< Iosua 22 >

1 A LAILA, kahea aku la o Iosua i ka Reubena, a me ka Gada a me ka ohana hapa a Munase,
Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
2 Olelo aku la oia ia lakou, Ua malama oukou i na mea a pau i kauoha mai ai o Mose, ke kauwa o Iehova ia oukou, a ua hoolohe mai oukou i ko'u leo e like me na mea a pau a'u i kauoha aku ai ia oukou:
ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
3 Aole oukou i haalele i ko oukou poe hoahanau i na la a pau a hiki i neia la, aka, ua malama oukou i ka olelo i kauoha mai ai o Iehova, ko oukou Akua.
Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
4 Ano la, ua hoomaha mai o Iehova ko oukou Akua i ko oukou poe hoahanau, e like me kana olelo ana mai ia lakou; ano la, e hoi aku oukou, a e hele hou i ko oukou mau halelewa, i ka aina i loaa ia oukou, ua haawi mai o Mose, ke kauwa a Iehova ia oukou i kela kapa o Ioredane.
Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
5 Aka, e ao pono oukou, e malama i ke kauoha a me ke kanawai i kauoha mai ai o Mose, ke kauwa a Iehova ia oukou, e aloha aku ia Iehova ko oukou Akua, e hele aku ma kona aoao a pau, e malama aku hoi i kona kanawai, e hoopili aku ia ia, a e hookauwa aku hoi nana, me ko oukou naau a pau, a me ko oukou uhane a pau.
Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
6 Alaila, hoomaikai aku la o Iosua ia lakou, a hookuu aku. A hele aku la lakou i ko lakou mau halelewa.
Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
7 Ua haawi mai o Mose no kekahi ohana hapa o Manase i noho ana ma Basana; o kekahi ohana hapa hoi, haawi mai o Iosua no lakou, me ko lakou poe hoahanau, ma keia kapa o Ioredane ma ke komohana. Alaila, hoouna aku la oia ia lakou i ko lakou halelewa, a hoomaikai oia ia lakou.
(Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
8 Olelo aku la oia ia lakou, i aku la, E hoi oukou i ko oukou mau halelewa, me ka waiwai nui, a me na holoholona he nui loa, a me ke kala, a me ke gula, a me ke keleawe, a me ka hao, a me ke kapa he nui loa. E puunauwe oukou i ka waiwai pio o ko oukou poe enemi, me ko oukou hoahanau.
Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
9 A hoi aku la ka Reubena poe mamo, a me ka Gada a me ka ohaha hapa a Manase, a hele lakou, mai ka Iseraela aku, a mai Silo ma ka aina o Kanaana aku, e hele i ka aina o Gileada, i ka aina a lakou i loaa mai, ua loaa hoi ia lakou e like me ka olelo a Iehova ma ka lima o Mose.
Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
10 A hiki lakou i kahi e pili ana i Ioredane, aia ma ka aina o Kanaana, hana ae la ka Reubena poe mamo, a me ka Gada a me ka ohana hapa a Manase i kuahu malaila, ma Ioredane, ua nui kela kuahu i ka nana aku.
Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
11 A lohe ae la na mamo a Iseraela, i ka i ana mai, Aia hoi, ua hana ae la ka Reubena a me ka Gada a me ka ohana hapa a Manase i ke kuahu imua o ka aina o Kanaana, ma ke kapa o Ioredane, ma kahi e hele ae na mamo a Iseraela.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
12 A lohe na mamo a Iseraela, hoakoakoa iho la ke anaina a pau o na mamo a Iseraela ma Silo, e hele aku ia lakou e kaua aku.
gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
13 Hoouna aku la na mamo a Iseraela ia Pinehasa i ke keiki a Eleazara, ke kahuna, e hele i ka Reubena poe mamo a me ka Gada, a me ka ohana hapa a Manase i ka aina o Gileada,
Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
14 A me na'lii pu me ia he umi, pakahi ke alii i ka hale o na kupuna ma na ohana a pau a Iseraela: he poe alii wale no lakou o na kupuna, ma na tausani o ka Iseraela.
Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
15 A hele aku la lakou i ka Reubena poe mamo, a me ka Gada, a me ka ohana hapa a Manase, i ka aina i Gileada, a kamailio pu me lakou, i aku la,
Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
16 Pela ka olelo ana mai a ke anaina a pau o Iehova, Heaha keia hewa a oukou i hana aku ai i ke Akua o Iseraela, e huli i keia la, mai o Iehova aku, i ko oukou kukulu ana i kuahu no oukou iho, i kipi aku oukou i keia la ia Iehova?
“Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
17 He uuku anei ka hewa o Peora ia kakou, aole kakou i holoi aku i keia mea, mai o kakou aku, a hiki mai i keia la, he mea ia i ahulau ai ke anaina o Iehova,
Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
18 I huli ai oukou i keia la, mai o Iehova aku? a i kipi aku oukou ia Iehova i keia la, a apopo e huhu mai oia i ke anaina a pau o Iseraela.
Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
19 Aka, ina he aina haumia, ka oukou i loaa ai, e hele aku oukou i kela kapa, i ka aina a Iehova i loaa ai, i kahi e noho ana kana pahuberita; a e hoonoho oukou ia oukou iho, mawaena konu o makou. Mai kipi hoi oukou ia Iehova, mai kipi no hoi ia makou, i ko oukou kukulu ana i ke kuahu no oukou iho, okoa ke kuahu o Iehova ko kakou Akua.
Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
20 Aole anei i lawehala o Akana, ke keiki a Zera, i ka mea laa, aole anei i hiki mai ka huhu maluna o na mamo a pau a Iseraela? Aole oia wale no ka i make i kona hewa.
Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
21 Alaila, ekemu mai la ka Reubena poe mamo, a me ka Gada, a me ka ohana hapa a Manase, i mai la lakou i ka poe luna o na tausani o ka Iseraela,
Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
22 O Iehova, o ke Akua o na'kua, o Iehova, o ke Akua o na'kua, oia ka i ike, a e ike no hoi auanei ka Iseraela; ina ma ke kipi ana a me ka hana hewa ana ia Iehova, mai hoola oukou ia makou i keia la,
Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
23 Ina paha makou i kukulu i ke kuahu no makou, e huli, mai o Iehova aku, a e kaumaha maluna iho i ka mohaikuni, a me ka mohaiai, a e kaumaha maluna olaila i ka mohai aloha, na Iehova no e hoopai ia mea.
Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
24 Ina aole i hana makou pela no ka makau ana i keia mea, me ka i ana iho, Mamuli paha, e olelo mai ka oukou poe keiki i ka makou poe keiki, me ka i ana mai, Heaha ka oukou ia Iehova, ke Akua o Iseraela?
“Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
25 Ua haawi mai o Iehova ia Ioredane nei, i mokuna mawaena o kakou, e ka Reubena, a me ka Gada, aole o oukou kuleana ma o Iehova la; pela no e hooki ai ka oukou poe keiki i ka makou poe keiki i ko lakou makau ana ia Iehova.
Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
26 Olelo iho la makou, Ina kakou, e kukulu i kuahu no kakou, aole no ka mohaikuni, aole no ka alana:
“Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
27 He mea hoike ia mawaena o makou a o oukou, a mawaena o ko kakou hanauna mahope aku nei o kakou; i hana makou i ka oihana a Iehova imua ona me ko makou mohaikuni a me ko makou alana, a me ko makou mohai aloha, i olelo ole ka oukou poe keiki i ka makou poe keiki mahope aku nei, Aohe o oukou kuleana ma o Iehova la.
Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
28 Nolaila i olelo ai makou, A hiki i ka wa e i mai ai lakou pela ia makou, a i ko makou hanauna mahope aku nei o makou, e olelo makou, Ea, e nana oukou i ka mea like me ke kuahu o Iehova, i ka mea i hanaia'i e ko makou poe makua, aole no ka mohaikuni, a me ka alana, aka, i mea hoailona mawaena o makou a me oukou.
“Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
29 Aole loa makou e kipi ia Iehova, a huli, mai o Iehova aku i keia la, a kukulu i ke kuahu no ka mohaikuni a me ka mohai ai a me na alana. Ke kuahu o Iehova ko kakou Akua, ka mea imua o kona halelewa, oia wale no ke kuahu.
“Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
30 A lohe ae la o Pinehasa, ke kahuna, a me na'lii o na mamo a Iseraela, a me na luna o na tausani o ka Iseraela, i na olelo i olelo mai ai ka Reubena poe mamo, a me ka Gada, a me ka Manase, he mea maikai no ia i ko lakou mau maka.
Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
31 Olelo aku la o Pinehasa, o ke kahuna, ke keiki a Eleazara, i ka Reubena poe mamo, a i ka Gada a i ka Manase, Ua ike pono kakou i keia la, o Iehova no mawaena o kakou, aole oukou i hana hewa i keia mea. A ua hoopakele oukou i na mamo a Iseraela mai ka lima mai o Iehova.
Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
32 Alaila, hoi aku la o Pinehasa, ke kahuna, ke keiki a Eleazara, a me na'lii, mai ka Reubena poe mamo, a me ka Gada, mai ka aina o Gileada aku, i ka aina o Kanaana, i na mamo a Iseraela, a hai aku la ia lakou i keia mea.
Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
33 A he mea maikai no ia i na maka o na mamo a Iseraela; a hoomaikai aku la na mamo a Iseraela i ke Akua; aole lakou i manao e pii aku ia lakou o kaua, e luku aku i ka aina o ka Reubena poe mamo a me ka Gada i noho ai.
Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
34 Kapa aku la o ka Reubena poe mamo a me ka Gada i ke kuahu, He mea hoike keia mawaena o kakou, o Iehova no, oia ke Akua.
Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”

< Iosua 22 >