< Lunakanawai 6 >

1 HANA hewa iho la na mamo a Iseraela imua o Iehova, a haawi ae la o Iehova ia lakou i ka lima o ko Midiana, i ehiku makahiki.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 Ikaika loa iho la ka lima o ko Midiana maluna o ka Iseraela; a hana ae la ka poe mamo a Iseraela i na lua no lakou, mai na maka aku o ko Midiana, aia ma na mauna, a i na ana hoi, a me na puukaua.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 A i ka manawa i lulu ai ka Iseraela, alaila, pii mai la ko Midiana, a me ka Amaleka, a me ka poe noho ma ka hikina, hele ku e mai la lakou.
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 A hoomoana ku e mai la, a hoopau iho la i na mea kupu o ka honua, a hiki aku i Gaza, aole i waiho i kekahi mea ola na ka Iseraela, aole i pa hipa, aole i ka bipi, aole i ka hoki.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Pii mai la lakou me ko lakou holoholona, a me ko lakou mau halelewa, hele mai lakou, e like me na uhini ka nui loa; o lakou a me ko lakou poe kamelo, he poe mea helu ole ia; a komo lakou i ka aina, e luku iho.
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 Hune loa iho la ka Iseraela, no ko Midiana, a hea aku la na mamo a Iseraela ia Iehova.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 A i ka wa i hea aku ai na mamo a Iseraela ia Iehova no ko Midiana,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 Alaila, hoouna mai o Iehova i kekahi kanaka, he kaula, i mai la ia ia lakou, Penei ka olelo ana mai a Iehova, ke Akua o ka Iseraela, Na'u no oukou i lawe mai nei, mai Aigupita mai, a hoopuka mai ia oukou, mai loko mai o ka halehooluhi;
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 Hoopakele ae au ia oukou, mai ka lima ae o ko Aigupita, a mai ka lima aku o ka poe a pau i hooluhihewa mai ia oukou, a kipaku aku la au ia lakou, mai ko oukou alo aku, a haawi aku la au i ko lakou aina no oukou.
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 I aku la au ia oukou, Owau no o Iehova, o ko oukou Akua. Mai makau oukou i na'kua o ka Amora, na mea nona ka aina, a oukou e noho ai. Aka, aole oukou i hoolohe i ko'u leo.
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 Hele mai la ka anela o Iehova, noho iho la malalo iho o kekahi laau oka, ma Opera no Ioasa, he kanaka no ko Abiezera. E hahi ana kana keiki o Gideona i ka huapalaoa, ma kahi kaomi waina, i nalo i ko Midiana.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 Ikea aku la ka anela o ka Haku e ia, i mai la ia ia, Eia pu no me oe o Iehova, e ke kanaka koa loa.
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 I aku la o Gideona ia ia, e kuu Haku e, ina o Iehova kekahi pu me makou, no ke aha la makou i loohia i keia mau mea a pau? Auhea kana mau hana mana nui, a ko makou poe makua i hai mai ai ia makou, i ka i ana mai, Aole anei i lawe mai o Iehova ia kakou, mai Aigupita mai? Aka, ua haalele mai o Iehova ia kakou, a ua haawi ia kakou iloko o na lima o ko Midiana.
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 Nana mai la o Iehova ia ia, i mai la, Ma keia mana ou, e hele ai oe, a e hoola no oe i ka Iseraela mai ka lima ae o ko Midiana. Aole anei au i hoouna aku ia oe?
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 I aku la keia ia ia, E kuu Haku, Pehea la wau e hoola'i i ka Iseraela? He nawaliwali ko'u hanauna i ka Manase a pau; a ua liilii au iloko o ka hale o ko'u makua.
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 I mai la o Iehova ia ia, Owau pu kekahi me oe, a e luku aku oe i ko Midiana, e like me ke kanaka hookahi.
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 I aku la keia ia ia, Ina i loaa ia'u ka lokomaikaiia mai imua ou, e haawi mai oe i hoailona no kou kamailio ana mai ia'u.
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 Ke noi aku nei au ia oe, Mai hele aku oe, a hiki mai au i ou la, a lawe mai i ko'u mohai makana, a waiho imua ou. I mai la kela, E kakali no wau, a hoi hou mai oe.
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Hele aku la o Gideona iloko, a hoomakaukau iho la i keiki kao, a i palaoa hu ole, i hookahi epa; a waiho iho la i ka io iloko o ka hinai, a o ke kai, waiho iho la ia maloko o ka ipu, a lawe ae la ia, io na la malalo o Ka laau oka, a haawi aku la.
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 I mai la ka anela o ke Akua ia ia, E lawe oe i ka io, a i ka palaoa hu ole, a e waiho maluna o keia pohaku, a e ninini iho i ke kai. A hana iho la ia pela.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Alaila, o aku la ka anela o Iehova i ka welau o ke kookoo, ma kona lima, a hoopa iho la i ka io, a me ka palaoa hu ole; a pii ae la ke ahi, mai loko ae o ka pohaku, a hoopau ae la i ka io, a me ka palaoa hu ole. Alaila, hele aku la ka anela o ka Haku, mai kona alo aku.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 A ike maopopo ae la o Gideona, he anela ia no Iehova, i iho la o Gideona, Auwe, e ka Haku, e Iehova e! no ka mea, ua ike au i kekahi anela o Iehova, he maka no he maka.
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 I mai la o Iehova ia ia, Aloha oe. Mai makou oe, aole oe e make.
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 Alaila hana iho la o Gideona i kuahu malaila, no Iehova, a kapa aku la oia ia mea, o Iehova-aloha. Aia no ia i keia la, ma Opera, no ka Abiezera.
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 Ia po no, olelo mai o Iehova ia ia, E kii oe i bipi opiopio, i ka bipi a kou makuakane, a me kekahi bipi ehiku makahiki, a e hoohiolo i ka lele o Baala, a kou makuakane, a e kua ilalo i ke kii o Asetarota e ku kokoke ana me ia;
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 A e hana oe i kuahu no Iehova, no kou Akua, me ka hoonohonoho pono, maluna o keia wahi paa; a e lawe oe i ka lua o na bipi, a e kaumaha aku i mohai kuni, me ka wahie o ua kii o Asetarota la, au e kua'i.
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 Alaila lawe ae la o Gideona, i umi kanaka o kona poe kauwa, a hana iho la e like me ka Iehova i kauoha mai ai ia ia. Eia kekahi, no kona makau ana i ko ka hale o kona makua, a i na kanaka o ke kulanakauhale, aole ia i hana i ke ao, aka, hana no ia i ka po.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 A i ke ala ana o na kanaka o ke kulanakauhale i kakahiaka nui, aia hoi, na hoohioloia ka lele o Baala, a ua kuaia ke kii o Asetarota e kokoke ana, a na kanmahaia ka lua o ka bipi maluna o ke kuahu i hanaia.
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 I ae la kekahi i kekahi, Nawai la i hana i keia mea? Imi lakou a ninau hoi; alaila, haiia mai la, Na Gideona, ke keiki a Ioasa, i hana i keia mea.
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Alaila olelo aku la na kanaka o ke kulanakauhale ia Ioasa, E lawe mai oe i kau keikikane iwaho, i make ia; no ka mea, ua hoohiolo oia i ke kuahu o Baala, a ua kua oia ilalo i ke kii o Asetarota e kokoke ana me ia.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 Olelo aku la o Ioasa i na kanaka a pau i ku e mai ia ia, E hakaka anei oukou mamuli o Baala? E hoola anei oukou ia ia? O ka mea e hakaka mamuli ona, e make ia, i keia kakahiaka. Ina he akua ia, e hakaka oia mamuli ona iho, no ka hoohiolo ana o kekahi i kona lele.
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 Nolaila kapa aku la oia ia ia i kela la, o i Ierubaala, i ae la, Na Baala e hakaka me ia, no ka mea, na hoohiolo oia i kona kuahu.
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Alaila akoakoa mai la ko Midiana a pau, a me ka Ameleka, a me ka poe noho ma ka hikina, hele ae la, a hoomoana iho la ma ka papu o Iezereela.
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 Uhi mai la ka Uhane o Iehova maluna o Gideona, a puhi iho la ia i ka pu, a akoakoa mai la ka Abiezera mamuli ona.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 A hoouna aku la ia i na luna i ka Manase a pau, a akoakoa mai la lakou mamuli ona; a hoouna aku la oia i na luna i ka Asera, a i ka Zebuluna, a i ka Napetali, a pii mai la lakou e halawai me ia poe.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 I aku la o Gideona ia Iehova, Ina e hook mai oe i ka Iseraela ma ko'u lima, e like me kau i olelo mai ai,
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 E halii au i huluhulu ma kahi e hehi ai i ka palaoa; a ina he hau ma ka huluhulu wale no, a e maloo ka honua e a pau, alaila, e ike pono an, e hoola no oe i ka Iseraela ma ko'u lima, e like me kau i olelo mai ai.
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 Eia hoi, i kona ala ana i kakahiaka ae, kaomi iho la oia i ka huluhulu, a uwi ae la i ke hau o ka huluhulu, a piha ka bola i ka wai.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 I aku la o Gideona i ke Akua, Mai wela mai kou huhu ia'u, a e olelo aku au i keia wale no; e ae mai oe ia'u i hookahi o'u hoao hou ana me ka huluhulu. Ke nonoi aku nei au ia oe, i maloo ma ka huluhulu wale no, a i hau hoi ma ka honua a pau.
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 Ia po, hana mai ke Akua pela: na maloo ma ka huluhulu wale no, he hau no ma ka honua a pau.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.

< Lunakanawai 6 >