< Lunakanawai 19 >

1 I A manawa, aohe alii ma ka Iseraela, a e noho ana kekahi Levi ma kekahi aoao o ka mauna o Eperaima, lawe ia i haiawahine nana, noloko mai o Betelehemaiuda.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì Israẹli kò ní ọba. Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Lefi tí ń gbé ibi tí ó sá pamọ́ nínú àwọn agbègbè òkè Efraimu, mú àlè kan láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda.
2 Moe kolohe ku e mai la kana haiawahine ia ia, a hele aku, mai ona aku la, a i ka hale o kona makuakane, ma Betelehemaiuda, a malaila no ia i na malama eha.
Ṣùgbọ́n àlè rẹ̀ náà sì ṣe panṣágà sí i, òun fi sílẹ̀, ó sì padà lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu ti Juda, ó sì wà ní ibẹ̀ ní ìwọ̀n oṣù mẹ́rin,
3 Ku ae la kana kane a hahai aku la ia ia, e olelo lokomaikai aku ia ia, a e hoihoi mai ia ia. Me ia pu no kana kauwa, a me na hoki elua. Hookomo aku la oia ia ia i ka hale o kona makuakane. A ike mai la ka makuakane o ua wahine la ia ia, olioli iho la oia, i ka halawai ana me ia.
ọkọ rẹ̀ lọ sí ibẹ̀ láti rọ̀ ọ́ pé kí ó padà sí ọ̀dọ̀ òun. Nígbà tí ó ń lọ ó mú ìránṣẹ́ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì lọ́wọ́, obìnrin náà mú un wọ inú ilé baba rẹ̀ lọ, nígbà tí baba obìnrin náà rí i ó fi tayọ̀tayọ̀ gbà á.
4 Kaohi ae la kona makuahonowaikane ia ia, o ka makuakane hoi o ua wahine la; a noho pu iho la oia me ia, i na la ekolu; a ai uo lakou, a inu, a moe iho la malaila.
Àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà rọ̀ ọ́, ó sì borí rẹ̀ láti dá a dúró fún ìgbà díẹ̀, òun sì dúró fún ọjọ́ mẹ́ta, ó ń jẹ, ó ń mu, ó sì ń sùn níbẹ̀.
5 A hiki i ka ha o ka la, i ko lakou ala ana i kakahiaka nui, ku mai la ia e hele. I mai la ka makuakane o ka wahine i kana hunonakane, E hooluolu i kou naau me kahi berena iki, a mahope iho, e hele aku olua.
Ní ọjọ́ kẹrin, wọ́n dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù òun sì múra láti padà lọ, ṣùgbọ́n baba ọmọbìnrin náà wí fún àna rẹ̀ pé, “Fi ohun jíjẹ díẹ̀ gbé inú ró nígbà náà kí ìwọ máa lọ.”
6 Noho no laua, ai iho la, a inu pu hoi laua; no ka mea, ua olelo mai ka makuakane o ua wahine la i kela kanaka, E lealea mai oe i ka noho i keia po, a e hooluolu i kou naau.
Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jókòó láti jọ jẹun àti láti jọ mu. Lẹ́yìn èyí ni baba ọmọbìnrin wí pé, “Jọ̀wọ́ dúró ní alẹ́ yìí kí o sì gbádùn ara rẹ.”
7 A i ke ala ana o ke kanaka e hele, koi mai la kona makuahonowaikane ia ia; nolaila, noho iho la ia ia po.
Nígbà tí ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, baba ìyàwó rẹ̀ rọ̀ ọ́, torí náà ó sùn níbẹ̀ ní alẹ́ ọjọ́ náà.
8 I ka lima o ka la, ala ae la ia i kakahiaka nui, e hele. I mai la ka makuakane o ka wahine, E hooluolu paha oe i kou naau. Kakali iho la laua a auwi ae ka la, a ai iho la laua.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ karùn-ún nígbà tí ó dìde láti lọ, baba ọmọbìnrin wí pé, “Fi oúnjẹ gbé ara ró. Dúró de ọ̀sán!” Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jọ jẹun.
9 A i ke ku ana o ke kanaka e hele, oia a me kana wahine, a me kana kauwa, alaila, olelo mai kona makuahonowaikane ia ia, o ka makuakane hoi o ua wahine la, Aia hoi, ua auwi ae ka la, ke noi aku nei au ia oe, e noho hou i keia po, kokoke po ka la, ea, e moe maanei i lealea kou naau; a apopo e hele oe i kakahiaka nui, a hoi aku i kou halelewa.
Nígbà tí ọkùnrin náà, pẹ̀lú àlè àti ìránṣẹ́ rẹ̀, dìde láti máa lọ, àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà ní, “Wò ó ilẹ̀ ti ń ṣú lọ, dúró níbí, ọjọ́ ti lọ. Dúró kí o sì gbádùn ara rẹ. Ìwọ lè jí ní àárọ̀ kùtùkùtù ọ̀la kí ìwọ sì máa lọ ilé.”
10 Aole i ae mai ua kanaka la e moe ia po, aka, ku ae la ia a hele aku la, a hiki ma ke ala o Iebusa, oia hoi o Ierusalema; aia no me ia pu na hoki elua, i paa i na noho lio, a o kana wahine kekahi me ia.
Ṣùgbọ́n nítorí pé òun kò fẹ́ dúró mọ́ níbẹ̀ ní òru náà ọkùnrin náà kúrò ó sì gba ọ̀nà Jebusi: ọ̀nà Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ méjèèjì tí ó fi dì í ní gàárì àti àlè rẹ̀.
11 A kokoke lakou i Iebusa, ua auwi loa ka la, i ae la ke kauwa i kona haku, E kipa ae kakou i keia kulanakauhale o ko Iebusa, a moe ilaila.
Nígbà tí wọ́n súnmọ́ Jebusi tí ilẹ̀ ti fẹ́ ṣú tan, ìránṣẹ́ náà sọ fún ọ̀gá rẹ̀ pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a dúró ní ìlú yìí tí í ṣe ti àwọn ará Jebusi kí a sì sùn níbẹ̀.”
12 I mai la kona haku ia ia, Aole kakou e kipa ae ilaila, i ke kulanakauhale o kanaka e, aole no na mamo a Iseraela; e hele aku kakou, a Gibea.
Ọ̀gá rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Rárá o, àwa kì yóò wọ ìlú àwọn àjèjì, àwọn tí olùgbé ibẹ̀ kì í ṣe ọmọ Israẹli, a yóò dé Gibeah.”
13 I mai la ia i kana kauwa, Ea, e hele aku kakou e moe i ka po ma Gibea, a i Rama paha.
Ó fi kún un pé, ẹ wá ẹ jẹ́ kí a gbìyànjú kí a dé Gibeah tàbí Rama kí a sùn ní ọ̀kan nínú wọn.
14 Hele aku la lakou i ko lakou wahi i hele ai; a ua po ka la ia lakou ma Gibea no Beniamina.
Wọ́n sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn, oòrùn wọ̀ bí wọ́n ti súnmọ́ Gibeah tí ṣe ti àwọn Benjamini.
15 Kipa ae la lakou e komo ilaila, e moe ai ma Gibea; a hiki aku la ia, noho iho la ma ke alanui o ke kulanakauhale; no ka mea, aohe kanaka nana lakou i hookipa i kona hale e moe ai.
Wọ́n yípadà wọ́n lọ sí inú ìlú Gibeah láti wọ̀ síbẹ̀ ní òru náà, wọ́n lọ wọ́n sì jókòó níbi gbọ̀ngàn ìlú náà, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó gbà wọ́n sínú ilé rẹ̀ láti wọ̀ sí.
16 Aia hoi i ke ahiahi, hele mai kekahi kanaka elemakule, mai kana hana, mai ke kula mai, he kanaka no ka mauna o Eperaima, a noho iho la ma Gibea. Aka, no Beniamina na kanaka o ia wahi.
Ní alẹ́ ọjọ́ náà ọkùnrin arúgbó kan láti àwọn òkè Efraimu, ṣùgbọ́n tí ń gbé ní Gibeah (ibẹ̀ ni àwọn ẹ̀yà Benjamini ń gbé) ń ti ibi iṣẹ́ rẹ̀ bọ̀ láti inú oko.
17 Alawa ae la kona mau maka iluna, ike iho la i ke kanaka, he malihini ma ke alanui o ke kulanakauhale. I ae la ua kanaka elemakule nei, E hele ana oe ihea? a mai hea mai oe i hele mai ai?
Nígbà tí ó wòkè ó rí arìnrìn-àjò náà ní gbọ̀ngàn ìlú náà, ọkùnrin arúgbó yìí bi í léèrè pé, “Níbo ni ò ń lọ? Níbo ni o ti ń bọ̀?”
18 I mai la kela ia ia, E hele ana makou mai Betelehemaiuda a i na mokuna o ka mauna o Eperaima, nolaila hoi au, a hele aku au i Betelehemaiuda; a ke hoi aku nei au i ka hale o Iehova, aole hoi kanaka nana wau i hookipa ae i ka hale.
Ọmọ Lefi náà dá a lóhùn pé, “Bẹtilẹhẹmu ti Juda ni àwa ti ń bọ̀, àwa sì ń lọ sí agbègbè tí ó sá pamọ́ ní àwọn òkè Efraimu níbi ti mo ń gbé. Mo ti lọ sí Bẹtilẹhẹmu ti Juda, èmi sì ń lọ sí ilé Olúwa nísinsin yìí. Kò sí ẹni tí ó gbà mí sí ilé rẹ̀.
19 He mauu no, a me ka ai na na hoki a makou, a he berena no a me ka waina na'u, a na kau kauwawahine, a na ke kanaka hou o kau mau kauwa nei; aohe mea e hemahema ai.
Àwa ní koríko àti oúnjẹ tó tó fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa àti oúnjẹ àti wáìnì fún àwa ìránṣẹ́ rẹ—èmi, ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú wa. A ò ṣe aláìní ohun kankan.”
20 I ae la ke kanaka elemakule, Aloha oe, aka, maluna o'u kou nele a pau; mai moe hoi ma ke alanui.
Ọkùnrin arúgbó náà sì wí pé. “Àlàáfíà fún ọ, bí ó ti wù kí ó rí, èmi yóò pèsè gbogbo ohun tí o nílò, kìkì pé kí ìwọ má ṣe sun ní ìgboro.”
21 Hookomo iho la oia ia ia i kona hale, hanai iho la i na hoki; a holoi no hoi lakou i ko lakou wawae, ai iho la, a inu hoi.
Òun sì mú wa sí ilé rẹ̀, ó ń bọ́ àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wẹ ẹsẹ̀ wọn, àwọn àlejò náà jẹ, wọ́n mu.
22 A i ko lakou hoolealea ana i ko lakou naau, aia hoi na kanaka o ke kulanakauhale, he poe kanaka hewa, hoopuni mai la lakou i ka hale, a kikeke i ka puka, olelo mai i ka mea hale, i ua kanaka elemakule nei, i mai la, E lawe mai iwaho nei i ke kanaka i hele mai i kou hale, i ike makou ia ia.
Ǹjẹ́ bí wọ́n ti ń ṣe àríyá, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin ìlú náà, àwọn ọmọ Beliali kan, yí ilé náà ká, wọ́n sì ń lu ìlẹ̀kùn; wọ́n sì sọ fún baálé ilé náà ọkùnrin arúgbó náà pé, “Mú ọkùnrin tí ó wọ̀ sínú ilé rẹ wá, kí àwa lè mọ̀ ọ́n.”
23 A o ke kanaka, ka haku o ka hale, hele aku la ia iwaho io lakou la, i aku la ia lakou, Ua oki, e na hoahanau, mai hana hewa oukou pela. Ua hele mai keia kanaka i ko'u hale, mai hana hoi oukou i keia mea lapuwale.
Ọkùnrin, baálé ilé náà sì jáde tọ̀ wọ́n lọ, ó sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ má ṣe hùwà búburú; nítorí tí ọkùnrin yìí ti wọ ilé mi, ẹ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
24 Eia hoi ka'u kaikamahine, he puupaa, a me kana wahine no hoi, o laua ka'u e lawe mai iwaho nei, e hoohaahaa oukou ia laua, a e hana hoi ia laua i ka mea i pono i ko oukou mau maka; aka, mai hana ia mea lapuwale i keia kanaka.
Kíyèsi i, ọmọbìnrin mi ni èyí, wúńdíá, àti àlè rẹ̀; àwọn ni èmi ó mú jáde wá nísinsin yìí, kí ẹ̀yin tẹ̀ wọ́n lógo, kí ẹ̀yin ṣe sí wọn bí ó ti tọ́ lójú yín: ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí ni kí ẹ̀yin má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí sí.”
25 Aole hoolohe ia poe kanaka ia ia, Nolaila, lalau iho la ke kanaka i kana haiawahine, a lawe ia ia iwaho io lakou la, a ike mai la lakou ia ia, a hana ino lakou ia ia ia po a pau, a kakahiaka; a i ke ao ana ae, kuu mai la ia ia.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà kò fetí sí tirẹ̀. Nítorí náà ọkùnrin náà mú àlè rẹ̀ ó sì tari rẹ̀ jáde sí wọn, wọ́n sì bá a fi ipá lòpọ̀, wọ́n sì fi gbogbo òru náà bá a lòpọ̀, nígbà tí ó di àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́.
26 I ka puka ana o ka malamalama, hele mai ua wahine la, a hina iho la ma ka puka o ka hale o ua kanaka la, ma kahi a kona haku, a malamalama ae la.
Nígbà tí ojúmọ́ bẹ̀rẹ̀ sí là obìnrin náà padà lọ sí ilé tí ọ̀gá rẹ̀ wà, ó ṣubú lulẹ̀ lọ́nà, ó sì wà níbẹ̀ títí ó fi di òwúrọ̀.
27 Ala mai la kona haku i kakahiaka, a wehe ae la i ka puka o ka hale, a puka aku e hele ma kona ala; aia hoi, ua hina ka wahine ana ma ka puka o ka hale, aia hoi kona mau lima iluna o ka paepae.
Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ jí tí ó sì dìde ní òwúrọ̀ tí ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé náà, tí ó sì bọ́ sí òde láti tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, kíyèsi i àlè rẹ̀ wà ní ṣíṣubú ní iwájú ilé, tí ọwọ́ rẹ̀ sì di òpó ẹnu-ọ̀nà ibẹ̀ mú,
28 I aku la keia ia ia, E ala mai, e hele kaua. Aohe mea pane mai, Alaila, hapai ae la ua kanaka la ia ia, a kau iho la iluna o ka hoki Ku ae la ke kanaka a hoi aku la i kona wahi.
òun sì wí fún obìnrin náà pé, “Dìde jẹ́ kí a máa bá ọ̀nà wa lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò dá a lóhùn. Nígbà náà ni ọkùnrin náà gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì kọjá lọ sí ilé e rẹ̀.
29 A hiki aku la ia i kona hale, lawe ae la ia i ka pahi, a lalau aku la i kana haiawahine, a okioki iho la ia ia, a me kona mau iwi, i umikumamalua apana, a hoouna aku la ia mea, i na mokuna a pau o ka Iseraela.
Nígbà tí ó dé ilé, ó mú ọ̀bẹ ó sì gé àlè rẹ̀ ní oríkeríke sí ọ̀nà méjìlá, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí gbogbo agbègbè Israẹli.
30 Eia hoi, o ka poe a pau i ike ia mea, i ae la lakou, Aohe mea i hanaia e like me neia, aole hoi i ikeia, mai ka la i hele mai ai na mamo a Iseraela, mai ka aina o Aigupita mai, a hiki mai i neia la. E noonoo oukou ia mea, a e kukakuka iho, a e olelo mai.
Gbogbo ẹni tí ó rí i sì wí pé, “A kò ti rí i, bẹ́ẹ̀ a kò tí ì ṣe irú nǹkan yìí rí, kì í ṣe láti ọjọ́ tí Israẹli ti jáde tí Ejibiti wá títí di òní olónìí. Ẹ rò ó wò, ẹ gbìmọ̀ràn, kí ẹ sọ fún wa ohun tí a yóò ṣe!”

< Lunakanawai 19 >