< Lunakanawai 5 >
1 I A la, mele aku la o Debora laua o Baraka, ke keiki a Abinoama, i ka i ana,
Nígbà náà ni Debora àti Baraki ọmọ Abinoamu kọ orin ní ọjọ́ náà wí pé,
2 No ke alakai koa ana o na'lii iloko o ka Iseraela, No ka hooikaika nui ana o na kanaka, E hoomaikai ia Iehova.
“Nítorí bí àwọn olórí ti síwájú ní Israẹli, nítorí bi àwọn ènìyàn ti fi tọkàntọkàn wa, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa!
3 E hoolohe mai, e na'lii, E haliu mai i pepeiao, e na mea nani; Owau, ia Iehova no wau e mele aku ai: E oli aku au ia Iehova i ke Akua o ka Iseraela.
“Ẹ gbọ́ ẹ̀yin ọba! Ẹ fetí yín sílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ-aládé! Èmi yóò kọrin sí Olúwa, èmi yóò kọrin ìyìn sí Olúwa: Ọlọ́run Israẹli.
4 E Iehova, i kou puka ana iwaho o Seira, I kou hele ana aku, mai ka papu aku o Edoma, Naue ae la ka honua, kulu ka lani, Nakulukulu no hoi na ao i ka wai.
“Olúwa nígbà tí o jáde kúrò ní Seiri, nígbà tí ìwọ ń yan jáde wá láti pápá Edomu, ilẹ̀ mì tìtì, àwọn ọ̀run sì kán sílẹ̀, àní àwọsánmọ̀ pẹ̀lú kàn omi sílẹ̀.
5 Hehee iho la na mauna imua o Iehova, O Sinai nei imua o Iehova, ke Akua o ka Iseraela.
Àwọn òkè ńlá wárìrì ní iwájú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Sinai ní iwájú Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
6 I na la o Samegara, ke keiki a Anata, I na la o Iaela, oki loa iho la na huakai hele, O ka poe i hele i ke alanui, hele lakou ma na ala malu
“Ní ọjọ́ Ṣamgari ọmọ Anati, ní ọjọ́ Jaeli, àwọn ọ̀nà òpópó dá; àwọn arìnrìn-àjò sì ń gba ọ̀nà ìkọ̀kọ̀.
7 Oki iho la na luna, Oki lakou iloko o ka Iseraela, A ku iluna au, o Debora nei, Ku mai la au, he makuwahine iloko o ka Iseraela.
Àwọn olórí tán ní Israẹli, wọ́n tán, títí èmi Debora fi dìde bí ìyá ní Israẹli.
8 Olioli lakou i na'kua hou, Alaila, he kaua ma na puka o ka pa; Ua ikea anei ka palekaua, a me ka pololu, I waena o na kanaha tausani o ka Iseraela?
Wọ́n ti yan ọlọ́run tuntun, nígbà náà ni ogun wà ní ibodè a ha rí asà tàbí ọ̀kọ̀ kan láàrín ọ̀kẹ́ méjì ní Israẹli bí.
9 Aia no ko'u naau me na luna o ka Iseraela, Me ka poe i hooikaika wale iwaena o na kanaka. E hoomaikai ia Iehova.
Àyà mi fà sí àwọn aláṣẹ Israẹli àwọn tí wọ́n yọ̀ǹda ara wọn tinútinú láàrín àwọn ènìyàn. Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa!
10 E, ka poe holo ma na hoki keokeo, Ka poe noho e hooponopono ana, Na mea hele ma na alanui, E noonoo oukou.
“Ẹ kéde rẹ̀: ẹ̀yin tí ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ funfun, ẹ̀yin tí ń jókòó lórí ẹní dáradára, àti ẹ̀yin tí ó ń rìn ní ọ̀nà. Ní ọ̀nà jíjìn sí
11 Me ka uwalaau ole o ka poe e puunaue ana i ka waiwai pio ma na holowaawai, Ilaila, e hookani lakou i na lanakila ana o Iehova; Na lanakila ana o kona poe luna maloko o ka Iseraela: Alaila, e iho no na kanaka o Iehova, i na puka o ka pa.
ariwo àwọn tafàtafà, ní ibi tí a gbé ń fa omi. Níbẹ̀ ni wọ́n gbé ń sọ ti iṣẹ́ òdodo Olúwa, àní iṣẹ́ òdodo ìjọba rẹ̀ ní Israẹli. “Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Olúwa sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibodè.
12 E ala, e ala, e Debora, E ala, e ala, e oli i ka oli: E ku mai, e Baraka, e alakai pio aku i kou poe pio, e ke keiki a Abinoama.
‘Jí, jí, Debora! Jí, jí, kọ orin dìde! Dìde ìwọ Baraki! Kó àwọn ìgbèkùn rẹ ní ìgbèkùn ìwọ ọmọ Abinoamu.’
13 O ka mea i pakele, ua hoolanakila mai kela ia ia maluna o na mea kiekie o kanaka: Ua hoolanakila mai o Iehova ia ia, maluna o ka poe koa.
“Nígbà náà ni àwọn tókù sọ̀kalẹ̀ àwọn ọlọ́lá lọ; àwọn ènìyàn Olúwa tọ̀ mí wá pẹ̀lú àwọn alágbára.
14 Mawaena mai o Eperaima, ke kumu i ku e i ko Ameleka; Mahope ou, e Beniamina, maloko o kou poe kanaka; Mai Makira mai i iho mai ai na luna, A mai Zebuluna mai ka poe i paa ai ka ihe o ka alihikaua.
Àwọn kan jáde wá láti Efraimu, àwọn tí gbòǹgbò wọn wà ní Amaleki; Benjamini wà pẹ̀lú àwọn tí ó tẹ̀lé ọ. Láti Makiri ni àwọn aláṣẹ ti sọ̀kalẹ̀ wá, láti Sebuluni ni àwọn ẹni tí ń mú ọ̀pá oyè lọ́wọ́.
15 Me Debora no na'lii o Isakara, O Isakara no, a pela no o Baraka. Ma kona wawae ia i hoounaia'ku ai i ke awawa. Ma na kahawai o Reubena, nui loa ka noonoo ana o ka naau.
Àwọn ọmọ-aládé Isakari wá pẹ̀lú Debora; bí Isakari ti ṣe olóòtítọ́ sí Baraki, wọ́n fi ẹsẹ̀ súré tẹ̀lé wọn lọ sí àfonífojì náà. Ní ipadò Reubeni ni ìgbèrò púpọ̀ wà.
16 No ke aha la oe i noho ai ma na pa holoholona, E hoolohe aku i ka uwe ana o na hipa? Ma na kahawai o Reubena, nui loa ka huli ana o ka naau.
Èéṣe tí ìwọ fi dúró pẹ́ láàrín agbo àgùntàn láti máa gbọ́ fèrè olùṣọ́-àgùntàn? Ní ipadò Reubeni ni ìgbèrò púpọ̀ wà.
17 Noho aku la ko Gileada mao aku o Ioredane. No ke aha la i noho ai ka Dana ma na moku? Noho no ka Asera ma kahakai, Ma kona awa lulu kona noho ana.
Gileadi dúró ní òkè odò Jordani. Èéṣe tí Dani fi dúró nínú ọkọ̀ ojú omi? Aṣeri jókòó ní etí bèbè Òkun, ó sì ń gbé èbúté rẹ̀.
18 He poe kanaka ka Zebuluna, i hoowahawaha i ko lakou ola i ka make, O ka Napetali kekahi, ma na puu o ke kula.
Àwọn ènìyàn Sebuluni fi ẹ̀mí wọn wéwu ikú; bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn Naftali ní ibi gíga pápá.
19 Hele mai na'lii, a kaua, Alaila, kaua na'lii o Kanaana Ma Taanaka, ma na wai o Megido; Aole lakou i lawe i ke kala i mea waiwai.
“Àwọn ọba wá, wọ́n sì jà; àwọn ọba Kenaani jà ní Taanaki ní etí odo Megido, ṣùgbọ́n wọn kò sì gba èrè owó.
20 Kaua mai ko ka lani, Kaua mai na hoku ma ko lakou kuamoo, ia Sisera.
Àwọn ìràwọ̀ já láti ojú ọ̀run wá láti inú ipa ọ̀nà wọn ni wọ́n bá Sisera jà.
21 Na ka muliwai o Kisona lakou i lawe aku, O ka muliwai kahiko, ka muliwai o Kisona. E kuu uhane, ua hele oe me ka ikaika nui.
Odò Kiṣoni gbá wọn lọ, odò ìgbàanì, odò Kiṣoni. Máa yan lọ, ìwọ ọkàn mi, nínú agbára!
22 Alaila, hehi iho na manea o na lio, No ka wikiwiki, ka wikiwiki o ko lakou alii.
Nígbà náà ni pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin ki ilẹ̀, nítorí eré sísá, eré sísá àwọn alágbára wọn.
23 E hoino aku ia Meroza, Wahi a ka anela o Iehova, Me ka hoino nui e hoiuo ai i ka poe i noho ilaila; No ka mea, aole lakou i hele e kokua mamuli o Iehova, E kokua ia Iehova imua o ka poe ikaika,
‘Ẹ fi Merosi bú,’ ni angẹli Olúwa wí. ‘Ẹ fi àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ìbú kíkorò, nítorí wọn kò wá sí ìrànlọ́wọ́ Olúwa, láti dojúkọ àwọn alágbára.’
24 Mamua o na wahine, e pomaikai ana o Iaela, Ka wahine a Hebera no ko Kena; E pomaikai ana ia mamua o na wahine iloko o na halelewa.
“Ìbùkún ni fún Jaeli, aya Heberi ará Keni ju àwọn obìnrin lọ, ìbùkún ni fún un ju àwọn obìnrin tí ń gbé nínú àgọ́.
25 Nonoi mai o [Sisera] i ka wai, Haawi aku oia i ka waiu; O ka waiu paa kana i lawe mai ai ma ka ipu nani.
Ó béèrè omi, ó fún un ní wàrà; ó mú òrí-àmọ́ tọ̀ ọ́ wá nínú àwo iyebíye tí ó yẹ fún àwọn ọlọ́lá.
26 Kau aku la oia i kona lima ma ke kui, O kona lima akau hoi ma ka hamare o ka mea paahana. Hahau ae la ia Sisera, hahau io no i kona poo, Kui aku la oia, a hou aku no i kona maha.
Ó na ọwọ́ rẹ̀ mú ìṣó àgọ́, ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ mú òòlù awọ gbẹ́nàgbẹ́nà, òòlù náà ni ó sì fi lu Sisera, ó gbá a mọ́ ọn ní orí, ó sì gun, ó sì kàn ẹ̀bátí rẹ̀ mọ́lẹ̀ ṣinṣin.
27 Mawaena o kona mau wawae ia i kulou ai, Hina no ia a moe iho la ilalo; Mawaena o kona mau wawae ia i kulou ai, a hina iho la; Ma kahi ana i kulou ai, malaila ia i hina make ai.
Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ó wólẹ̀, ó ṣubú; ó dùbúlẹ̀. Ó wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ṣubú níbi tí ó gbé ń wólẹ̀; níbẹ̀ náà ni ó ṣubú kú sí.
28 Ma ka puka makani i hakapono aku ai ka makuwahine o Sisera, Ma ka puka olu oia i hea aku ai, No ke aha la i hookaulua kona kaakaua ke hele mai? Ua lohi na pokaka o kona mau kaakaua i ke aha?
“Ìyá Sisera yọjú láti ojú fèrèsé, ó sì kígbe, ó kígbe ní ojú fèrèsé ọlọ́nà pé, ‘Èéṣe tí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ fi pẹ́ bẹ́ẹ̀ láti dé? Èéṣe tí ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ fi dúró lẹ́yìn?’
29 I mai la na'lii wahine akamai, Nana no i hai mai ia ia iho;
Àwọn amòye obìnrin rẹ̀ dá a lóhùn; àní òun náà pẹ̀lú ti dá ara rẹ̀ lóhùn pé,
30 Aole anei i loaa ia lakou? Aole anei lakou i puunaue i ka waiwai pio? Pakahi, papalua paha na ke kane ke kaikamahine? No Sisera ka waiwai pio onionio, Ka waiwai pio onionio i humuia, Ka mea i humu onionio ia no na a-i o ka poe lanakila?
‘Wọn kò ha ń wa kiri, wọn kò ha ti pín ìkógun bi: ọmọbìnrin kan tàbí méjì fún ọkùnrin kan, fún Sisera ìkógun aṣọ aláràbarà, ìkógun aṣọ aláràbarà àti ọlọ́nà, àwọn aṣọ ọlọ́nà iyebíye fún ọrùn mi, gbogbo èyí tí a kó ní ogun?’
31 Pela e make ai kou poe enemi a pau, e Iehova, Aka, o ka poe aloha ia oe, e like ae lakou me ka la e puka ana ma kona ikaika. Hoomaha iho la ka aina, i hookahi kanaha makahiki.
“Bẹ́ẹ̀ ni kí ó jẹ́ kí gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kí ó ṣègbé Olúwa! Ṣùgbọ́n jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ọ ràn bí oòrùn, nígbà tí ó bá yọ nínú agbára rẹ̀.” Ilẹ̀ náà sì sinmi ní ogójì ọdún.