< Ieremia 5 >
1 E HOLOHOLO oukou ma na alanui o Ierusalema, a e nana, a e hoomaopopo, a e imi ma kolaila wahi akea, ina paha e loaa ia oukou ke kanaka, ina he mea hana i ka pono, a imi i ka oiaio; a na'u e kala aku i ka hala ona.
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
2 A ina paha lakou e olelo, Ke ola la no Iehova; malaila no lakou i hoohiki wahahee ai.
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 E Iehova e, aole anei kou mau maka ma ka oiaio? Ua hahau no oe ia lakou, aole nae lakou i uwe. Ua hoopau no oe ia lakou, aka, ua hoole lakou, aole lakou e hoonaauao: a ua hana lakou i ko lakou maka a oi ka paakiki i ko ka pohaku; ua hoole lakou, aole e hoi mai.
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 A olelo no hoi au, He poe ilihune lakou, ua naaupo hoi; no ka mea, aole lakou i ike i ka aoao o Iehova, aole hoi i ka pono o ko lakou Akua.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 E hele aku no au i na kanaka koikoi, a e olelo aku ia lakou; no ka mea, ua ike lakou i ka aoao o Iehova, i ka pono hoi o ko lakou Akua: aka, o keia poe, ua uhaki loa lakou i ka auamo, ua moku ia lakou na kaula e paa ai.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
6 Nolaila, na ka liona mai ka ululaau mai e luku ia lakou, a na ka iliohae o ke ahiahi e anai ia lakou; a na ka leopadi e kiai i ko lakou mau kulanakauhale: o kela mea keia mea o lakou e puka aku iwaho, e haehaeia no; no ka mea, ua nui loa ka lakou hana hewa ana, a ua hoomahuahuaia ko lakou hoihope ana.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 Pehea la wau e kala'i i keia hewa nou? Ua haalele kau mau keiki ia'u, a ua hoohiki lakou ma na mea akua ole. Hanai aku la au ia lakou a maona, alaila, moe kolohe iho la lakou, a hoakoakoa lakou me ka lehulehu ma na hale o na wahine hookamakama.
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 Holoholo lakou e like me na lio i hanai maikai ia; uhuuhu kela mea keia mea o lakou i ka wahine a kona hoalauna.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 Aole anei au e hoopai i keia mau mea? wahi a Iehova. Aole anei e ko ka inaina o kuu uhane i ka lahuikanaka e like me neia?
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 E pii aku oukou maluna o kona mau pa, a e luku aku; mai hooki loa nae; e lawe aku i kona mau puupuu kaua, no ka mea, aole no Iehova ia mau mea.
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 No ka mea, ua hana wahahee loa mai ia'u ko ka hale o ka Iseraela, a me ko ka hale o Iuda, wahi a Iehova.
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
12 Ua hoole lakou ia Iehova, a ua olelo iho, Aole ia, aole e hiki mai ka hewa maluna o makou, aole hoi e ike makou i ka pahikaua, a me ka wi.
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 A e lilo auanei na kaula i makani, aole iloko o lakou ka olelo; pela e hanaia'i io lakou la.
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 Nolaila, ke olelo mai nei o Iehova, ke Akua o na kaua, peneia, No ka oukou olelo ana i keia olelo, aia hoi, e hoolilo no wau i ka'u mau olelo iloko o kou waha, i ahi, a o keia poe kanaka i wahie, a e hoopau ia ia lakou.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Aia hoi, e lawe mai no wau maluna o oukou, e ko ka hale o ka Iseraela, i ka lahuikanaka, mai kahi mamao aku mai, wahi a Iehova; he lahuikanaka ikaika, he lahuikanaka kahiko, he lahuikanaka, aole oe i ike i ka lakou olelo, aole hoi i hoomaopopo i ka mea a lakou e olelo mai ai.
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 O ko lakou aapua, he lua kupapau hamama ia, he poe kanaka ikaika lakou a pau.
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 A e ai no lakou i kau ai, a me kau palaoa i hoiliiliia i mea na kau poe keiki kane, a na kau poo kaikamahine e ai ai: e ai no lakou i kau poe hipa, a me kau poe bipi; e ai no lakou i kou mau kumuwaina, a me kou laau fiku; e anai aku no lakou ma ka pahikaua, i kou mau kulanakauhale i paa i ka pa, i na mea au i hilinai ai.
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 Aka, i kela mau la, wahi a Iehova, aole au e hooki loa ia oukou.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
19 A i ka wa e olelo mai ai oukou, No ke aha la i hana mai ai o Iehova, ko makou Akua, i keia mau mea a pau ia makou? Alaila, e i aku oe ia lakou, E like me oukou i haalele mai ai ia'u, a hookauwa aku na na akua e, ma ko oukou aina, pela no oukou e hookanwa aku ai na na kanaka e, ma ka aina aole no oukou.
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 E hai aku i keia maloko o ka hale o ka Iakoba, a e hoolaha aku hoi ma ka Iuda, e i aku,
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 E hoolohe mai oukou i keia, e ka lahuikanaka lapuwale, a naauao ole; ka poe mea maka, a ike ole, ka poe mea pepeiao, a lohe ole;
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Aole anei oukou e makau mai ia'u? wahi a Iehova; aole anei oukou e haalulu imua o ko'u alo, ka mea i hoonoho i ke one i mokuna no ke kai, mamuli o ka manao paa mau loa, i pii ole ia a kela aoao: a ina hooleilei kona mau ale, aole hiki ia lakou ke pii, a ina halulu mai, aole no lakou e hele mai i keia aoao?
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 Aka, o keia poe kanaka, he naau kipi ku e ko lakou; ua kipi no lakou, a ua lilo.
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 Aole nae lakou i olelo ma ko lakou naau, Ano, e makau aku kakou ia Iehova, i ko kakou Akua, i ka mea i haawi mai i ka ua, i ka ua mua, a me ka ua hope i kona manawa pono; a hookoe hoi no kakou i na hobedoma e hoiliili ai.
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Na ko oukou hewa i hoohuli aku i keia mau mea, a na ko oukou hala i hoopaa i na mea maikai, i loaa ole ia oukou.
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 Ua loaa no na mea hewa iwaena o ko'u poe kanaka; kiai malu lakou, e like me ke kulou ana o ka mea hoopahele manu; kau no lakou i ka upiki, a paa no na kanaka ia lakou.
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 E like me na hinai manu i piha i na manu, pela no ka piha ana o ko lakou hale i ka wahahee; nolaila lakou i nui ai, a ua waiwai hoi.
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 Ua momona ae nei lakou, ua hinuhinu hoi; oia, ua hele lakou, a ua pakela mamua o ka hana ana a ka poe hewa; aole lakou i kokua i ka pono, i ka pono hoi o na keiki makua ole, ua pomaikai nae lakou; aole lakou i hoopono ma ka hoopii ana o ka poe kaumaha.
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Aole anei au e hoopai i keia mau mea? wahi a Iehova; aole anei e ko ka ukiuki o kuu uhane i ka lahuikanaka e like me keia?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 Ua hanaia ka mea kupanaha ma ka aina, a he mea haumia loa hoi;
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 Wanana wahahee mai na kaula, a ma o lakou la i noho alii ai na kahuna; a ua makemake ko'u poe kanaka ia mea; a pehea hoi oukou e hana'i i ka hopena o ia mea?
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?