< Oihanakahuna 7 >

1 EIA hoi ke kanawai o ka mohaihala: he hoano loa ia.
“‘Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà fún rírú ẹbọ ẹ̀bi, tí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
2 Ma kahi e pepehi ai lakou i ka mohaikuni, malaila no e pepehi ai lakou i ka mohaihala, a e pipi i ke koko ona maluna o ke kuahu a puni.
Níbi tí wọn ti ń pa ẹran ẹbọ sísun ni kí ẹ ti pa ẹran ẹbọ ẹ̀bi, kí ẹ sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yí pẹpẹ náà ká.
3 A e mohai aku oia i kona kaikea a pau; o ka huelo, a me ka nikiniki maluna o ka naau,
Gbogbo ọ̀rá rẹ̀ ni kí ẹ sun, ọ̀rá ìrù rẹ̀ àti ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú rẹ̀.
4 A o na puupaa elua, a me ke konahua maluna o laua, ka mea ma ka puhaka, a me ka aa o ke au ma ke akepaa, me na puupaa, oia kana e lawe ai:
Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ó wà lẹ́bàá ìhà rẹ̀, àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ pẹ̀lú àwọn kíndìnrín.
5 A e kuni aku ke kahuna ia mau mea, maluna o ke kuahu, he mohai kanmahaia ma ke ahi ia Iehova; he mohaihala ia.
Àlùfáà yóò sun wọ́n lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa. Ẹbọ ẹ̀bi ni.
6 A e ai na kane a pau iwaena o na kahuna ia mea; e aiia ma kahi hoano; he mea hoano loa ia.
Gbogbo ọkùnrin ní ìdílé àlùfáà ló lè jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́, ó jẹ́ mímọ́ jùlọ.
7 E like me ka mohailawehala, pela no ka mohaihala, he kanawai hookahi no ia mau mea; e lilo no ia i ke kahuna, nana ia e hoolilo i kalahala.
“‘Òfin yìí kan náà ló wà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ ẹ̀bi: méjèèjì jẹ́ tí àlùfáà, tó fi wọ́n ṣe ètùtù.
8 A o ke kahuna nana i mohai aku i ka mohaikuni o kekahi kanaka, e lilo nona ka ili o ka mohaikuni ana i mohai ai.
Àlùfáà tó rú ẹbọ sísun fún ẹnikẹ́ni le è mú awọ ẹran ìrúbọ náà.
9 A o kamohaiai apau i moa i ka umu, a i moa i ko paparai, a me ke pa, e lilo no ia na ke kahuna nana ia i mohai aku.
Gbogbo ẹbọ ohun jíjẹ tí a bá yan lórí ààrò, àti gbogbo èyí tí a yan nínú apẹ, àti nínú àwopẹ̀tẹ́, ni kí ó jẹ́ ti àlùfáà tí ó rú ẹbọ náà.
10 A o na mohaiai a pau i huiia me ka aila, a maloo, e lilo na na keiki a pau a Aarona e like ka kekahi me ka kekahi.
Bẹ́ẹ̀ náà ni ẹbọ ohun jíjẹ yálà a fi òróró pò ó tàbí èyí tó jẹ́ gbígbẹ, wọ́n jẹ́ ti gbogbo ọmọ Aaroni.
11 Eia hoi ke kanawai o ka alaila o na mohaihoomalu ana e mohai aku ai ia Iehova.
“‘Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà fún ọrẹ àlàáfíà tí ẹnikẹ́ni bá gbé wá síwájú Olúwa.
12 A ma e mohai oia ia i mea e hoomaikai ai, alaila, e mohai aku oia me ka alana hoomaikai i na popopalaoa hn ole i huiia me ka aila, a me na papapalaoa hu ole i hamoia me ka aila, a me na popopalaoa i huiia me ka aila, no ka palaoa wali i paraiia.
“‘Bí ẹni náà bá gbé e wá gẹ́gẹ́ bí àfihàn ọkàn ọpẹ́, pẹ̀lú ẹbọ ọpẹ́ yìí, ó gbọdọ̀ mú àkàrà aláìwú tí a fi òróró pò wá àti àkàrà aláìwú fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a dà òróró sí àti àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára tí a fi òróró pò ṣe.
13 A he mea e ae kana e mohaiai he mohai nana, o ka berena hu me ka alana hoomaikai no kana mau mohaihoomalu.
Pẹ̀lú ọrẹ àlàáfíà rẹ̀, kí ó tún mú àkàrà wíwú wá fún ọpẹ́,
14 A noloko o ia mea e mohai aku ai ia i hookahi no ka mohai okoa, i mohai hoali ia Iehova; a e lilo ia na ke kahuna nana i pipi i ke koko o na mohaihoomalu.
kí ó mú ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú oríṣìíríṣìí ọrẹ àlàáfíà rẹ wá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn fún Olúwa, ó jẹ́ tí àlùfáà tí ó wọ́n ẹ̀jẹ̀ ọrẹ àlàáfíà.
15 A o ka io o ka alana, o kana mau mohaihoomalu no ka hoomaikai, e aiia ia i ka la i mohaiia'i ia; aole oia e hookoe i kauwahi a kakahiaka.
Ẹran ọrẹ àlàáfíà ti ọpẹ́ yìí ni wọ́n gbọdọ̀ jẹ ní ọjọ́ gan an tí wọ́n rú ẹbọ, kò gbọdọ̀ ṣẹ́ ẹran kankan kù di àárọ̀ ọjọ́ kejì.
16 Aka, ina he mea hoohiki paha, a he mohai haawi wale, ka alana o kona mohai, e aiia ia i ka la i mohai aku ai oia i kana mohai; a ia la ae, aiia'i kolaila koena.
“‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ó mú ọrẹ wá, nítorí ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ tàbí kí ó jẹ́ ọrẹ àtinúwá, wọn yóò jẹ ẹbọ náà ní ọjọ́ tí wọ́n rú ẹbọ yìí, ṣùgbọ́n wọ́n lè jẹ èyí tó ṣẹ́kù ní ọjọ́ kejì.
17 Aka o ke koena o ka io o ka alana, i ke kolu o ka la, e hoopauia ia i ke ahi.
Gbogbo ẹran tó bá ṣẹ́kù di ọjọ́ kẹta ní ẹ gbọdọ̀ sun.
18 A ina e aiia kauwahi o ka io o ka alana o kana mau mohaihoomalu, i ke kolu o ka la, aole ia e maliuia mai, aole hoi e heluia ia na ka mea nana ia e mohai aku; e lilo ia i mea e hoowahawahaia, a o ka mea nana e ai ia mea, o kau maluna ona kona hewa.
Bí ẹ bá jẹ ọ̀kankan nínú ẹran ọrẹ àlàáfíà ní ọjọ́ kẹta, kò ni jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà. A kò ní í kà á sí fún ẹni tó rú ẹbọ náà, nítorí pé ó jẹ́ àìmọ́, ẹnikẹ́ni tó bá sì jẹ ẹ́, ni a ó di ẹ̀bi rẹ̀ rù.
19 A o ka io i pili i ka mea maemae ole, aole ia e aiia, e hoopauia oia i ke ahi. A o ka io hoi, e ai ka poe maemae a pau i ka io.
“‘Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran tí ó bá ti kan ohun tí a kà sí àìmọ́, sísun ni kí ẹ sun ún. Ẹnikẹ́ni tí a ti kà sí mímọ́ le è jẹ nínú ẹran tí ó kù.
20 Aka o ka mea nana e ai i ka io o ka alana o na mohaihoomalu, na mea o Iehova, e kau ana kona haumia maluna ona, e okiia'ku ia mai kona poe kanaka aku.
Ṣùgbọ́n bí ẹni tí kò mọ́ bá jẹ́ ẹran ọrẹ àlàáfíà tí ó jẹ́ tí Olúwa, a ó gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
21 A o ke kanaka nana e hoopa aku i ka mea haumia, i ka haumia paha o ke kanaka, a i ka holoholona haumia, a i kekahi mea haumia e hoowahawahaia, a e ai hoi i ka io o ka alana o na mohaihoomalu, na mea o Iehova, e okiia'ku oia mai kona poe kanaka aku.
Bí ẹnikẹ́ni bá fọwọ́ kan ohun aláìmọ́ yálà ohun àìmọ́ ti ènìyàn, ẹranko aláìmọ́, ohun àìmọ́ yówù kí ó jẹ́ tàbí ohunkóhun tí ó jẹ́ ìríra, tí ó sì tún jẹ́ ẹran ọrẹ àlàáfíà tó jẹ́ ti Olúwa, a ó gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ.’”
22 Olelo mai la hoi o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pé,
23 E olelo aku oe i na mamo a Iseraela, penei, Mai ai oukou i ke kaikea o ka bipi kauo, a o ka hipa, a o ke kao.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ má ṣe jẹ ọ̀rá màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́.
24 A o ke kaikea o ka holoholona make wale, a o ke kaikea o ka mea i haehaeia e na holoholona, e pono ia i ka kela mea keia mea e ae, aole loa hoi oukou e ai ia mea.
Ẹ lè lo ọ̀rá ẹran tó kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí tí ẹranko igbó pa, fún nǹkan mìíràn, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ́.
25 A o ka mea nana e ai i ko kaikea o ka holoholona a na kanaka i kaumaha ai i ka mohai ma ke ahi ia Iehova, o ka mea i ai ia mea, oia ke okiia'ku mai kona poo kanaka aku.
Ẹnikẹ́ni tó bá jẹ ọ̀rá ẹran tí a fi rú ẹbọ sísun sí Olúwa ni ẹ gbọdọ̀ gé kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
26 Aole hoi oukou e ai i ko koko, o ke koko o ka manu, a o ka holoholona, iloko o kahi o ko oukou mau hale.
Ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ tàbí ẹran ní gbogbo ibi tí ẹ bá ń gbé.
27 O ke kanaka i ai i ke koko, oia ke okiia'ku mai kona poe kanaka aku.
Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ ẹ̀jẹ̀, a ó gé ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.’”
28 Olelo mai la hoi o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pé,
29 E olelo aku oe i na mamo a Iseraela, penei, O ka mea mohai i ka alana o kana mau mohaihoomalu ia Iehova, e lawe mai oia i kana mohai ia Iehova noloko o ka alana o kana mau mohaihoomalu.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹnikẹ́ni tó bá mú ọrẹ àlàáfíà wá fún Olúwa.
30 Na kona mau lima no e lawe mai i na mohai o Iehova i kaumahaia ma ke ahi, o ke kaikea me ka umauma, oia kana e lawe mai ai, i hooluliia ka umauma i mohaihoali ma ke alo o Iehova.
Pẹ̀lú ọwọ́ ara rẹ̀ ni kí ó fi mú ọrẹ tí a fi iná sun wá fún Olúwa, kí ó mú ọ̀rá àti igẹ̀, kí ó sì fi igẹ̀ yìí níwájú Olúwa bí ọrẹ fífì.
31 A e kuni ke kahuna i ke kai kea maluna o ke kuahu; a e lilo ka umauma na Aaroua a me kana mau keiki.
Àlùfáà yóò sun ọ̀rá náà lórí pẹpẹ ṣùgbọ́n igẹ̀ ẹran náà jẹ́ ti Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀,
32 A o ka uha mua akau, oia ka oukou e haawi aku ai i ke kahuna i mohaihoali, noloko o na alana o na mohaihoomalu a oukou.
kí ẹ fún àlùfáà ní itan ọ̀tún lára ọrẹ àlàáfíà yín gẹ́gẹ́ bí ìpín tiyín fún àlùfáà.
33 O kekahi o ka Aarona mau keiki nana e mohai aku i ke koko o na mohaihoomalu a me ke kaikea, e lilo nana ka nha mua akau i kuleana nona.
Ọmọ Aaroni ẹni tí ó rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ àti ọ̀rá ọrẹ àlàáfíà ni kí ó ni itan ọ̀tún gẹ́gẹ́ bí ìpín tirẹ̀.
34 No ka mea, o ka umauma luli, a me ka uha hoali, oia ka'u i lawe ai mai na mamo a Iseraela, noluna mai hoi o na alana o ka lakou mau mohaihoomalu, a na haawi hoi aa ia mau mea ia Aarona ke kahuna, a i kana mau keiki; he kanawai mau iwaena o na mamo a Iseraela,
Nínú ọrẹ àlàáfíà àwọn ọmọ Israẹli, mo ti ya igẹ̀ tí a fi àti itan tí ẹ mú wá sọ́tọ̀ fún Aaroni àlùfáà àti àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní gbogbo ìgbà láti ọ̀dọ̀ ara Israẹli.’”
35 Oia hoi ko ka poni ana o Aarona, a me ko ka pom ana o kana mau keiki noloko mai o na mohai o Iehova i kanmahaia ma ke ahi, i ka la i haawi ai oia ia lakou e lawelawe imua o Iehova ma ka oihanakahuna;
Èyí ni ìpín tí a yà sọ́tọ̀ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ nínú ẹbọ tí a finá sun sí Olúwa lọ́jọ́ tí wọ́n mú wọn wá láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
36 O ka mea a Iehova i kanoha mai ai e haawiia na lakou ko na mamo a Iseraela, i ka la i poni ai oia ia lakou, he kanawai mau no ko lakou mau hanauna.
Lọ́jọ́ tí a fi òróró yàn wọ́n, ni Olúwa ti pa á láṣẹ pé kí àwọn ọmọ Israẹli máa fún wọn ní àwọn nǹkan wọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ìgbà gbogbo fún àwọn ìran tó ń bọ̀.
37 Oia ka kanawai o ka mohaikuni, o ka mohaiai, a o ka mohailawehala, a me ka mohaihala, a o na mohai poni, a me ka alana o na mohaihoomalu;
Nítorí náà, àwọn nǹkan wọ̀nyí jẹ́ ìlànà fún ẹbọ sísun, ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, ẹbọ ẹ̀bi, ìfinijoyè àlùfáà àti ẹbọ àlàáfíà
38 Ka mea a Iehova i kanoha mai ai ia Mose ma ka mauna Sinai, i ka la i kanoha mai ai oia i na mamo a Iseraela e kanmaha lakou i ko lakou mau mohai ia Iehova, ma ka waonahele o Sinai.
èyí tí Olúwa fún Mose lórí òkè Sinai lọ́jọ́ tí Olúwa pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọ́n máa mú ọrẹ wọn wá fún Olúwa ni ijù Sinai.

< Oihanakahuna 7 >