela, i aku la, O ka aina a makou i kaahele ai e makaikai, he aina maikai loa ia.
Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
8 Ina i oluolu mai o Iehova ia ka kou, alaila e kai aku oia ia kakon i ua aina la, a e haawi mai hoi ia no kakou; he aina e kahe ana ka waiu a me ka meli
Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
9 Aka, mai kipi aku oukou ia Iehova, mai makau hoi i na kanaka o ka aina; no ka mea, he mea ai lakou na kakou: ua hala aku la ko lakou malu mai o lakou aku la, me kakou no hoi o Iehova; mai makau ia lakou.
Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
10 Aka. kena ae la ke anaina kanaka a pau e hailuku ia laua i ua pohaku Alaila ikea ae la ka nani o Iehova ma ka halelewa o ke anaina, imua o na mamo a pau a Iseraela.
Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
11 I mai la o Iehova ia Mose, Pehea la ka loihi o ka hoonaukiuki ana mai o keia poe kanaka ia'u? Ahea la hoi lakou e manaoio mai ai ia'u no na mea mana a pau a'u i hoike ai iwaena o lakou?
Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
12 E luku aku au ia lakou i ke ahulau, a e pai ia lakou i ka aina hooili; a e hoolilo au ia oe i lahuikanaka e oi aku ana ka nui a me ka ikaika i ko lakou.
Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
13 Olelo aku la o Mose ia Iehova, Alaila e lohe ai ko Aigupita, (no ka mea, ma kou mana kau i lawe mai ai i keia poe kanaka mawaena mai o lakou, )
Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
14 A e hai aku lakou ia i na kanaka o keia aina. Ua lohe lakou, e Iehova, o oe no mo keia poe kanaka, a ua ikeia hoi oe, e Iehova, he maka no he maka; a ua ku hoi kou ao maluna o lakou; a ua hele hoi oe imua o lakou i ko ao ma ke kia ao, a ma ke kia ahi i ka po.
Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
15 A i pepehi mai oe i keia poe kanaka e like me ke kanaka hookahi, alaila e olelo mai na lahuikanaka i lohe i kou kaulana ana, i ka i ana,
Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
16 No ka hiki ole ia Iehova ke hookomo aku i keia poe kanaka i ka aina ana i hoohiki ai no lakou, nolaila na pepehi oia ia lakou ma ka waouahele.
‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
17 Ano la, ku nonoi aku nei au ia oe, i nui ka mana o kuu Haku. e like me ka olelo au i olelo mai ai, penei,
“Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
18 Ua altonui o Iehova, a ua nui kona lokomaikai, e kala ana i ka hew a a me ka lawehala ana, aole loa hoi e hoapono wale ana mai; e hoopai ana nae i ko ka tnakua lawehala maluna o na keiki a hiki aku i ke kuakahi a me ke kualua.
‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
19 Ke noi aku nei au ia oe, e kala mai oe i ka hala o keia poe kanaka, e like me ka nui o kou lokomaikai; e like hoi me kau i kala mai ai i keia poe kanaka mai Aigupita mai, a hiki i keia manawa.
Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
20 I mai la o Iehova, Ua kala aku no wau, e like me kau i olelo mai ai.
Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
21 Aka, me au e ola nei, e hoopihaia auanei ka honua i ka nani o Iehova.
Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
22 No ka men, o kela poe kanaka a pau, ka poe i ike mai i kuu na-ni, a me na mea mana a'u i hana'i ma Aigupita, a ma ka waonahele, a he umi ko lakou aa ana mai ia'u. aole hoi i hooloho mai i kuu leo;
Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
23 Aole loa lakou e ike i ka aina a'u i hoohiki ai no ko lakou poe kupuna, aole hoi kekahi o ka poe i hoonaukiuki mai ia'u e ike aku in wahi:
ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
24 Aka, o ka'u kauwo, o Kaleha, no ka mea, he manao okoa maloko ona, a ua hahai pono mai oia ia'u, oia ka'u e hookomo ai i ka aina ana i hele aku ai; a e loaa i kana poe keiki ia aina.
Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
25 (Ua noho no ka Ameleka a me ka Kanaana ma ke awawa.) Apopo, e huli oukou, a e komo aku iloko o ka waonahele, ma ke ala e hiki ai i ke Kaiula.
Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
26 Olelo mai la o Iehova ia Mose a me Aarona, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
27 Pehea la ka loihi o ko keia anaina kanaka ino e ohumu mai ai ia'u? Ua lohe no wau i na ohumu ana a na mamo a Iseraela i ohumu mai ai ia'u.
“Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
28 E hai aku oe ia lakou, Ke i mai nei o Iehova, He oiaio, me ka oukou i olelo mai ai maloko o ko'u mau pepeiao, pela hoi ka'u e hana aku ai ia oukou.
Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
29 E hanle no auanei ko oukou kupapau ma keia waonahele; a o ka poe a pau o oukou i heluia, ma ka huiualielu okoa o oukou, mai ka iwakalua o ka makahiki a keu aku, o ka poe i ohumu mai ia'u,
Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
30 Aole loa oukou e komo aku iloko o ka aina a'u i hoohiki ai e hoonoho ia oukou ilaila; o laua wale no, o Kaleba ke keiki a Iepune, a o Iosua ke keiki a Nuna,
Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
31 Aka, o ka oukou poe keiki, na mea a oukou i olelo ai e lilo ana lakou i pio, o lakou ka'u e hookomo aku ai iloko, a e ike auanei lakou i ka aina a oukou i hoowahawaha ai.
Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
32 Aka, o oukou, e haule auanei ko oukou mau kupapau ma ka waonahele.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
33 A e aea ana ka oukou poe keiki ma ka waonahele i na makahiki he kanaha, a e halihali lakou i ko oukou moekolohe ana, a hiki i ka nalo ana o ko oukou mau kupapau maloko o ka waonahele.
Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
34 E like me ka helu ana o na la a oukou i makaikai ai i ka aina, hookahi kanaha la; o kekahi la no ka makahiki hookahi, pela oukou e lawe ai i ko oukou hewa, hookahi kanaha makahiki, a e ike auanei oukou i ko'u haalele ana ia oukou.
Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
35 Owau o Iehova ka mea i olelo, a he oiaio no, e hana aku no wau ia i keia anaina kanaka ino a pau, i ka poe i akoakoa e ku e ia'u. Ma keia waonahele lakou e hoopauia'i, a ilaila hoi e make ai lakou.
Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
36 A o na kanaka a Mose i hoouna aku ai e makaikai i ka aina, a i ka hoi ana mai, hoolilo ae la lakou i ke anaina kanaka a pau i ka ohumu ia ia, i ka lakou olelo alapahi ana i ka aina;
Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
37 O ua mau kanaka la, ka poe i olelo hoino i ka aina, make iho la lakou i ke ahnlau imua o Iehova.
Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
38 Aka, o Iosua ke keiki a Nuna, a o Kaleba ke keiki a Iepune, o laua kekahi mau mea i hele e makaikai i ka aina, ola no laua.
Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
39 Hai aku la o Mose ia mau olelo i na mamo a Iseraela; a uwe nui iho la na kanaka.
Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
40 Ala ae la lakou i kakahiaka nui, a pii ae la maluna pono o ka pun, me ka i ana, Eia no kakon, e hele aku hoi kakou i kahi a Iehova i olelo mai ai; no ka mea, ua hana hewa makou.
Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
41 Olelo aku la o Mose, No ke aha la oukou e hoohala nei i ke kauoha a Iehova? aka aole ia e hiki.
Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
42 Mai noho a pii aku oukou, aole o Iehova me oukou; o pepehiia auanei oukou imua o ko oukou poe enemi.
Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
43 No ka mea, aia no ka Ameleka a me ka Kanaana imua o oukou. a e haule auanei oukou i ka pahikana; no ka mea, ua huli ae oukou mai o Iehova aku; no ia mea, aole o Iehova me oukou.
Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
44 Aka, ua aa lakou e pii maluna pono o ka puu: aole nae i hele aku ka pahuberita o Iehova a me Mose, iwaho o kahi hoomoana.
Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
45 Alaila, iho mai la ka Ameleka a me ka Kanaana e noho ana ma ia puu, pepehi iho la ia lakou, a hoopuehu aku la a hiki i Horema.
Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.