< Iosua 9 >

1 A LOHE na'lii a pau loa ma keia aoao o Ioredane, ma na mauna, a ma na awawa, a makai ma kahi e pili ana i ka moana nui ma ke alo o Lebanona, o ka Heta, a me ka Amora, a me ko Kanaana, a me ka Pereza, a me ka Heva, a me ka Iebusa,
Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
2 Alaila, hoakoakoa mai la lakou e kaua lokahi mai ia Iosua, a me ka Iseraela.
wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
3 A lohe ka poe i noho ma Gibeona i ka mea a Iosua i hana'i ia Ieriko a me Ai,
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
4 Alaila hana maalea iho la lakou, a hele aku la, hoomakaukau iho la i o na lakou; a lawe no hoi lakou i na puolo kahiko ma ko lakou mau hoki, a me na hueili waina kahiko, a ua haehae, a ua pahonoia;
wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
5 A me na kamaa kahiko, a hawele iho la ma ko lakou kapuwai, a aahu iho la i ka lole kahiko; a o ka berena, ka lakou ai, ua maloo a okaoka.
Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
6 A hele mai la lakou io Iosua la, ma kahi a lakou i hoomoana'i ma Gilegala, i mai la ia ia, a me na kanaka o ka Iseraela, Ua hele mai nei makou, mai ka aina loihi mai; no ia mea, e hana kakou i olelo kuikahi.
Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
7 I aku la na kanaka o ka Iseraela i ka poe Heva, Ke noho nei paha oukou iwaena o makou: pehea la makou e hana'i me oukou i olelo kuikahi?
Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
8 I mai la lakou ia Iosua, He poe kauwa makou nau. I aku la o Iosua ia lakou, Owai oukou? a mai hea mai oukou i hele mai nei?
“Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
9 I mai la lakou ia ia, O kau poe kauwa nei, ua hele mai makou, mai ka aina loihi loa mai, no ka inoa o Iehova o kou Akua: no ka mea, ua lohe makou i kona kaulana ana, a me na mea a pau ana i hana'i ma Aigupita,
Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
10 A me na mea a pau ana i hana aku ai i na'lii elua o ka Amora, mao aku o Ioredane, ia Sihona, ke alii o Hesebona, a me Oga, ke alii o Basana, aia ma Asetarota.
àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
11 Nolaila i olelo mai ai ko makou poe lunakahiko, a me ka poe a pau i noho i ko makou aina, i mai la ia makou, E lawe oukou ma ko oukou lima i o na oukou ma ke ala, a e hele e halawai me lakou, a e i aku ia lakou, O ka oukou kauwa makou, e hana kakou i olelo kuikahi.
Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
12 O keia berena a makou, o ka makou o noloko mai o ko makou hale, ua hoomakaukau hou ia no makou, i ko makou la i hele mai ai e halawai me oukou, aia hoi, ua maloo, a ua helelei.
Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
13 O keia mau hueili waina hoi, a makou i ukuhi hou ai, aia, ua nahaehae. A o keia mau aahu o makou, a me ko makou kamaa, ua weluwelu, no ka loihi loa o ke ala.
Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
14 Lawe no na kanaka i ka lakou ai, aole hoi i ninau aku ma ka waha o Iehova.
Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
15 Hoomalu aku la o Iosua ia lakou, a hana iho la i olelo kuikahi me lakou, e ola'i lakou; a hoohiki aku la na luna o ka Iseraela ia lakou.
Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
16 A mahope iho, i ka pau ana o na la ekolu, mai ka wa mai o ka lakou hana ana i ka olelo kuikahi, alaila lohe o Iosua ma, he kamaaina lakou, a ua noho pu me lakou.
Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
17 Hele ae la na mamo a Iseraela, a po akolu hiki i ko lakou mau kulanakauhale. Eia ko lakou mau kulanakauhale, o Gibeona, o Hepira, o Beerota a me Kiriatiarima.
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
18 Aole i pepehi aku na mamo a Iseraela, no ka mea, ua hoohiki ia lakou na luna o ka Iseraela, ma Iehova, ke Akua o Iseraela. Ohumu iho la na kanaka a pau i na luna.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
19 Aka, olelo mai la na luna a pau i kanaka a pau, Ua hoohiki no makou ia lakou, ma Iehova, ke Akua o Iseraela. Nolaila aole pono e hoopa aku kakou ia lakou.
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
20 Eia ka kakou e hana aku ai ia lakou. E hoola no kakou ia lakou, o huhuia mai kakou, no ka hoohiki ana a makou i hoohiki ai ia lakou.
Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
21 I mai la na luna i ka Iseraela, E ola no lakou, aka, e lilo no lakou i poe kalai laau, a i poe huki wai, no ke anainakanaka a pau, e like me ka na luna i olelo aku ai ia lakou.
Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
22 Kii aku la o Iosua ia lakou, ninau aku la, me ka i ana aku ia lakou, No ke aha la oukou i nolu mai ai a puni makou, me ka olelo mai, Ua loihi aku makou, mai o oukou aku; a eia hoi oukou, ke noho nei iwaena o makou?
Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
23 No ia mea e poino auanei oukou, aole loa e kuuia kekahi o oukou; e lilo no oukou i poe kauwa, a i poe kalai laau, a i poe huki wai, no ka hale o ko'u Akua.
Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
24 Olelo mai lakou ia Iosua, i mai la, No ka hai maopopo ia mai i kau poe kauwa nei, ka mea a Iehova kou Akua i kauoha mai ai i kana kauwa ia Mose, e haawi mai i ka aina a pau no oukou, a e luku hoi i na kanaka a pau o ka aina, imua o oukou; nolaila, i makau loa ai makou i ko makou ola, no oukou, a ua hana hoi i keia mea.
Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
25 Eia hoi makou iloko o kou lima; a o ka mea pono a pololei hoi i kou manao, o kau ia e hana mai ai ia makou.
Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
26 A pela no ia i hana aku ai ia lakou, a hoopakele ia lakou, mai ka lima ae o na mamo a Iseraela, i pepehi ole aku lakou.
Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
27 Ia la, hoolilo iho la o Iosua ia lakou i poe kalai laau, a i poe huki wai no na kanaka, a no ke kuahu o Iehova, ma kahi ana i makemake ai, pela no, a hiki loa mai i neia la.
Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.

< Iosua 9 >