< Ieremia 42 >

1 A LAILA, hookokoke mai la na luna o ka poe koa, a me Iohanana, ke keiki a Karea, a me Iezania, ke keiki a Hosaia, a me na kanaka a pau, mai ka mea uuku a ka mea nui,
Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
2 A olelo mai la lakou ia Ieremia i ke kaula, Ke noi aku nei makou ia oe e ae mai i ka haule ana o ko makou nonoi imua ou, a e pule aku hoi ia Iehova, i kou Akua no makou, no keia koena a pau; (no ka mea, ua koe mai makou, he poe uuku noloko mai o na mea nui, e like me ka ike ana o kou mau maka ia makou; )
Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
3 I hoike mai ai o Iehova, kou Akua ia makou i ke ala e pono ai makou ke hele, a i ka mea hoi e pono ai makou ke hana.
Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
4 Alaila, olelo aku la o Ieremia, ke kaula ia lakou, Ua lohe an, aia hoi, e pule no wau ia Iehova, i ko oukou Akua, e like me na olelo a oukou; a o ka mea a Iehova e olelo mai ia oukou, oia ka'u e hai aku ai ia oukou; aole au e huna i kekahi mea ia oukou.
Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
5 Alaila, olelo mai la lakou ia Ieremia, O Iehova no ka mea hoike oiaio, a pono iwaena o kakou, ke hana ole makou e like me na mea a pau a Iehova e hoouna mai ai ia oe io makou nei;
Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
6 Ina he maikai, a ina he hewa, e hoolohe no makou i ka leo o Iehova ko makou Akua, ka mea ia ia makou e hoouna aku ai ia oe, i pomaikai ai makou i ka wa e hoolohe ai makou i ka leo o Iehova ko makou Akua.
Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
7 A mahope iho o na la he umi, alaila hiki mai ka olelo a Iehova ia Ieremia.
Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
8 Alaila, hea aku oia ia Iohanana, i ke keiki a Karea, a me na luna a pau o na koa, e noho pu ana me ia, a me na kanaka a pau, mai ka mea uuku, a ka mea nui;
O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
9 I mai la oia ia lakou, Ke olelo mai nei o Iehova ke Akua o ka Iseraela, ka mea ia ia oukou i h ouna aku ai ia'u, e hookau i ko oukou nonoi ana imua ona;
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
10 Ina e noho oukou ma keia aina, alaila, e kukulu no wau ia oukou, aole e hoohiolo, e hoonipaa loa wau ia oukou, aole au e uhuki; no ka mea, na mihi au i ka ino a'u i hana aku ai ia oukou.
Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
11 Mai makau i ke alii o Babulona, i ka mea a oukou e makau nei; mai makau ia ia, wahi a Iehova; no ka mea, owau pu me oukou e hoola ia oukou, a e hoopakele hoi ia oukou mai kona lima aku.
Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
12 A e hoike aku au i ka lokomaikai ia oukou, i lokomaikai ai oia ia oukou, a hoihoi mai ia oukou i ko oukou aina iho.
Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
13 Aka, ina olelo oukou, Aole makou e noho ma keia aina, aole hoi e hoolohe i ka leo o Iehova, ko oukou Akua;
“Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
14 A olelo hoi, Aole; e hele no makou i ka aina o Aigupita, ma kahi e ike ole ai makou i ke kaua, aole hoi e lohe i ke kani ana o ka pu, aole hoi e pololi i ka berena; a malaila no makou e noho ai;
Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
15 No ia mea la, ea, e hoolohe oukou i ka olelo a Iehova, e ke koena o ka Iuda; Ke i mai nei o Iehova o na kaua, ke Akua o ka Iseraela, Ina ikaika ke kau ana o ko oukou maka e hele i Aigupita, e hele hoi a noho malaila;
nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
16 Alaila, e hiki mai no keia, o ka pahikaua a oukou i makau ai, e loaa no ia oukou ia malaila, ma ka aina o Aigupita; a o ka wi, ka mea a oukou i makau ai, e pipili no ia ia oukou malaila, ma Aigupita, a malaila oukou e make ai.
Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
17 E hiki no ia i na kanaka a pau e kau ana i ko lakou maka e hele i Aigupita e noho malaila: e make no lakou i ka pahikaua, a i ka wi, a i ka mai ahulau; aohe mea e koe, aole hoi e pakele i ka hewa a'u e lawe ai maluna o lakou.
Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
18 No ka mea, ke olelo mai nei o Iehova o na kaua, ke Akua o ka Iseraela, E like me ka ninini ana o ko'u huhu, a me ko'u ukiuki maluna o ka poe e noho la ma Ierusalema: pela no e nininiia'i ko'u ukiuki maluna o oukou. i ka wa e hiki aku ai oukou iloko o Aigupita; a e lilo oukou i mea hailiiliia, a i mea e kahaha'i, a i mea poino, a i mea hoowahawahaia; aole hoi oukou e ike hou mai i keia wahi.
Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
19 Ua olelo no o Iehova no oukou, E, oukou ke koena o ka Iuda, Mai hele oukou i Aigupita; e ike pono oukou, ua hoike aku au ia oukou i keia la.
“Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
20 Ua hele hewa oukou e pilikia ai ko oukou ola, i ka wa i hoouna aku ai oukou ia'u io Iehova la, i ko oukou Akua, i ka i ana mai la, E pule aku oe ia Iehova i ko makou Akua no makou; a e like me na mea a pau a Iehova, ko makou Akua e olelo mai ai, pela no oe e hai mai ia makou, a e hana no makou.
pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
21 A ua hai aku au ia oukou i keia la; aole oukou i hoolohe i ka leo o Iehova o ko oukou Akua, aole ma kekahi mea ana i hoouna mai ai ia'u, io oukou la.
Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
22 No ia mea la, ea, e ike pono oukou, e make oukou i ka pahikaua, a i ka wi, a i ka mai ahulau, ma kahi a oukou e makemake ai e hele, a e noho.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”

< Ieremia 42 >