< Lunakanawai 18 >

1 I A manawa, aole alii maluna o ka Iseraela, a i kela mau la e imi ana o ka Dana i aina kahi e noho ai no lakou, no ka mea, a hiki mai ia wa, aole i ili mai ko Dana aina iwaena o na ohana o ka Iseraela.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
2 Hoouna ae la na mamo a Dana i elima kanaka o ka lakou ohana, no ko lakou aina, he poe kanaka koa, no Zora, a no Esetaola, e kiu i ka aina, a makaikai; a i mai la lakou, E hele, e makaikai i ka aina. A hiki lakou i ka mauna o Eperaima, i ka hale o Mika, kipa ae la lakou ilaila.
Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
3 A ma ka hale o Mika lakou, maopopo ia lakou ka leo o ke kanaka hou o ka Levi; kipa ae la lakou ilaila, i ae la ia ia, Nawai oe i kai mai nei? Heaha hoi kau e hana nei ma keia wahi? Heaha kau o nei?
Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
4 I mai la ia, Penei, a penei ka hana ana o Mika ia'u, a ua hoolimalima mai ia'u, a owau no kona kahuna.
Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
5 I aku la lakou ia ia, E ninau aku paha oe i ke Akua, i ike makou, e pomaikai paha ko makou hele, e hele nei.
Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
6 I mai la ke kahuna ia lakou, O hele me ka pomaikai, he pololei ia Iehova ka hele a oukou e hele nei.
Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
7 Alaila, hele aku la ua mau kanaka la elima, a hiki aku la i Laisa, ike iho la i ko laila kanaka e noho makau ole ana, ma ke ano o ko Zidona, ua malie, aole i makau, aole mea e noho alii ana ma ka honua nei i hana ino mai; a ua loihi lakou, mai Zidona aku, aohe o lakou mea pu me kekahi kanaka e.
Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
8 A hoi mai la lakou i ko lakou poe hoahanau ma Zora, a me Esetaola. I aku la ko lakou poe hoahanau ia lakou, Heaha ka oukou?
Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
9 I mai la lakou, E ala mai, i pii ku e kakou ia lakou no; ka mea, ua ike makou i ka aina, aia hoi, ua maikai loa ia; a e noho malie ana oukou? Mai hoomolowa oukou i ka pii aku, a komo, a hoopio i ka aina.
Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
10 I ko oukou hele ana, e hiki no oukou i ka poe kanaka, e makau ole ana, a i ka aina nui; no ka mea, ua haawi mai ke Akua ia aina i ko oukou lima. Aole hoi i nele ia aina i kekahi mea o ka honua.
Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
11 Hele aku la, mai ia wahi aku, no ka ohana a Dana, mai Zora, a me Esetaola aku, eono haneri kanaka i kahikoia i na mea kaua.
Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
12 Pii aku la lakou a hoomoana iho la ma Kiriatiarima ma ka Iuda: nolaila, kapa aku la lakou ia wahi, o Mahanedana, a hiki mai i neia la; aia no ma ke kua o Kiriatiarima.
Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
13 A malaila aku lakou i hele ai a i ka mauna o Eperaima, a hiki aku la i ka hale o Mika.
Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
14 Alaila, ninau ae la na kanaka elima, i hele aku e makaikai i ka aina o Laisa, i aku la i ko lakou poe hoahanau, Ua ike anei oukou, aia maloko o keia mau hale, he epoda, a he terapima, a me ke kii, a me ke kii hooheheeia? Nolaila ea, e noonoo oukou i ka oukou mea e hana'i.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
15 Kipa ae la lakou ilaila, a hiki ae la i ke kanaka hou o ka Levi, i ka hale hoi o Mika, a aloha ae la ia ia.
Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
16 Ku iho la ma ka ipuka, kela poe kanaka eono haneri i kahikoia i na mea kaua, o ka poe mamo hoi a Dana.
Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
17 Pii ae la a komo ilaila na kanaka elima i pii aku e makaikai i ka aina, a lawe lakou i ke kii, a me ka epoda, a me ke terapima, a me ke kii i hooheheeia; a ku mai la ke kahuna ma ka ipuka me na kanaka eono haneri i kahikoia i na mea kaua.
Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
18 Hele aku la keia poe iloko o ka hale o Mika, a lawe mai la i ke kii, a me ka epoda, a me ke terapima, a me ke kii i hooheheeia. Alaila, i aku la ke kahuna ia lakou, Heaha ka oukou e hana nei?
Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
19 I mai la lakou ia ia, Hamau, e kau oe i kou lima ma kou waha, a e hele pu me makou, i lilo oe i makua no makou, a i kahuna hoi. He mea maikai anei ia oe i kahuna oe no ka hale o ke kanaka hookahi, no ka ohana paha, a no ka hanauna iloko o ka Iseraela?
Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
20 Olioli iho la ka naau o ke kahuna, a lawe ae la oia i ka epoda, a me ke terapima, a me ke kii, a hele aku la iwaena o na kanaka.
Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
21 Huli ae la lakou a hele aku la, a hoonoho iho la i ka poe opio, a me na holoholona, a me ka ukana imua o lakou.
Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
22 A hiki lakou i kahi mamao mai ka hale o Mika aku, alaila, hoakoakoaia mai la na kanaka o kauhale e kokoke ana ma ka hale o Mika, a hahai aku la i na mamo a Dana.
Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
23 Hea aku la lakou i na mamo a Dana; a huli mai ko lakou maka, i mai la ia Mika, Heaha kau i akoakoa mai nei?
Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
24 I aku la keia, Ua lawe aku oukou i ko'u mau akua, a'u i hana'i, a me ke kahuna, a ua hele oukou. Heaha hoi ka mea i koe ia'u? Heaha hoi keia mea a oukou i ninau mai nei ia'u? Heaha kau?
Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
25 I mai la na mamo a Dana ia ia, Mai lohe hou ia kou leo iwaena o makou, o lele aku maluna o oukou na kanaka i walania, a lilo kou ola, a me ke ola o ko ka hale ou.
Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
26 Hele aku la na mamo a Dana i ko lakou wahi i hele ai. A ike iho la o Mika, ua oi ko lakou ikaika i kona, huli mai la ia, a hoi ae la i kona hale.
Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
27 Lawe lakou i na mea a Mika i hana'i, a me kona kahuna, a hele aku la i Laisa, i ka poe kanaka e noho malie ana, me ka makau ole; a luku aku la keia poe ia lakou i ka maka o ka pahikaua, a puhi aku la i ko lakou kulanakauhale i ke ahi.
Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
28 Aohe mea nana i hoopakele, no ka mea, ua loihi ia mai Zidona aku, aole hoi lakou he mea pu me kekahi kanaka e. Aia no ia ma ke kahawai e kokoke ana i Beterehoba. Hana iho la lakou i kulanakauhale, a noho no ilaila.
Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
29 Kapa iho la lakou i ka inoa o ia kulanakauhale, o Dana, mamuli o Dana, o ko lakou kupuna kane, ka mea i hanau na Iseraela; aka, o Laisa ka inoa kahiko o ua kulanakauhale la.
Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
30 Kukulu iho la na mamo a Dana i ke kii; a o Ionetana, ke keiki a Geresoma, ke keiki a Manase, oia, a me kana mau keiki na kahuna no ka ohana a Dana, a hiki i ka la i pio ai ka aina.
Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
31 Kukulu lakou i ke kii o Mika, ana i hana'i, i ka manawa a pau i ku ai ka hale o ke Akua ma Silo.
Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.

< Lunakanawai 18 >