< Na Helu 13 >

1 OLELO mai la o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 E hoouna aku oe i na kanaka e makaikai ai i ka aina o Kanaana, kahi a'u e haawi aku nei i na mamo a Iseraela: i hookahi kanaka o kela ohana a o keia ohana a na kupuna o lakou ka oukou e hoouna aku ai, he mau luna kela mea keia mea iwaena o lakou.
“Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kenaani wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Israẹli. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
3 A ma ke kauoha a Iehova i hoouna aku ai o Mose ia lakou, mai ka waonahele o Parana aku: a o ia mau kanaka a pau, he mau luna lakou no na mamo a Iseraela.
Mose sì rán wọn jáde láti aginjù Parani gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Israẹli.
4 Eia na inoa o lakou: no ka ohana o Reubena, o Samua ke keiki a Zakura.
Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubeni, Ṣammua ọmọ Sakkuri;
5 No ka ohana a Simeona, o Sapata ke keiki a Hori.
láti inú ẹ̀yà Simeoni, Ṣafati ọmọ Hori;
6 No ka ohana a Iuda, o Kaleba ke keiki a Iepune.
láti inú ẹ̀yà Juda, Kalebu ọmọ Jefunne;
7 No ka ohana a Isakara, o Igala ke keiki a Iosepa.
láti inú ẹ̀yà Isakari, Igali ọmọ Josẹfu;
8 No ka ohana a Eperaima, o Hosea ke keiki a Nuna.
láti inú ẹ̀yà Efraimu, Hosea ọmọ Nuni;
9 No ka ohana a Beniamina, o Paleti ke keiki a Rapu.
láti inú ẹ̀yà Benjamini, Palti ọmọ Rafu;
10 No ka ohana a Zebuluna, o Gadiela ke keiki a Sodi.
láti inú ẹ̀yà Sebuluni, Daddieli ọmọ Sodi;
11 No ka ohana a Iosepa, ka ohana a Manase, o Gadi ke keiki a, Susi.
láti inú ẹ̀yà Manase (ẹ̀yà Josẹfu), Gaddi ọmọ Susi;
12 No ka ohana a Dana, o Amiela ke keiki a Gemali.
láti inú ẹ̀yà Dani, Ammieli ọmọ Gemalli;
13 No ka ohana a Asera, o Setiela ke keiki a Mikaela.
láti inú ẹ̀yà Aṣeri, Seturu ọmọ Mikaeli.
14 No ka ohana a Napetali, o Nabi ke keiki a Vopesi.
láti inú ẹ̀yà Naftali, Nabi ọmọ Fofsi;
15 No ka ohana a Gada, o Geuela ke keiki a Maki.
láti inú ẹ̀yà Gadi, Geueli ọmọ Maki.
16 Oia na inoa o na kanaka a Mose i hoouna aku ai e makaikai i ka aina. A kapa aku la o Mose ia Hosea ke keiki a Nuna, o Iosua.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ènìyàn tí Mose rán láti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò. (Hosea ọmọ Nuni ni Mose sọ ní Joṣua.)
17 Hoouna aku la o Mose ia lakou e makaikai i ka aina o Kanaana, i aku la hoi ia lakou, E haele oukou ma keia aoao kukuluhema, a e pii iluna i ka mauna.
Nígbà tí Mose rán wọn lọ láti yẹ ilẹ̀ Kenaani wò, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ gba ọ̀nà gúúsù lọ títí dé àwọn ìlú olókè.
18 E nana i ke ano o ka aina, a me na kanaka e noho ana ilaila, he ikaika paha lakou, he nawaliwali paha; he hapa paha lakou, he nui loa paha;
Ẹ wò ó bí ilẹ̀ náà ti rí, bóyá àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà jẹ́ alágbára tàbí aláìlágbára, bóyá wọ́n pọ̀ tàbí wọn kéré.
19 Me ka aina hoi a lakou e noho la, he maikai paha, he ino paha; a me na kulanakauhale a lakou e noho la, ma na halelewa paha, ma na pakaua paha;
Irú ilẹ̀ wo ni wọ́n gbé? Ṣé ilẹ̀ tó dára ni àbí èyí tí kò dára? Báwo ni ìlú wọn ti rí? Ṣé ìlú olódi ni àbí èyí tí kò ní odi?
20 A me ke ano o ka aina, he momona paha, he wi paha; he laau paha ilaila, aole paha: i nui hoi ka ikaika o oukou, a e lawe mai i kekahi hua o ka aina. O ka manawa ia o ka huawaina pala mua.
Báwo ni ilẹ̀ náà ti rí? Ṣé ilẹ̀ ọlọ́ràá ni tàbí aṣálẹ̀? Ṣé igi wà níbẹ̀ àbí kò sí? E sa ipá yín láti rí i pé ẹ mú díẹ̀ nínú èso ilẹ̀ náà wá.” (Ìgbà náà sì jẹ́ àkókò àkọ́pọ́n èso àjàrà gireepu.)
21 Pii aku la lakou a makaikai ae la i ka aina, mai ka waonahele o Zina a hiki aku i Rehoba, ma ke ala e hele aku ai i Hamata.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ láti yẹ ilẹ̀ náà wò, wọ́n lọ láti aginjù Sini títí dé Rehobu lọ́nà Lebo-Hamati.
22 A pii aku la lakou ma ke kukulu hema, a hiki aku i Heberona, i kahi o Ahimana, o Sesai a me Talemai, na keiki a Anaka. (Ua hookumuia o Heberona ehiku makahiki mamua o Zoana i Aigupita.)
Wọ́n gba gúúsù lọ sí Hebroni níbi tí Ahimani, Ṣeṣai àti Talmai tí í ṣe irú-ọmọ Anaki ń gbé. (A ti kọ́ Hebroni ní ọdún méje ṣáájú Ṣoani ní Ejibiti.)
23 A hele aku lakou i ke kahawai i Esekola, a old iho la i kekahi lala me ka huiwaina hookahi, a amo mai la maluna o ka mamaka mawaena o na kanaka elua, O na pomeraite kekahi a me na fiku.
Nígbà tí wọ́n dé àfonífojì Eṣkolu, wọ́n gé ẹ̀ka kan tó ní ìdì èso àjàrà gireepu kan. Àwọn méjì sì fi ọ̀pá kan gbé e; wọ́n tún mú èso pomegiranate àti èso ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú.
24 Ua kapaia ia wahi ke kahawai o I Esekola, no ka huiwaina a na mamo a Iseraela i oki ai malaila.
Wọ́n sì sọ ibẹ̀ ní àfonífojì Eṣkolu nítorí ìdì èso gireepu tí àwọn ọmọ Israẹli gé níbẹ̀.
25 A hala na la he kanaha o ka makaikai ana i ka ama, hoi mai la lakou.
Wọ́n padà sílé lẹ́yìn ogójì ọjọ́ tí wọ́n ti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò.
26 Hele mai la lakou a hiki io Mose la a me Aarona, a me ke anaina kanaka a pau o na mamo a Iseraela, i ka waonahele o Parana, i Kadesa; a hoakaka mai la lakou ia laua, a i ke anaina kanaka a pau, a hoike mai la i ka hua o ka aina.
Wọ́n padà wá bá Mose àti Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní ijù Kadeṣi Parani. Wọ́n mú ìròyìn wá fún wọn àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn, wọ́n fi èso ilẹ̀ náà hàn wọ́n.
27 Olelo mai la lakou ia ia, i mai la, Ua hele aku makou i ka aina au i hoouna aku ai ia makou, a he oiaio no e kahe ana ka waiu a me ka meli ilaila; eia hoi ka hua o ia wahi.
Wọ́n sì fún Mose ní ìròyìn báyìí, “A lọ sí ilẹ̀ ibi tí o rán wa, lóòtítọ́ ló sì ń sàn fún wàrà àti fún oyin! Èso ibẹ̀ nìyìí.
28 Aka, ua ikaika na kanaka e noho ana ma ia aina; a na paa i na papohaku na kulanakauhale, a nui loa: eia hoi kekahi, ua ike makou i na keiki a Anaka malaila.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tó ń gbé níbẹ̀ lágbára, àwọn ìlú náà jẹ́ ìlú olódi bẹ́ẹ̀ ni ó sì tóbi púpọ̀. A tilẹ̀ rí àwọn irú-ọmọ Anaki níbẹ̀.
29 E noho ana ka Ameleka ma ka aina kukuluhema; o ka Heta, me ka Iebusa, a me ka Amora, ua noho lakou ma na mauna; a ua noho ko Kanaana ma ka moana a ma kapa o Ioredane.
Àwọn Amaleki ń gbé ní ìhà gúúsù; àwọn ará Hiti, àwọn ará Jebusi àti àwọn ará Amori ni wọ́n ń gbé ní orí òkè ilẹ̀ náà, àwọn ará Kenaani sì ń gbé ẹ̀bá òkun àti ní etí bèbè Jordani.”
30 Hoomalielie iho o Kaleba i kanaka imua o Mose, i mai la, E hele koke aku kakou, a e komo i ka aina; no ka mea, e hiki pono no ia kakou ke lanakila maluna ona.
Kalebu sì pa àwọn ènìyàn náà lẹ́nu mọ́ níwájú Mose, ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gòkè lọ lẹ́ẹ̀kan náà láti lọ gba ilẹ̀ náà, nítorí pé àwa le è gbà á.”
31 Aka, i mai la na kanaka i hele pu me ia, Aole e hiki ia kakou ke hele ku e i ua poe kanaka la; no ka mea, ua oi aku ko lakou ikaika i ko kakou.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ gòkè lọ yẹ ilẹ̀ wò sọ pé, “Àwa kò le gòkè lọ bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí nítorí pé wọ́n lágbára jù wá lọ.”
32 A lawe mai la lakou i ka olelo hoino i ka aina a lakou i makaikai aku ai i na mamo a Iseraela, i mai la, O ka aina kahi a makou i kaahele ai e makaikai aku, he aina ia e hoopau ana i na kanaka e noho ana malaila: a o na kanaka a pau a makou i ike ai malaila, he poe kanaka nunui.
Báyìí ni wọ́n ṣe mú ìròyìn búburú ti ilẹ̀ náà, tí wọ́n lọ yọ́wò wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ tí a lọ yẹ̀ wò jẹ́ ilẹ̀ tí ń run àwọn olùgbé ibẹ̀. Gbogbo àwọn ènìyàn tí a rí níbẹ̀ jẹ́ ènìyàn tó fìrìgbọ̀n tó sì síngbọnlẹ̀.
33 Malaila makou i ike ai i na kanaka nunui, i na keiki a Anaka, na ka poe kanaka nunui mai: ua like makou me na uhini i ko makou maka, a pela hoi makou imua o ko lakou maka.
A sì tún rí àwọn òmíràn (irú àwọn ọmọ Anaki) àwa sì rí bí i kòkòrò tata ní ojú ara wa, bẹ́ẹ̀ ni àwa náà sì rí ní ojú wọn.”

< Na Helu 13 >