< Iosua 6 >

1 U A pani paa loa ia o Ieriko, no na mamo a Iseraela, aohe mea i puka aku iwaho, aole hoi he mea i komo mai iloko.
Wàyí o, a ti há Jeriko mọ́lé gágá nítorí àwọn ọmọ Israẹli, ẹnikẹ́ni kò jáde, ẹnikẹ́ni kò sì wọlé.
2 Olelo mai la o Iehova ia Iosna, E nana, ua haawi aku au ia Ieriko i kou lima, a me kona alii, a me na mea koa nui.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo ti fi Jeriko lé ọ lọ́wọ́ pẹ̀lú ọba rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀.
3 E poai oukou i ua kulanakauhale la, o na kanaka kaua a pau, hookahi no ka poai ana ia kulanakauhale; pela e hana'i oe i na la eono.
Ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan pẹ̀lú gbogbo àwọn jagunjagun. Ẹ ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
4 Na na kahuna ehiku e lawe i na pu kiwi hipa ehiku, mamua o ka pahu; a i ka hiku o ka la, ehiku ko oukou poai ana i ua kulanakauhale nei, a e puhi no na kahuna i ka pu.
Jẹ́ kí àwọn àlùfáà méje gbé fèrè ìwo àgbò ní iwájú àpótí ẹ̀rí. Ní ọjọ́ keje, ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, pẹ̀lú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè.
5 A hiki i ka wa e puhi loihi ai lakou i ke kiwi hipa, a lohe oukou i ke kani ana o ua mau pu nei, alaila, e hooho na kanaka a pau i ka hooho nui. Alaila e hiolo loa ilalo ka pa o ua kulanakauhale la, a e pii no kela kanaka keia kanaka ma kona alo iho.
Nígbà tí ẹ bá gbọ́ ohùn fèrè náà, kí àwọn ènìyàn hó yèè ní igbe ńlá, nígbà náà ni odi ìlú náà yóò sì wó lulẹ̀, àwọn ènìyàn yóò sì lọ sí òkè, olúkúlùkù yóò sì wọ inú rẹ̀ lọ tààrà.”
6 Hea aku la o Iosua, ke keiki a Nuna i na kahuna, i aku la ia lakou, E hapai i ka pahuberita; a na na kahuna ehiku e lawe i na pu kiwi hipa ehiku, mamua o ka pahu o Iehova.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ọmọ Nuni pe àwọn àlùfáà ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa náà kí àwọn àlùfáà méje tí ó ru fèrè ìwo wà ní iwájú u rẹ̀.”
7 I mai la ia i kanaka, O haele, a e poai i ke kulanakauhale, a o ka mea i makaukau i ke kaua, e hele ia mamua o ka pahu o Iehova.
Ó sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ lọ, kí ẹ sì yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn olùṣọ́ tí ó hámọ́ra kọjá ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa.”
8 A pau ka Iosua olelo ana i kanaka, alaila, hele ae la imua o Iehova, na kahuna ehiku, e lawe ana i na pu kiwi hipa ehiku, a puhi iho la lakou i ka pu; a hele ae la ka pahu o Iehova mahope o lakou.
Nígbà tí Joṣua ti bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ tán, àwọn àlùfáà méje tí wọ́n gbé fèrè méje ní iwájú Olúwa kọjá sí iwájú, wọ́n sì fọn fèrè wọn, àpótí ẹ̀rí Olúwa sì tẹ̀lé wọn.
9 A o ka poe i makaukau i ke kaua, hele lakou mamua o na kahuna, ka poe i puhi i ka pu, a hele ka hunapaa mahope o ka pahu, a hele lakou me ke puhi i ka pu.
Àwọn olùṣọ tí ó hámọ́ra sì lọ níwájú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè, olùṣọ́ ẹ̀yìn sì tẹ̀lé àpótí ẹ̀rí náà. Ní gbogbo àsìkò yìí fèrè sì ń dún.
10 Ua kauoha no o Iosua i kanaka, me ka i aku, mai hooho oukou, aole hoi e uwalaau iki aku. Mai puka aku kekahi olelo, mailoko aku o ko oukou waha, a hiki i ka la a'u e olelo aku ai ia oukou, e hooho, alaila, e hooho oukou.
Ṣùgbọ́n Joṣua tí pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ kígbe ogun, ẹ kò gbọdọ̀ gbé ohùn yín sókè, ẹ má ṣe sọ ọ̀rọ̀ kan títí ọjọ́ tí èmi yóò sọ fún un yín pé kí ẹ hó. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì hó!”
11 Poai aku la ka pahu o Iehova ia kulanakauhale, hookahi no ko lakou poai ana; a hoi mai lakou i kahi i hoomoana'i, a malaila lakou i moe ai.
Bẹ́ẹ̀ ni ó mú kí àpótí ẹ̀rí Olúwa yí ìlú náà ká, ó sì yí i ká lẹ́ẹ̀kan. Nígbà náà ni àwọn ènìyàn náà padà sí ibùdó, wọ́n sì gbé ibẹ̀ fún alẹ́ náà.
12 Ala mai la o Iosua i ke kakahiaka nui, a hapai ae la na kahuna i ka pahu o Iehova.
Joṣua sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
13 A o na kahuna ehiku e lawe ana i na pu kiwi hipa ehiku, mamua o ka pahu o Iehova, hele ae la lakou me ke puhi i ka pu; a o ka poe i makaukau i ke kaua, hele ae la lakou mamua o na kahuna, a o ka hunapaa, hele ae la ia mahope o ka pahu o Iehova, a hele lakou me ke puhi i ka pu.
Àwọn àlùfáà méje tí ó gbé ìpè ìwo àgbò méje ń lọ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n sì ń fọ́n àwọn ìpè: àwọn tí ó hámọ́ra ogun ń lọ níwájú u wọn; àwọn ọmọ tó wà lẹ́yìn sì ń tọ àpótí ẹ̀rí Olúwa lẹ́yìn, àwọn àlùfáà sì ń fọn ìpè bí wọ́n ti ń lọ.
14 Hookahi no ko lakou poai ana i ua kulanakauhale la, i ka lua o ka la; a hoi mai la lakou i kahi i hoomoana'i; a pela lakou i hana'i i na la eono.
Ní ọjọ́ kejì, wọ́n yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan wọ́n sì padà sí ibùdó. Wọ́n sì ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
15 A i ka hiku o ka la, ala lakou i ka wanaao, a ehiku ko lakou poai ana i ke kulanakauhale, e like me ka mea mamua; ehiku hoi ko lakou poai ana ia la.
Ní ọjọ́ keje, wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní àfẹ̀mọ́júmọ́, wọ́n sì wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí i ti ìṣáájú, ní ọjọ́ keje nìkan ṣoṣo ni wọ́n wọ́de ogun yí ìlú náà ká nígbà méje.
16 A i ka hiku o ka poai ana, i ka wa i puhi na kahuna i ka pu, alaila, olelo ae la o Iosua i kanaka, E hooho oukou; no ka mea, na haawi mai o Iehova i ke kulanakauhale no oukou.
Ní ìgbà keje, nígbà tí àwọn àlùfáà fọn fèrè, Joṣua pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ hó! Nítorí pé Olúwa ti fún un yín ní ìlú náà.
17 A e laa kela kulanakauhale ia Iehova, oia, a me na mea a pau iloko. O Rahaba, o ka wahine hookamakama, oia wale no ke ola, oia a me na mea a pau iloko o ka hale me ia, no ka mea, nana no i huna i na elele a kakou i hoouna aku ai.
Ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà níbẹ̀ ni yóò jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ fún Olúwa. Rahabu tí ó jẹ́ panṣágà nìkan àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ ni a ó dá sí; nítorí tí ó pa àwọn ayọ́lẹ̀wò tí á rán mọ́.
18 E malama hoi oukou ia oukou iho i na mea i laa, o laa oukou i ko oukou lawe ana i na mea laa, a hoolilo oukou i ka Iseraela i mea laa, a hoopilikia hoi ia lakou.
Ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun, kí ẹ̀yin kí ó má ba à ṣojú kòkòrò nípa mímú nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀. Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ẹ ó sọ ibùdó Israẹli di ìparun. Kí ẹ sì mú wàhálà wá sórí i rẹ̀.
19 A o ke kala a pau, a me ke gula, a me na ipu keleawe a pau, a me ka hao, e kapu no ia mau mea no Iehova. E komo no ia iloko o ka waihona kala o Iehova.
Gbogbo fàdákà àti wúrà àti ohun èlò idẹ àti irin jẹ́ mímọ́ fún Olúwa, wọ́n yóò wá sínú ìṣúra Olúwa.”
20 A i ko lakou puhi ana i ka pu, hooho aku la na kanaka; a lohe na kanaka i ke kani ana o ka pu, a me ka hooho nui ana a kanaka i hooho ai, alaila hiolo ka pa ilalo, a pii aku la lakou i ke kulanakauhale, o kela kanaka keia kanaka ma kona alo iho, a pio ke kulanakauhale ia lakou.
Nígbà tí àwọn àlùfáà fọn ìpè, àwọn ènìyàn náà sì hó. Ó sì ṣe, bí àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìró ìpè, tí àwọn ènìyàn sì hó ìhó ńlá, odi ìlú náà wó lulẹ̀ bẹẹrẹ; bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ya wọ inú ìlú náà lọ tààrà, wọ́n sì kó ìlú náà.
21 Me ka maka o ka pahi kaua lakou i luku loa ai i na mea a pau iloko o ke kulanakauhale, o na kane a me na wahine, o na mea opiopio, a me na mea kahiko, o ka bipi, a me ka hipa a me ka hoki.
Wọ́n ya ìlú náà sọ́tọ̀ fún Olúwa àti fún ìparun, wọ́n sì fi idà run gbogbo ohun alààyè ní ìlú náà—ọkùnrin àti obìnrin, ọ́mọdé, àti àgbà, màlúù, àgùntàn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
22 Olelo aku la o Iosua i ua mau kanaka la nana i makai i ka aina, E komo olua iloko o ka hale o ka wahine hookipa, a e lawe mai iwaho i ka wahine a me kana mea a pau, e like me ka olua i hoohiki ai nona.
Joṣua sì sọ fún àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ti wá ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà pé, “Ẹ lọ sí ilé panṣágà nì, kí ẹ sì mu jáde àti gbogbo ohun tí í ṣe tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ tí búra fún un.”
23 Komo aku la ua mau kanaka ui la o na kiu, a lawe mai la iwaho ia Rahaba, a me kona makuakane, a me kona makuwahine, a me na kaikunane ona, a me kona mau mea a pau; a lawe mai la no hoi lakou i kona poe hoahanau a pau, a waiho iho la ia lakou mawaho o kahi i hoomoana'i ka Iseraela.
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó lọ ṣe ayọ́lẹ̀wò wọlé lọ, wọ́n sì mú Rahabu jáde, baba rẹ̀, ìyá rẹ̀, àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. Wọ́n sì mú gbogbo ìdílé rẹ̀ jáde, wọ́n sì fi wọ́n sí ibìkan ní ìta ibùdó àwọn ará Israẹli.
24 Puhi iho la lakou i ke kulanakauhale i ke ahi, a me na mea a pau iloko; aka, o ke kala, a me ke gula, a me na ipu keleawe melemele, a me na ipu hao, waiho iho la lakou iloko o ka waihona kala o ka hale o Iehova.
Nígbà náà ni wọ́n sun gbogbo ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà nínú u rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n fi fàdákà, wúrà ohun èlò idẹ àti irin sínú ìṣúra ilé Olúwa.
25 Hoola aku la o Iosua ia Rahaba, ka wahine hookipa, a me ka poe o kona makuakane, a me kona mea a pau, aia no hoi ia e noho la i neia la, me ka Iseraela; no ka mea, nana no i huna i na elele a Iosua i hoouna aku ai e makai ia Ieriko.
Ṣùgbọ́n Joṣua dá Rahabu panṣágà pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Joṣua rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jeriko mọ́. Ó sì ń gbé láàrín ará Israẹli títí di òní yìí.
26 Ia manawa kauoha no o Iosua ia lakou, me ka hoohiki a me ka i ana aku, E poino auanei imua o Iehova, ke kanaka nana e ku ae a kukulu hou i keia kulanakauhale ia Ieriko. Me kana hiapo ia e hookumu ai, a me kana muli loa e hoopaa ai ia i na puka ona.
Ní àkókò náà Joṣua sì búra pé, “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jeriko kọ́: “Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni yóò fi pilẹ̀ rẹ̀; ikú àbíkẹ́yìn rẹ̀ ní yóò fi gbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”
27 Aia no o Iehova me Iosua, a kaulana loa kona inoa ma na aina a pau.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Joṣua; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.

< Iosua 6 >