< Lunakanawai 11 >

1 HE kanaka koa loa o Iepeta, no Gileada, a he keiki ia na kekahi wahine hookamakama: na Gileada o Iepeta.
Jefta ará Gileadi jẹ́ akọni jagunjagun. Gileadi ni baba rẹ̀; ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ jẹ́ panṣágà.
2 Hanau mai la ka Gileada wahine i mau keikikane nana; a oo ae la na keikikane a kana wahine, kipaku aku la lakou ia Iepeta, i aku la ia ia, Aole ou kuleana ma ka hale o ko makou makuakane; no ka mea, he keiki oe na kekahi wahine e.
Ìyàwó Gileadi sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un, nígbà tí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí dàgbà, wọ́n rán Jefta jáde kúrò nílé, wọ́n wí pé, “Ìwọ kì yóò ní ogún kankan ní ìdílé wa, nítorí pé ìwọ jẹ́ ọmọ obìnrin mìíràn.”
3 Holo aku la o Iepeta, mai ke alo aku o kona poe hoahanau, a noho ma ka aina o Toba. Akoakoa mai la na kanaka lapuwale io Iepeta la, a hele pu me ia.
Jefta sì sá kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì pàgọ́ sí ilẹ̀ Tobu, ó sì ń gbé níbẹ̀, níbẹ̀ ni àwọn ènìyàn kan ti ń tẹ òfin lójú parapọ̀ láti máa tẹ̀lé e kiri.
4 A mahope iho o ia mau la, kaua aku la na mamo a Amona i ka Iseraela.
Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ammoni dìde ogun sí àwọn Israẹli,
5 A i ka manawa i kaua aku ai na mamo a Amona i ka Iseraela, alaila, hele aku la na lunakahiko o Gileada e lawe mai ia Iepeta, mai ka aina mai o Toba.
Ó sì ṣe nígbà tí àwọn Ammoni bá Israẹli jagun, àwọn àgbàgbà Gileadi tọ Jefta lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tobu.
6 I aku la lakou ia Iepeta, E hele mai oe i luna kaua no makou, i kaua aku makou i na mamo a Amona.
Wọ́n wí fún Jefta wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ammoni.”
7 I mai la o Iepeta i na luna kahiko o Gileada, Aole anei oukou i hoowahawaha mai ia'u, a kipaku mai ia'u, mai ka hale mai o ko'u makuakane? No ke aha la oukou e hele mai ai io'u nei, i keia wa a oukou i pilikia'i?
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kórìíra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”
8 I aku la na lunakahiko o Gileada ia Iepeta, Ke hoi hou mai nei makou ia oe, e hele pu oe me makou, e kaua aku i na mamo a Amona, a i lilo oe i poo maluna o ka poe a pau e noho ana ma Gileada.
Àwọn àgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ammoni, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gileadi.”
9 I mai la o Iepeta i na lunakahiko o Gileada, Ina hoihoi oukou ia'u e kaua aku i na mamo a Amona, a haawi mai o Iehova ia lakou imua o'u, e lilo anei au i poo no oukou?
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ammoni jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́?”
10 I aku la na lunakahiko o Gileada ia Iepeta, Na Iehova no e hoolohe mai mawaena o kakou, ke hana ole makou e like me kau olelo.
Àwọn àgbàgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”
11 Alaila hele pu o Iepeta me na lunakahiko o Gileada, a hoonoho iho la na kanaka ia Iepeta, i poo, a i luna hoi maluna o lakou. Olelo aku la o Iepeta i kana olelo a pau imua o Iehova ma Mizepa.
Jefta sì tẹ̀lé àwọn àgbàgbà Gileadi lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jefta sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mispa.
12 Hoouna aku la o Iepeta i elele, i ke alii o na mamo a Amona, i aku la, Heaha kau ia'u, i hele mai ai oe e kaua i ko'u aina?
Jefta sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ammoni pé, “Kí ni ẹ̀sùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”
13 I mai la ke alii o na mamo a Amona i na elele o Iepeta, No ka mea, lawe lilo ka Iseraela i ko'u aina, mai Arenona a hiki i Iaboka, a me Ioredane, i ka wa a lakou i hele mai ai, mailoko mai o Aigupita; nolaila, e hoihoi mai oe ia, me ka malu.
Ọba àwọn Ammoni dá àwọn oníṣẹ́ Jefta lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli jáde ti Ejibiti wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Arnoni dé Jabbok, àní dé Jordani, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”
14 Hoouna hou aku la o Iepeta i elele i ke alii o na mamo a Amona:
Jefta sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ammoni
15 I aku la ia ia, Ke olelo mai nei o Iepeta, aole i lawe ka Iseraela i ka aina o Moaba, aole hoi i ka aina o na mamo a Amona;
ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Jefta wí: àwọn ọmọ Israẹli kò gba ilẹ̀ Moabu tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ammoni.
16 I ka manawa i hele mai ai ka Iseraela, mai Aigupita mai, hele no lakou, ma ka waonahele a hiki i ke Kaiula, a komo no i Kadesa.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Ejibiti àwọn ọmọ Israẹli la aginjù kọjá lọ sí ọ̀nà Òkun Pupa wọ́n sì lọ sí Kadeṣi.
17 Alaila, hoouna ka Iseraela i elele i ke alii o Edoma, i aku la, E hele paha wau mawaena o kou aina. Aole hoolohe mai ke alii o Edoma. Pela no lakou i hoouna aku ai i ke alii o Moaba. Aole ia i ae, a noho no ka Iseraela ma Kadesa.
Nígbà náà Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Edomu pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Edomu kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Moabu bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Israẹli dúró sí Kadeṣi.
18 Hele ae la lakou ma ka waonahele, a puni ka aina o Edoma, a me ka aina o Moaba, ma ka aoao hikina o Moaba ka hele ana; a hoomoana iho la ma kela aoao o Arenona, aole hoi i komo maloko o na mokuna o Moaba; no ka mea, o Arenona ka mokuna o Moaba.
“Wọ́n rin aginjù kọjá, wọ́n pẹ́ àwọn ilẹ̀ Edomu àti ti Moabu sílẹ̀, nígbà tí wọ́n gba apá ìlà-oòrùn Moabu, wọ́n sì tẹ̀dó sí apá kejì Arnoni. Wọn kò wọ ilẹ̀ Moabu, nítorí pé ààlà rẹ̀ ni Arnoni wà.
19 Hoouna aku la ka Iseraela i elele ia Sihona, i ke alii o ka Amora, ke alii o Hesebona, i aku la o Iseraela ia ia, E hele paha makou mawaena o kou aina, a hiki i ko'u wahi.
“Nígbà náà ni Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ń ṣe àkóso ní Heṣboni, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Jẹ́ kí a la ilẹ̀ rẹ kọjá lọ sí ibùgbé wa.’
20 Aole oluolu o Sihona ke hele ka Iseraela ma kona mokuna. Hoakoakoa mai la o Sihona i kona poe kanaka a pau, a hoomoana iho la ma Iahaza, a kaua mai la i ka Iseraela.
Ṣùgbọ́n Sihoni kò gba Israẹli gbọ́ (kò fọkàn tán an) láti jẹ́ kí ó kọjá. Ó kó gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ jọ, ó sì tẹ̀dó sí Jahisa láti bá Israẹli jagun.
21 Haawi mai la o Iehova, ke Akua o ka Iseraela ia Sihona, a me kona poe kanaka a pau i ka lima o ka Iseraela, a luku aku la lakou nei i kela poe. A komo iho ka Iseraela i ka aina a pau o ka Amora, ka poe i noho ma ia aina.
“Olúwa Ọlọ́run Israẹli sì fi Sihoni àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Israẹli sì gba gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Amori tí wọ́n ń gbé ní agbègbè náà,
22 A komo no lakou i na mokuna a pau o ka Amora, mai Arenona, a hiki i Iaboka, mai ka waonahele, a hiki i Ioredane.
wọ́n gbà gbogbo agbègbè àwọn ará Amori, láti Arnoni tí ó fi dé Jabbok, àti láti aginjù dé Jordani.
23 Ua hoonele mai o Iehova, ke Akua o ka Iseraela i ka Amora, mai ke alo aku o ka Iseraela, a e komo anei oe ia wahi?
“Wàyí o, nígbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti lé àwọn ará Amori kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀; Israẹli, ẹ̀tọ́ wo ni ẹ ní láti gba ilẹ̀ náà?
24 Aole anei oe e komo i kahi a Kemosa, a kou akua, e hookomo ai ia oe? A o na mea a pau a Iehova a ko makou Akua e hoonele ai imua o makou, oia ka makou e komo ai.
Ǹjẹ́ ìwọ kì yóò ha gba èyí tí Kemoṣi òrìṣà rẹ fi fún ọ? Bákan náà àwa yóò gba èyíkéyìí tí Olúwa Ọlọ́run wa fi fún wa.
25 Ua oi aku anei kou maikai mamua o ko Balaka, ke keiki a Zipora ke alii o Moaba? Ua paio anei ia me ka Iseraela, ua kaua anei ia lakou,
Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu lọ? Ǹjẹ́ òun ha ṣe gbólóhùn asọ̀ pẹ̀lú Israẹli bí? Tàbí òun dojú ìjà kọ wọ́n rí bí?
26 I ka noho ana o ka Iseraela ma Hesebona, a me kona mau kulanakauhale, a ma Aroera, a me kona mau kulanakauhale, a ma na kulanakauhale a pau e kokoke ana i na mokuna o Arenona, ekolu haneri makahiki? No ke aha la oukou i kii ole mai e lawe ia manawa?
Fún ọ̀ọ́dúnrún ọdún ni Israẹli fi ṣe àtìpó ní Heṣboni, Aroeri àti àwọn ìgbèríko àti àwọn ìlú tí ó yí Arnoni ká. Èéṣe tí ìwọ kò fi gbà wọ́n padà ní àsìkò náà?
27 Aole au i hana hewa ia oe, aka, ke hana hewa mai nei oe ia'u i kou kaua ana mai ia'u. O Iehova ka lunakanawai, nana no e hooponopono mai i keia la iwaena o na mamo a Iseraela a me na mamo a Amona.
Èmi kọ́ ni ó ṣẹ̀ ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ ni ó ṣẹ̀ mí nípa kíkógun tọ̀ mí wá. Jẹ́ kí Olúwa olùdájọ́, ṣe ìdájọ́ lónìí láàrín àwọn ọmọ Israẹli àti àwọn ará Ammoni.”
28 Aole hoolohe ke alii o na mamo a Amona i na olelo a Iepeta ana i hoouna aku ai ia ia.
Ṣùgbọ́n ọba àwọn Ammoni kò fetí sí iṣẹ́ tí Jefta rán sí i.
29 Alaila kau mai la ka Uhane o ke Akua maluna o Iepeta, a kaahele ae la ia i Gileada, a me ko Manase, a kaahele aku ia Mizepa o Gileada, a mai Mizepa o Gileada ia i hele aku ai a i na mamo a Amona.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jefta òun sì la Gileadi àti Manase kọjá. Ó la Mispa àti Gileadi kọjá láti ibẹ̀, ó tẹ̀síwájú láti bá àwọn ará Ammoni jà.
30 Hoohiki iho la o Iepeta, me ka olelo haawi no Iehova, i aku la, Ina e haawi io mai oe i na mamo a Amona i ko'u lima,
Jefta sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí ìwọ bá fi àwọn ará Ammoni lé mi lọ́wọ́,
31 Alaila, o ka mea e puka e mai ana, mailoko mai o na puka o ko'u hale, e halawai me au, i ko'u hoi ana me ka malu, mai na mamo a Amona aku, oia ko Iehova, a i ole ia na'u ia e kaumaha aku i mohai kuni.
yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ó bá jáde láti ẹnu-ọ̀nà ilé mi láti wá pàdé mi, nígbà tí èmi bá ń padà bọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ammoni ní àlàáfíà, yóò jẹ́ ti Olúwa, èmi yóò sì fi rú ẹbọ bí ọrẹ ẹbọ sísun.”
32 Hele aku la o Iepeta i na mamo a Amona, e kaua aku ia lakou; a haawi mai o Iehova ia lakou i kona lima.
Jefta sì jáde lọ láti bá àwọn ará Ammoni jagun, Olúwa sì fi wọ́n lé e lọ́wọ́.
33 Luku aku la ia ia lakou, mai Aroera aku a hiki i Minita, he iwakalua kulanakauhale, a hiki no hoi i ka papu o na malawaina, he luku nui loa. Pio iho la na mamo a Amona imua o ke alo o na mamo a Iseraela.
Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní à pa tán láti Aroeri títí dé agbègbè Minniti, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Keramimu. Báyìí ni Israẹli ti ṣẹ́gun àwọn ará Ammoni.
34 Hoi mai la o Iepeta i Mizepa, i kona hale; aia hoi kana kaikamahine i hele mai iwaho, e halawai me ia, me na pahu kani, a me ka hula. O kana hanau kahi no ia; aole ana keikikane, aole hoi kaikamahine e ae.
Nígbà tí Jefta padà sí ilé rẹ̀ ní Mispa, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú timbrili àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.
35 A ike aku la o Iepeta ia ia, haehae iho la i kona aahu, i aku la, Auwe kuu kaikamahine e! Ua hookaumaha loa mai oe ia'u; o oe kekahi i hoopilikia mai ia'u. Ua oaka ae la au i kuu waha ia Iehova, aole hiki ia'u ke hoi hope.
Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le sẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”
36 I aku la oia ia ia, E kuu makuakane, ua oaka oe i kou waha ia Iehova ea, e hana mai oe ia'u, e like me kela mea i puka aku, mai kou waha aku; no ka mea, ua hoopai o Iehova i kou poe enemi nou, i na mamo hoi a Amona.
Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀san fún ọ lára àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ará Ammoni.
37 I aku la oia i kona makuakane, E hanaia keia mea no'u; e waiho wale ia'u, i elua malama, i hele au a kaahele i na mauna, a uwe i ko'u puupaa ana, owau a me ko'u poe hoahanau.
Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láààyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n sọkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúńdíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”
38 I mai la kela, O hele. Hoouna ae la oia ia ia i elua malama. Hele aku la ia me kona mau hoalauna, a uwe iho la ma na mauna no kona puupaa ana.
Jefta dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láààyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yòókù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n sọkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.
39 A i ka pau ana o na malama elua, hoi mai la kela i kona makuakane, a hana aku la oia ia ia i kona hoohiki ana i hoohiki ai; aole hoi ia i ike i ke kane: a lilo ia i oihana mawaena o ka Iseraela,
Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúńdíá tí kò mọ ọkùnrin rí. Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Israẹli
40 O ka hele ana o na kaikamahine o ka Iseraela, i kela makahiki, i keia makahiki, e hoomaikai i ke kaikamahine a Iepeta, no Gileada, eha la i ka makahiki
wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrín ọdún àwọn obìnrin Israẹli a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jefta ti Gileadi.

< Lunakanawai 11 >