< Na Helu 11 >

1 I KA ohumu ana a na kanaka, ua hewa ia i na pepeiao o Iehova; lohe ae la o Iehova, a hoaia kona inaina; a aku la ke ahi o Iehova iwaena o lakou, a ai aku la ma ka palena o kahi hoomoana.
Àwọn ènìyàn ń ṣe àròyé nípa wàhálà wọn sí etí ìgbọ́ Olúwa. Ìbínú Olúwa sì ru sókè nígbà tí ó gbọ́ àròyé yìí. Nígbà náà ni iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa bọ́ sí àárín wọn, ó sì run àwọn tó wà ní òpin ibùdó.
2 Kahea aku la na kanaka ia Mose, a pule aku la o Mose ia Iehova, alaila pio iho la ke ahi.
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn kígbe sí Mose, Mose sì gbàdúrà sí Olúwa iná náà sì kú.
3 Kapa aku la ia i ka inoa o ia wahi, o Tabera; no ka mea, ua ai mai ke ahi o Iehova iwaena o lakou.
Wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Tabera nítorí pé, iná láti ọ̀dọ̀ Olúwa jó láàrín wọn.
4 A o ka poe e i hui pu ia mai me lakou, kuko nui aku lakou: a uwe hou iho la na mamo a Iseraela, i ae la, Nawai la e haawi mai i ka io na kakou e ai ai?
Àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí tó wà láàrín àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú ọkàn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn fi ìtara béèrè fún oúnjẹ mìíràn, àwọn ọmọ Israẹli náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún wí pé, “Bí i pé kí á rí ẹran jẹ báyìí!
5 Ke hoomanao nei makou i ka ia a makou i ai wale iho ai ma Aigupita; i na kaukama me na ipuaimaka, i na leka me na akaakai, a me na galika.
Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Ejibiti, apálà, bàrà, ewébẹ̀, àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn.
6 Ano hoi, ua maloo loa ko kakou naau; aohe mea e ae, o ka mane wale no imua o ko kakou maka.
Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi manna nìkan tí a rí yìí!”
7 Ua like ka mane me ka hua koriana, a o kona helehelena ua like ia me ka deliuma.
Manna náà dàbí èso korianderi, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
8 A hele ae la na kanaka, a hoiliili iho la, a wawahi iho la maloko o na mea wili; a i ole ia, kui iho la lakou iloko o na ipukui, kahu iho la a moa ma na pa, a hana iho la ia i popo. A o ka hoao ana o ia mea, ua like me ka hoao ana i ka aila hou.
Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
9 Aia haule iho ka hau maluna o kahi hoomoana i ka po, haule pu no hoi ka mane me ia.
Nígbà tí ìrì bá ẹ̀ sí ibùdó lórí ni manna náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
10 Alaila lohe ae la o Mose i na kanaka e uwe ana me ka lakou mau ohana, o kela kanaka keia kanaka ma ka puka o kona halelewa: hoa nui ia ka inaina o Iehova; a ukiuki iho la hoi o Mose.
Mose sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mose sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
11 I aku la o Mose ia Iehova, No ke aha la oe i hoopilikia mai ai i kau kauwa? no ke aha hoi i loaa ole mai ai ia'u ka lokomaikaiia mai imua o kou maka, i kau mai ai oe maluna o'u i ke kaumaha o keia poe kanaka a pau?
Mose sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá ìránṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
12 Na'u no anei i hoohapai i keia poe kanaka a pau? Ua hoohanau no anei au ia lakou, i olelo mai ai oe ia'u, E hiipoi oe ia lakou ma kou umauma, e like me ka hali aua a ka makua hanai i ke keiki omo waiu, a hiki aku i ka aina au i hoohiki ai i na kupuna o lakou?
Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn baba ńlá wọn.
13 Nohea la e loaa mai ai ia'u ka io e haawi aku ai na keia poe kanaka a pau? No ka mea, ke uwe mai uei lakou ia'u, me ka olelo mai, E haawi mai oe na makou i io, e ai iho ai makou.
Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sọkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’
14 Aole e hiki ia'u, owau wale no ke halihali i keia poe kanaka a pau; no ka mea, he mea kaumaha loa ia no'u.
Èmi nìkan kò lè dágbé wàhálà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹrù wọn ti wúwo jù fún mi.
15 A i hana mai oe pela ia'u, ea, ke nonoi aku nei au ia oe, e pepehi mai oe ia'u a make, ina paha i loaa ia'u ka lokomaikaiia mai imua o kou mau maka, a ike ole au i kuu popilikia ana.
Bí ó bá sì ṣe pé báyìí ni ìwọ ó ṣe máa ṣe fún mi, kúkú pa mí báyìí, tí mo bá ti bá ojúrere rẹ pàdé—kí ojú mi má ba à rí ìparun mi.”
16 Olelo mai la o Iehova ia Mose, E houluulu mai oe io'u nei i na kanaka he kanahiku o ka poe kahiko o ka Iseraela, i na mea au e ike ai he poe kahiko o na kanaka, a he poe luna hoi no lakou; a e kai mai oe ia lakou ma ka halelewa o ke anaina i ku ai lakou me oe ilaila.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú àádọ́rin ọkùnrin nínú àwọn àgbàgbà àwọn ọmọ Israẹli, àwọn tí o mọ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí àti olóyè láàrín àwọn ènìyàn wá sínú àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n lé dúró níwájú mi.
17 A e iho no au ilalo, e kamailio pu me oe ilaila; a e lawe au i ko ka Uhane maluna ou, a e kau aku maluna o lakou; a e amo pu lakou me oe i ke kaumaha o na kanaka, i halihali ole ai oe, o oe wale no, ia mea.
Èmi ó sì sọ̀kalẹ̀ wá bá yín sọ̀rọ̀ níbẹ̀. Èmi ó sì mú díẹ̀ nínú agbára Ẹ̀mí tí ń bẹ lára rẹ láti fi sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru àjàgà àwọn ènìyàn kí ó má ṣe pé ìwọ nìkan ni ó o máa ru àjàgà náà.
18 E olelo aku hoi oe i na kanaka, E huikala oukou ia oukou iho no ka la apopo, a e ai auanei oukou i ka io; no ka mea, ua uwe aku oukou maloko o na pepeiao o Iehova, ua i aku, Nawai la e haawi mai i ka io na kakou e ai ai? Ua pono kakou ma Aigupita: no ia mea, e haawi mai no o Iehova i io na oukou, a e ai iho hoi oukou.
“Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ ní ìmúrasílẹ̀ fún ọ̀la, ẹ ó sì jẹ ẹran. Nítorí pé Olúwa ti gbọ́ igbe ẹkún yín, èyí tí ẹ sun pé, “Ìbá ṣe pé a lè rí ẹran jẹ ni! Ó sàn fún wa ní Ejibiti jù báyìí lọ!” Nítorí náà ni Olúwa yóò fi fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.
19 E ai no oukou, aole i ka la hookahi, aole i na la elua, aole hoi i na la elima, aole no hoi i na la he umi, aole no hoi i na la he iwakalua:
Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,
20 Aka, he malama okoa, a puka mai ia iwaho ma ko oukou mau puka ihu, a hoopailua oukou ia: no ka mea, ua hoowahawaha oukou ia Iehova e noho ana iwaena o oukou, a ua uwe oukou imua ona, me ka i ana ae, No ke aha la kakou i hele mai ai mai Aigupita mai?
ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan, títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín, nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrín yín, ẹ sì ti sọkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Ejibiti gan an?”’”
21 I aku la o Mose, O ka poe kanaka a'u e noho nei iwaena, he eono haneri tausani lakou, ka poe hele wawae, a ke olelo mai nei oe, E haawi no au i io na lakou e ai ai a pau ka malama okoa.
Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Mo wà láàrín ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn ni ìrìnkiri, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’
22 E kaluaia anei na pua hipa a me na pua bipi na lakou, i mea e maona ai lakou? E hoiliiliia paha anei na ia a pau o ke kai na lakou, i mea e maona ai lakou?
Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”
23 Olelo mai la o Iehova ia Mose, Ua hoopokoleia anei ko Iehova lima? E ike auanei oe i ka hookoia ana paha o ka'u olelo ia oe, a i ka ole ana paha.
Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”
24 Hele aku la o Mose, a hai aku la i na kanaka i na olelo a Iehova, a houluulu ae la ia i na kanaka, he kanahiku o ka poe lunakahiko no na kanaka, a hooku ae la ia lakou a puni ka halelewa.
Mose sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin àgbàgbà Israẹli dúró yí àgọ́ ká.
25 Iho mai la o Iehova ma ke ao, a olelo mai la ia ia, a. lawe ae la ia i ko ka Uhane maluna o Mose, a haawi aku la i ka poe lunakahiko he kanahiku: a i ka manawa i kau iho ai ka Uhane maluna o lakou, alaila wanana mai la lakou, aole i hooki.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọ̀ sánmọ̀ ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lára Ẹ̀mí tó wà lára Mose sí ara àwọn àádọ́rin àgbàgbà náà, Ó sì ṣẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò sọtẹ́lẹ̀ mọ́.
26 Elua kanaka i koe aku ma kahi hoomoana, o Eledada, ka inoa o kekahi, a o Medada ka inoa o kekahi. Kau mai la ka Uhane maluna o laua: no ka poe laua i kakauia, aole nae laua i hele aku i ka halelewa, a wanana mai la laua ma kahi hoomoana.
Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Eldadi àti Medadi kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin àgbàgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ síbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.
27 A holo mai la kekahi kanaka opiopio, a hai mai la ia Mose, i mai la, Ke wanana mai la o Eledada laua o Medada ma kahi hoomoana.
Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mose pé, “Eldadi àti Medadi ń sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”
28 Pane mai la o Iosua ke keiki a Nuna, ke kauwa a Mose, he kanaka opiopio ona, i mai la, E kuu haku, e Mose, e papa aku oe ia laua.
Joṣua ọmọ Nuni tí í ṣe ìránṣẹ́ Mose, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mose olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”
29 I aku la o Mose ia ia, Ke huwa nei anei oe no'u? ke ake nei au e lilo ko Iehova poe kanaka a pau i poe kaula, a e kau mai o Iehova i kona Uhane maluna o lakou!
Mose sì wí fún un pé, “Àbí ìwọ ń jowú nítorí mi? Ìbá ti wù mí tó, kí gbogbo àwọn ènìyàn Olúwa jẹ́ wòlíì, kí Olúwa sì fi Ẹ̀mí rẹ̀ sí wọn lára!”
30 Hoi mai la o Mose i kahi hoomoana, oia a me ka poe lunakahiko o ka Iseraela.
Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli yìí sì padà sínú àgọ́.
31 A huai mai la ka makani mai o Iehova mai, a hoopuka mai la i na selu mai ka moana mai, a hoohaule iho la ia lakou ma kahi hoomoana, e like me kekahi la hele ma keia aoao, a me kela aoao, a puni i kahi hoomoana, elua paha kubita maluna o ka honua.
Afẹ́fẹ́ sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì kó àparò wá láti inú Òkun. Ó sì dà wọ́n káàkiri gbogbo ibùdó ní ìwọ̀n gíga ẹsẹ̀ bàtà mẹ́ta sórí ilẹ̀, bí ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ kan ní gbogbo àyíká.
32 Ku ae la na kanaka iluna ia la a po, ia po a ao, a ia la aku a po; ohi iho la lakou i na selu: a o ka mea hoiliili hapa, he umi na homera kana i hoiliili ai, a kaulai aku la lakou ia mea no lakou iho a puni kahi hoomoana.
Ní gbogbo ọjọ́ náà àti òru, títí dé ọjọ́ kejì ni àwọn ènìyàn fi ń kó àparò yìí, ẹni tó kó kéré jùlọ kó ìwọ̀n homeri mẹ́wàá, wọ́n sì ṣà wọ́n sílẹ̀ fún ara wọn yí gbogbo ibùdó.
33 Aia iwaena o ko lakou mau niho ka io, aole ia i nauia, aa mai la ka inaina o Iehova i na kanaka, a pepehi iho la o Iehova i na kanaka, he ahulau nui loa.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrín eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn.
34 A kapa iho la oia i ka inoa o ia wahi, o Kiberotahataava; no ka mea, malaila i kanu ai lakou i na kanaka kuko.
Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kibirotu-Hattaafa nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúwà oúnjẹ sí.
35 Hele aku la na kanaka mai Kiberotahataava aku a hiki i Hazerota, a noho iho la lakou i Hazerota.
Àwọn ènìyàn yòókù sì gbéra láti Kibirotu-Hattaafa lọ pa ibùdó sí Haserotu wọ́n sì dúró níbẹ̀.

< Na Helu 11 >