< Iosua 10 >
1 EIA hoi kekahi; a lohe o Adonizedeka, ke alii o Ierusalema, i ke pio ana o Ai ia Iosua, a me kona luku ana ia wahi; e like me kana hana ana ia Ieriko a me kona alii, pela kana hana ana ia Ai, me ko laila alii; a ua hookuikahi aku na kanaka o Gibeona me ka Iseraela, a ua noho pu me lakou;
Ní báyìí tí Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu gbọ́ pé Joṣua ti gba Ai, tí ó sì ti pa wọ́n pátápátá; tí ó sì ṣe sí Ai àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Jeriko àti ọba rẹ̀, àti bí àwọn ènìyàn Gibeoni ti ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú Israẹli, tí wọ́n sì ń gbé nítòsí wọn.
2 Makau loa oia, me kona poe, no ka mea, he kulanakanhale nui o Gibeona, me he kulanakauhale alii la, no ka mea, oia ka nui o laua o Ai, a o ko laila poe kanaka a pau, he poe koa loa.
Ìbẹ̀rù sì mú òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀ torí pé Gibeoni jẹ́ ìlú tí ó ṣe pàtàkì, bí ọ̀kan nínú àwọn ìlú ọba; ó tóbi ju Ai lọ, gbogbo ọkùnrin rẹ̀ ní ó jẹ́ jagunjagun.
3 Nolaila kii aku la o Adonizedeka, ke alii o Ierusalema, ia Hohama, i ke alii o Heberona, a ia Pirama, i ke alii o Iaremuta, a ia Iapia, i ke alii o Lakisa, a ia Debira, ke alii o Egelona, i aku la ia lakou,
Nítorí náà Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu bẹ Hohamu ọba Hebroni, Piramu ọba Jarmatu, Jafia ọba Lakiṣi àti Debiri ọba Egloni. Wí pe,
4 E hele mai oukou io'u nei, e kokua mai ia'u, i pepehi kakou i ko Gibeona; no ka mea, ua hookuikahi lakou me Iosua a me na mamo a Iseraela.
“Ẹ gòkè wá, kí ẹ sì ràn mi lọ́wọ́ láti kọlu Gibeoni, nítorí tí ó ti wà ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Joṣua àti àwọn ará Israẹli.”
5 Alaila, akoakoa mai la na'lii elima o ka Amora, o ke alii o Ierusalema, o ke alii o Heberona, o ke alii o Iaremuta, o ke alii o Lakisa, a me ke alii o Egelona, a pii aku la lakou a me ko lakou huna kau a a pau, a hoomoana iho la ma ke alo o Gibeona, a kaua aku la.
Àwọn ọba Amori márààrún, ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni, kó ara wọn jọ, wọ́n sì gòkè, àwọn àti gbogbo ogun wọn, wọ́n sì dojúkọ Gibeoni, wọ́n sì kọlù ú.
6 Hoouna koke mai la na kanaka o Gibeona ia Iosua, ma kahi ana i hoomoana'i ma Gilegala, i mai la, Mai hookaulua oe i kou lima i kau poe kauwa nei; e pii koke mai io makou nei, e hoopakele, a e kokua mai ia makou; no ka mea, ua akoakoa mai nei na'lii a pau o ka Amora, ka poe e noho ana ma na mauna, e ku e ia makou.
Àwọn ará Gibeoni sì ránṣẹ́ sí Joṣua ní ibùdó ní Gilgali pé, “Ẹ má ṣe fi ìránṣẹ́ yín sílẹ̀. Ẹ gòkè tọ̀ wà wá ní kánkán kí ẹ sì gbà wá là. Ẹ ràn wá lọ́wọ́, nítorí gbogbo àwọn ọba Amori tí ń gbé ní orílẹ̀-èdè òkè dojú ìjà kọ wá.”
7 Alaila, pii aku la o Iosua, mai Gilegala aku, oia, a me na kanaka kaua a pau pu me ia, a me ka poe koa ikaika a pau.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gòkè lọ láti Gilgali pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, àti akọni nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
8 I mai la o Iehova ia Iosua, Mai makau ia lakou; no ka mea, ua haawi au ia lakou a pau iloko o kou lima, aole loa e ku kekahi kanaka o lakou imua ou.
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, Mo ti fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́. Kò sí ẹnikẹ́ni nínú wọn ti yóò lè dojúkọ ọ́.”
9 Hiki koke aku la o Iosua ia lakou, i kona hele ana, mai Gilegala aku i ka po a ao.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wọ́de ogun ní gbogbo òru náà láti Gilgali, Joṣua sì yọ sí wọn lójijì.
10 Hooauhee aku la o Iehova ia lakou imua o ka Iseraela, a luku aku la oia ia lakou i ka make nui loa, ma Gibeona, a hahai aku la no hoi oia ia lakou, ma ke ala e hiki aku ai i Betehorona, a pepehi iho la ia lakou a hiki i Azeka, a i Makeda.
Olúwa mú kí wọn dààmú níwájú àwọn Israẹli, wọ́n sì pa wọ́n ní ìpakúpa ní Gibeoni. Israẹli sì lépa wọn ní ọ̀nà tí ó lọ sí Beti-Horoni, ó sì pa wọ́n dé Aseka, àti Makkeda.
11 A i ko lakou hee ana imua o ka Iseraela, i ko lakou iho ana i Betehorona, hoolei mai la o Iehova i na pohaku nui maluna o lakou, mai ka lani mai, a hiki i Azeka, a make lakou. Ua nui ka poe i make i ka huahekili, he hapa ka poe i make i na mamo a Iseraela, i ka pahikaua.
Bí wọ́n sì tí ń sá ní iwájú Israẹli ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ ní ọ̀nà láti Beti-Horoni títí dé Aseka, Olúwa rọ yìnyín ńlá sí wọn láti ọ̀run wá, àwọn tí ó ti ipa yìnyín kú sì pọ̀ ju àwọn tí àwọn ará Israẹli fi idà pa lọ.
12 Alaila, olelo aku la o Iosua ia Iehova, i ka la i haawi mai ai o Iehova i ka Amora na na mamo a Iseraela, i aku la ia imua o ke alo o ka Iseraela, E ka la, e kau malie oe maluna o Gibeona, a o oe hoi, e ka mahina, maluna o ke awawa o Aialona.
Ní ọjọ́ tí Olúwa fi àwọn ọmọ Amori lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sọ fún Olúwa níwájú àwọn ará Israẹli, “Ìwọ oòrùn, dúró jẹ́ẹ́ ní orí Gibeoni, Ìwọ òṣùpá, dúró jẹ́ẹ́ lórí àfonífojì Aijaloni.”
13 Kau malie iho la ka la, a ku malie no hoi ka mahina, a hoopai aku la na kanaka i ko lakou, poe enemi. Aole anei keia ka mea i palapalaia ma ka buke a Iasera? Kau malie no ka la mawaena o ka lani, aole i hoomau i kona hele a pau ka la hookahi.
Bẹ́ẹ̀ ni oòrùn náà sì dúró jẹ́ẹ́, òṣùpá náà sì dúró, títí tí ìlú náà fi gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú ìwé Jaṣari. Oòrùn sì dúró ní agbede-méjì ọ̀run, kò sì wọ̀ ní ìwọ̀n odindi ọjọ́ kan.
14 Aole la e like me ia mamua, aole hoi mahope, i lohe ai o Iehova i ka leo o ke kanaka; no ka mea, kaua maoli no o Iehova mamuli o ka Iseraela.
Kò sí ọjọ́ tí o dàbí rẹ̀ ṣáájú tàbí ní ẹ̀yìn rẹ̀, ọjọ́ tí Olúwa gbọ́ ohùn ènìyàn. Dájúdájú Olúwa jà fún Israẹli!
15 Hoi mai la o Iosua a me ka Iseraela a pau pu me ia, a i kahi i hoomoana'i ma Gilegala.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli padà sí ibùdó ní Gilgali.
16 Holo aku la ua mau alii nei elima, a pee iho la iloko o ke ana ma Makeda.
Ní báyìí àwọn ọba Amori márùn-ún ti sálọ, wọ́n sì fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta kan ní Makkeda,
17 Ua haiia mai ia Iosua, i ka i ana mai, Ua loaa na'lii elima, ua pee lakou iloko o kekahi ana aia ma Makeda.
nígbà tí wọ́n sọ fún Joṣua pé, a ti rí àwọn ọba márààrún, ti ó fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta ní Makkeda,
18 I aku la o Iosua, E olokaa i mau pohaku nui ma ka waha o ke ana, a e hoonoho i mau kanaka e kiai ia lakou:
ó sì wí pé, “Ẹ yí òkúta ńlá dí ẹnu ihò àpáta náà, kí ẹ sì yan àwọn ọkùnrin sí ibẹ̀ láti ṣọ́ ọ.
19 Mai kakali oukou, e hahai oukou i ko oukou poe enemi, a e pepehi i ko lakou hopena. Mai kuu aku ia lakou e komo iloko o ko lakou mau kulanakauhale; no ka mea, na Iehova ko oukou Akua i haawi mai ia lakou i ko oukou lima.
Ṣùgbọ́n, ẹ má ṣe dúró! Ẹ lépa àwọn ọ̀tá yín, ẹ kọlù wọ́n láti ẹ̀yìn, kí ẹ má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó dé ìlú wọn, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
20 Luku aku la o Iosua a me na mamo a Iseraela ia lakou i ka make nui loa, a oki loa iho la lakou, alaiia, holo aku la ke koena o lakou a komo iloko o na kulanakauhale i paa i ka pa.
Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli pa wọ́n ní ìpakúpa wọ́n sì pa gbogbo ọmọ-ogun àwọn ọba márààrún run, àyàfi àwọn díẹ̀ tí wọ́n tiraka láti dé ìlú olódi wọn.
21 Hoi maluhia mai la na kanaka a pau i kahi a lakou i hoomoana'i, io Iosua la, ma Makeda. Aole loa i hookala kekahi i kona alelo i na mamo a Iseraela.
Gbogbo àwọn ọmọ-ogun sì padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní ibùdó ogun ní Makkeda ní àlàáfíà, kò sí àwọn tí ó dábàá láti tún kọlu Israẹli.
22 I aku la o Iosua, E wehe i ka waha o ke ana, a e lawe mai iwaho io u nei, i ua mau alii la elima, mai ke aua mai.
Joṣua sì wí pe, “Ẹ ṣí ẹnu ihò náà, kí ẹ sì mú àwọn ọba márààrún jáde wá fún mi.”
23 Hana iho la no lakou pela, a lawe mai la i ua mau alii la elima io na la, mai ke ana mai; o ke alii o Ierusalema, a me ke alii o Heberona, a me ke alii o Iaremuta, a me ke alii o Lakisa, a me ke alii o Egelona.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú àwọn ọba márààrún náà kúrò nínú ihò àpáta, àwọn ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni.
24 A i ka wa i lawe mai ai lakou i ua mau alii nei io Iosua la, alaila, hea aku la o Iosua i kanaka a pau o ka Iseraela, i aku la i na alihi o ka poe koa, i hele pu me ia, E neenee mai oukou, a e hehi ko oukou kapuwai maluna o na a-i o keia poe alii. Neenee mai la lakou a hehi aku la ko lakou kapuwai, maluna o ko lakou mau a-i.
Nígbà tí wọ́n mú àwọn ọba náà tọ Joṣua wá, ó pe gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli, ó sì sọ fún àwọn olórí ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ bí, kí ẹ sì fi ẹsẹ̀ yín lé ọrùn àwọn ọba wọ̀nyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wá sí iwájú, wọ́n sì gbé ẹsẹ̀ lé ọrùn wọn.
25 I aku la o Iosua ia lakou, Mai makau oukou, aole hoi e weliweli; e ikaika oukou, a e koa hoi, no ka mea, pela no e hana mai ai o Iehova i na euemi a pau a oukou e kaua aku ai.
Joṣua sì sọ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ ṣe gírí, kí ẹ sì mú àyà le. Báyìí ni Olúwa yóò ṣe sí gbogbo àwọn ọ̀tá yín, tí ẹ̀yin yóò bá jà.”
26 A mahope iho, luku aku la o Iosua ia lakou a pepehi iho la, a kaawe ae la ma na laau elima; a e kaulia ana no lakou ma na laau, a hiki i ke ahiahi.
Nígbà náà ni Joṣua kọlù wọ́n, ó sì pa àwọn ọba márààrún náà, ó sì so wọ́n rọ̀ ní orí igi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ márùn-ún, wọ́n sì fi wọ́n sí orí igi títí di ìrọ̀lẹ́.
27 A hiki i ka manawa i napoo ai ka la, kauoha ae la o Iosua, e kuu ia lakou mailuua iho o na laau, a e kiola ia lakou iloko o ke ana, ma kahi a lakou i pee aku ai; a waiho aku la i na pohaku nui ma ka waha o ke ana, a hiki loa mai i neia la.
Nígbà tí oòrùn wọ̀, Joṣua pàṣẹ, wọ́n sì sọ̀ wọ́n kalẹ̀ kúrò ní orí igi, wọ́n sì gbé wọn jù sí inú ihò àpáta ní ibi tí wọ́n sá pamọ́ sí. Wọ́n sì fi òkúta ńlá dí ẹnu ihò náà, tí ó sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
28 Ia la no i hoopio ai o Iosua ia Makeda, a luku aku la me ka maka o ka pahikaua, a pepehi aku la i ko laila alii a make loa, o lakou, a me ko laila kanaka a pau, aole ia i waiho i kekahi koena. Hana aku la ia i ko laila alii, e like me ia i hana aku ai i ke alii o Ieriko.
Ní ọjọ́ náà Joṣua gba Makkeda. Ó sì fi ojú idà kọlu ìlú náà àti ọba rẹ̀, ó sì run gbogbo wọn pátápátá, kò fi ẹnìkan sílẹ̀. Ó sì ṣe sí ọba Makkeda gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe sí ọba Jeriko.
29 Hele aku la o Iosua, a me ka Iseraela a pau pu me ia, mai Makeda aku a hiki i Libena, a kaua aku la ia Libena.
Nígbà náà ní Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Makkeda lọ sí Libina wọ́n sì kọlù ú.
30 Haawi mai no hoi o Iehova ia wahi a me ko laila alii a me ko laila poe kanaka a pau, i ka lima o ka Iseraela, a luku aku la oia ia wahi ma ka maka o ka pahikaua; aole ia i waiho i koena ma ia wahi. Hana aku no hoi ia i ko laila alii e like me ia i hana aku ai i ke alii o Ieriko.
Olúwa sì fi ìlú náà àti ọba rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́. Ìlú náà àti gbogbo àwọn ènìyàn ibẹ̀ ni Joṣua fi idà pa. Kò fi ẹnìkan sílẹ̀ ní ibẹ̀: Ó sì ṣe sí ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí ọba Jeriko.
31 Hele aku la o Iosua, a me ka Iseraela a pau pu me ia mai Libena aku a Lakisa, hoomoana iho la ma ke alo o ia wahi, a kaua aku la.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo ará Israẹli, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Libina lọ sí Lakiṣi; ó sì dó tì í, ó sì kọlù ú.
32 Haawi mai la o Iehova ia Lakisa i ka lima o ka Iseraela, a i ka lua o ka la, hoopio iho la oia ia wahi a luku aku la ia wahi ma ka maka o ka pahikaua, a me na kanaka a pau ma ia wahi, e like me na mea a pau ana i hana aku ai ia Libena.
Olúwa sì fi Lakiṣi lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sì gbà á ní ọjọ́ kejì. Ìlú náà àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀ ní ó fi idà pa gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Libina.
33 Alaila, hele ae la o Horama, ke alii o Gezera, e kokua mamuli o Lakisa. Luku aku la o Iosua ia ia, a me kona kanaka, a pau loa lakou i ka make, aole i koe.
Ní àkókò yìí, Horamu ọba Geseri gòkè láti ran Lakiṣi lọ́wọ́, ṣùgbọ́n Joṣua ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ títí ti kò fi ku ẹnìkan sílẹ̀.
34 Hele aku la o Iosua a me ka Iseraela a pau pu me ia, mai Lakisa aku a Egelona, a hoomoana iho la ma ke alo o ia wahi, a kaua aku la ia ia.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Lakiṣi lọ sí Egloni; wọ́n sì dó tì í, wọ́n sì kọlù ú.
35 Hoopio iho la lakou ia wahi ia la no, a luku aku la ia wahi ma ka maka o ka pahikaua, a me ko laila kanaka a pau, luku loa aku la ia, e like me na mea a pau ana i hana aku ai ia Lakisa.
Wọ́n gbà á ní ọjọ́ náà, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì run gbogbo ènìyàn ibẹ̀ pátápátá, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe sí Lakiṣi.
36 Hele aku la o Iosua, a me ka Iseraela a pau pu me ia, mai Egelona aku a Heberona, a kaua aku la ia wahi.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli ṣí láti Egloni lọ sí Hebroni, wọ́n sì kọlù ú.
37 Hoopio iho la lakou ia wahi, a luku aku la ma ka maka o ka pahikaua, a me ko laila alii, a me ko laila kulanakauhale a pau, a me ko laila kanaka a pau; aole ia i waiho i koena, e like me na mea a pau ana i hana aku ai ia Egelona. Hooki loa iho la oia ia wahi a me ko laila kanaka a pau.
Wọ́n gba ìlú náà, wọ́n sì ti idà bọ̀ ọ́, pẹ̀lú ọba rẹ̀, gbogbo ìletò wọn àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀. Wọn kò dá ẹnìkan sí. Gẹ́gẹ́ bí ti Egloni, wọ́n run un pátápátá àti gbogbo ènìyàn inú rẹ̀.
38 Hoi mai la o Iosua a me ka Iseraela a pau pu me ia, a i Debira, a kaua ae la ia wahi;
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ yí padà, wọ́n sì kọlu Debiri.
39 A hoopio iho la, a me ko laila alii, a me ko laila kulanakauhale a pau, a luku aku la ia lakou ma ka maka o ka pahikaua, a hooki loa iho la ia i kanaka a pau o ia wahi, aole i waiho i koena; e like me ia i hana aku ai ia Heberona, pela no ia i hana'i ia Debira, a me kona alii, e like hoi me ia i hana'i ia Libena, a me kona alii.
Wọ́n gba ìlú náà, ọba rẹ̀ àti gbogbo ìlú wọn, wọ́n sì fi idà pa wọ́n. Gbogbo ènìyàn inú rẹ̀ ni wọ́n parun pátápátá. Wọn kò sì dá ẹnìkankan sí. Wọ́n ṣe sí Debiri àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wọn ti ṣe sí Libina àti ọba rẹ̀ àti sí Hebroni.
40 Luku aku la o Iosua i ka aina mauna a pau, a ma ka lima hema, a ma kahi papu, a ma kahi haahaa, a me ko laila poe alii a pau. Aole ia i waiho i kekahi koena. Hooki loa iho la ia i na mea hanu a pau, e like me ke kauoha ana mai o Iehova ke Akua o ka Iseraela.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ṣẹ́gun gbogbo agbègbè náà, ìlú òkè, gúúsù, ìlú ẹsẹ̀ òkè ti ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè pẹ̀lú gbogbo ọba, wọn kò dá ẹnìkankan sí. Ó pa gbogbo ohun alààyè run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti pàṣẹ.
41 Luku aku la o Iosua ia lakou, mai Kadesabanea a hiki i Gaza, a me ka aina a pau o Gosena a hiki loa i Gibeona.
Joṣua sì ṣẹ́gun wọn láti Kadeṣi-Barnea sí Gasa àti láti gbogbo agbègbè Goṣeni lọ sí Gibeoni.
42 Hoopio iho la o Iosua i keia poe alii a pau, a me ko lakou aina, i kela wa hookahi no, no ka mea, na Iehova no, ke Akua o ka Iseraela, i kaua mai mamuli o ka Iseraela.
Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí àti ilẹ̀ wọn ní Joṣua ṣẹ́gun ní ìwọ́de ogun ẹ̀ẹ̀kan, nítorí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, jà fún Israẹli.
43 Hoi mai la o Iosua, a me ka Iseraela a pau pu me ia, a hiki i kahi a lakou i hoomoana'i ma Gilegala.
Nígbà náà ni Joṣua padà sí ibùdó ní Gilgali pẹ̀lú gbogbo Israẹli.