< Oihanakahuna 4 >

1 OLELO mai la hoi o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 E olelo aku oe i na mamo a Iseraela, penei, Ina no ka ike ole e hana hewa kekahi uhane i kekahi kauoha a Iehova, i ka mea pono ole ke hana, a e hana hewa aku i kekahi o ia mau mea:
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ láìmọ̀, tí ó ṣe ohun tí kò yẹ kó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa.
3 Ina e hana hewa ke kahuna i poniia i hewa ai na kanaka: alaila e lawe mai oia no ka hewa ana i hana'i, i ka bipikane opiopio kina ole ia Iehova i mohailawehala.
“‘Bí àlùfáà tí a fi òróró yàn bá ṣẹ̀, tí ó sì mú ẹ̀bi wá sórí àwọn ènìyàn, ó gbọdọ̀ mú ọmọ akọ màlúù tí kò lábùkù wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀.
4 A e lawe mai ia i ka bipikane i ka puka o ka halelewa o ke anaina imua o Iehova; a e kau i kona lima ma ke poo o ka bipikane, a e pepehi iho i ka bipikane ma ke alo o Iehova.
Kí ó mú ọ̀dọ́ màlúù wá síwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á níwájú Olúwa.
5 A e lalau iho ke kahuna i poniia i ke koko o ka bipikane, a e lawe mai ia i ka puka o ka halelewa.
Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, kí ó sì gbé e lọ sínú àgọ́ ìpàdé.
6 A e hoo ke kahuna i kona manamana lima iloko e ke koko, a e pipi i kauwahi o ke koko, i ehiku ka pipi ana ma ke alo o Iehova, mamua o ka paku o ke keenakapu.
Kí ó ti ìka bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọ́n díẹ̀ nínú rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa, níwájú aṣọ títa ibi mímọ́.
7 A e kau ke kahuna i kauwahi o ke koko ma na pepeiaohao o ke kuahu mea ala ono, ma ke alo o Iehova, ka mea maloko o ka halelewa o ke anaina; a e ninini iho i ke koko a pau o ka bipikane, malalo o ke kuahu mohaikuni, ka mea ma ka puka o ka halelewa o ke anaina.
Àlùfáà yóò tún mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tùràrí tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Kí ó da gbogbo ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù tókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
8 A e lawe nolaila mai i ke kaikea a pau o ka bipikane, i mohailawehala; o ka makaupena e uhi ana i ka naau a me ka nikiniki a pau ma ka naau,
Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá tí ń bẹ nínú akọ màlúù ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú àti gbogbo ohun tó so mọ́ wọn.
9 O na puupaa hoi elua a me ke konahua maluna iho o laua, ka mea ma na puhaka, a me ka aa o ke au ma ke akepaa, me na puupaa, oia kana e lawe aku ai;
Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá wọn tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ pẹ̀lú kíndìnrín.
10 Me ia i laweia'e mai luna ae o ka alana o na mohaihoomalu; a e kuni iho ke kahuna ia mau mea ma ke kuahu mohaikuni.
Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń yọ ọ̀rá kúrò lára màlúù tí a fi rú ẹbọ àlàáfíà; àlùfáà yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ ẹbọ sísun.
11 A o ka ili o ka bipikane, a me kona io a pau, me kona poo, a me kona mau wawae, a me kona naau, a me kona lepo;
Ṣùgbọ́n awọ màlúù àti gbogbo ara rẹ̀, àti ẹsẹ̀, gbogbo nǹkan inú àti ìgbẹ́ rẹ̀.
12 O ka bipikane hoi a pau, oia kana e lawe aku ai iwaho o kahi e hoomoana'i, i kahi maemae, kahi i nininiia'i ka lehu, a e hoopau iho ia ia maluna o ka wahie me ke ahi; ma kahi i nininiia'i ka lehu e kuniia'i ia.
Èyí túmọ̀ sí pé gbogbo ìyókù akọ màlúù náà ni kí ẹ gbé jáde síta lẹ́yìn ibùdó sí ibi tí a sọ di mímọ́ níbi tí à ń da eérú sí, kí ẹ sì sun wọ́n lórí iná igi, níbi eérú tí a kójọ.
13 A ina e hana hewa ke anaina a pau o Iseraela, no ka ike ole, a i hunaia ia i na maka o ka ahakanaka, a ua hana i kekahi o na kauoha a Iehova, i ka mea pono ole ke hana, a ua hewa;
“‘Bí gbogbo àpapọ̀ ènìyàn Israẹli bá ṣèèṣì ṣẹ̀, tí wọ́n sì ṣe ohun tí kò yẹ kí wọ́n ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àpapọ̀ ènìyàn náà kò mọ̀ sí ọ̀rọ̀ náà, wọ́n jẹ̀bi.
14 A i ka wa e ikeia'i ka hewa a lakou i hana aku ai ia ia, alaila e mohai iho ke anaina i ka bipikane opiopio, no ia hewa, a e lawe mai ia ia i ke alo o ke anaina.
Nígbà tí wọ́n bá mọ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn yóò mú akọ màlúù wá sí àgọ́ ìpàdé gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
15 A e kau na lunakahiko o ke anaina i ko lakou mau lima maluna o ke poo o ka bipikane, imua i ke alo o Iehova; a e pepehi i na bipikane la imua i ke alo o Iehova.
Kí àwọn àgbàgbà ìjọ Israẹli gbé ọwọ́ lórí akọ ọmọ màlúù náà níwájú Olúwa.
16 A e lawe mai ke kahuna i poniia i ke koko o ka bipikane i ka halelewa o ke anaina.
Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn sì mú díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ akọ ọmọ màlúù náà wá sínú àgọ́ ìpàdé.
17 A e hoo iho ke kahuna i kona manamana lima i kauwahi o ke koko, a e pipi aku ia, i ehiku ka pipi ana, ma ke alo o Iehova, imua o ka paku.
Kí ó ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọn ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa níbi aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà.
18 A e kau aku oia i kauwahi o ke koko ma na pepeiaohao o ke kuahu, ka mea ma ke alo o Iehova, ka mea iloko o ka halelewa o ke anaina, a e ninini aku i ke koko a pau malalo o ke kuahu mohaikuni, ka mea ma ka puka o ka halelewa o ke anaina.
Kí ó sì mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó dà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
19 A e lawe oia i ke kaikea a pau mai ona aku, a e kuni iho ma ke kuahu.
Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá kúrò lára rẹ̀, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ.
20 A e hana hoi oia i ka bipikane, me ia i hana aku ai i ka bipikane i mohailawehala, pela no ia e hana'i i keia; a e hana ke kahuna i kala hala no lakou, a e kalaia mai ko lakou hewa.
Kí ó sì ṣe akọ ọmọ màlúù yìí gẹ́gẹ́ bí ó ṣe ṣe akọ màlúù tó wà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ṣe ètùtù fún wọn, á ó sì dáríjì wọ́n.
21 A e lawe aku oia i ka bipikane mawaho o kahi e hoomoana'i, a e puhi ia ia, me ia i puhi aku ai i ka bipikane mua; he mohailawehala ia no ke anaina.
Lẹ́yìn náà ni yóò sun màlúù yìí lẹ́yìn ibùdó, yóò sì sun ún gẹ́gẹ́ bó ṣe sun màlúù àkọ́kọ́. Èyí ni ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli.
22 Aia hana hewa ke'lii, a no ka ike ole i hana aku ai i kekahi o na kauoha a Iehova kona Akua, i ka mea pono ole ke hana, a na hewa ia;
“‘Bí olórí kan bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ kí ó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó jẹ̀bi.
23 A ina i loaa ia ia kona hewa ana i hana'i; e lawe mai no oia i kana mohai he keikikao, he kane kina ole.
Nígbà tí a bá sì sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú akọ ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ rẹ̀.
24 A e kau ae i kona lima maluna o ke poo o ke kao, a e pepehi ia ia ma kahi i pepehi ai lakou i ka mohaikuni imua o Iehova; he mohailawehala ia.
Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ náà, kí ó sì pa á níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun níwájú Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
25 A e lawe ke kahuna i kauwahi o ke koko o ka mohailawehala me kona manamana lima, a e kau aku hoi ia ma na pepeiaohao o ke kuahu mohaikuni, a e ninini aku i kona koko malalo o ke kuahu mohaikuni.
Lẹ́yìn èyí, kí àlùfáà ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ẹ̀jẹ̀ yòókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
26 A e kuni iho oia i kona kaikea a pau maiuna o ke kuahu, e like me ke kaikea o ka alana o na mohaihoomalu; a e hana ke kahuna i ke kalahala no kona hewa, a e kalaia kona hewa.
Kí ó sun gbogbo ọ̀rá rẹ̀ lórí pẹpẹ bí ó ṣe sun ọ̀rá ọrẹ àlàáfíà. Báyìí ní àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin náà, a ó sì dáríjì í.
27 A ina e hana hewa no ka ike ole kekahi o na kanaka i kana hana ana i kekahi o na kauoha a Iehova, i ka mea pono ole ke hana, a ua hewa ia:
“‘Bí ènìyàn nínú àwọn ará ìlú bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, ó jẹ̀bi.
28 A ina e loaa ia ia kona hewa ana i hana'i; alaila e lawe mai no oia i kana mohai, he keikikao, he wahine kina ole, no kona hewa ana i hana'i.
Nígbà tí a bá sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú abo ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
29 A e kau ae oia i kona lima maluna o ke poo o ka mohailawehala, a e pepeni i ka mohailawehala ma kahi o ka mohaikuni.
Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó sì pa á níbi ẹbọ sísun.
30 A e lawe ke kahuna i kauwahi o kona koko me kona manamana lima, a e kau ae ma na pepeiaohao o ke kuahu mohaikuni, a e ninini aku i kona koko a pau malalo o ke kuahu.
Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ́ ẹ̀jẹ̀ náà, yóò fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
31 A e lawe aku oia i kona kaikea a pau, e like me ke kaikea i laweia ku ai mai ka alana o na mohaihoomalu; a e kuni iho ke kahuna ia mea ma ke kuahu i mea ala ono ia Iehova; a e hana ke kahuna i ke kalahala nona, a e kalaia kona hewa.
Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá ẹran náà gẹ́gẹ́ bó ṣe yọ ọ̀rá ẹran fún ọrẹ àlàáfíà. Kí àlùfáà sì sun ọ̀rá yìí lórí pẹpẹ bí òórùn dídùn sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, a ó sì dáríjì í.
32 A ina i lawe mai oia i ke keikihipa i mohailawehala, e lawe mai hoi oia ia ia he wahine kina ole.
“‘Bí ó bá mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, kí ó mú abo tí kò lábùkù.
33 A e kau oia i kona lima ma ke poo o ka mohailawehala, a e pepehi ia ia i mohailawehala ma kahi i pepehi ai lakou i ka mohaikuni.
Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun.
34 A e lawe ke kahuna i kauwahi o ke koko o ka mohailawehala me kona manamana lima, a e kau ae ma na pepeiaohao o ke kuahu mohaikuni, a e ninini aku i kona koko a pau malalo o ke kuahu.
Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, yóò sì fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, yóò sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ.
35 A e lawe aku oia i kena kaikea a pau, me ke kaikea o ke keikihipa i laweta'ku ai mai ka alana aku o na mohaihoomalu; a e kuni iho ke kahuna ia ma ke kuahu, e like me na mohai i kaumahaia ma ke ahi ia Iehova: a e hana ke kahuna i ke kalahala nona, no kona hewa ana i hana'i, a e kalaia mai ia.
Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá rẹ̀ bó ti yọ ọ̀rá lára ọ̀dọ́-àgùntàn ọrẹ àlàáfíà, àlùfáà yóò sì sun ún ní orí pẹpẹ, lórí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀, a ó sì dáríjì í.

< Oihanakahuna 4 >