< Ieremia 36 >

1 I KA makahiki eha o Iehoiakima, ke keiki a Iosia, ke alii o ka Iuda, hiki mai keia olelo io Ieremia la, mai Iehova mai, i mai la,
Ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé:
2 E lawe oe i owili palapala nau, a e kakau iloko i na olelo a pau a'u i olelo aku ai ia oe no ka Iseraela, a no ka Iuda, a no na lahuikanaka a pau, mai na la mai a'u i olelo aku ai ia oe, mai na la mai o Iosia, a hiki mai i keia la.
“Mú ìwé kíká fún ará rẹ, kí o sì kọ sínú rẹ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ nípa Israẹli àti ti Juda, àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè láti ìgbà tí mo ti sọ fún ọ láti ọjọ́ Josiah títí di òní.
3 E lohe auanei paha ko ka hale o ka Iuda i ka hewa a pau a'u e manao nei e hana aku ai ia lakou; a nolaila e huli kela kanaka keia kanaka mai kona aoao hewa mai, i kala aku ai au i ko lakou hala, a me ko lakou hewa.
Ó lè jẹ́ wí pé ilé Juda yóò gbọ́ gbogbo ibi tí mo ti pinnu láti ṣe fún wọn; kí wọn kí ó sì yípadà, olúkúlùkù wọn kúrò ní ọ̀nà búburú rẹ̀. Kí èmi kí ó lè dárí àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n.”
4 Alaila, hea ae la o Ieremia ia Baruka, i ke keiki a Neria, a kakau iho la o Baruka, mai ka waha mai o Ieremia, i na olelo a pau a Iehova ana i olelo ai ia ia.
Nígbà náà ni Jeremiah pe Baruku ọmọ Neriah, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run bá a sọ fún, Baruku sì kọ láti ẹnu Jeremiah, gbogbo ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ fún un sórí ìwé kíká náà.
5 A kauoha ae la o Ieremia ia Baruka, i ae la, Ua paa wau, aole hiki ia'u ke hele iloko o ka hale o Iehova;
Nígbà náà ni Jeremiah wí fún Baruku pé, “A sé mi mọ́! Èmi kò lè lọ sí ilé Olúwa.
6 Nolaila, o hele oe e heluhelu i ka owili au i kakau ai mamuli o ko'u waha, i na olelo hoi a Iehova ma na pepeiao o na kanaka maloko o ka hale o Iehova, i ka la e hookeai ai. A e heluhelu no hoi oe ia ma na pepeiao o ka Iuda a pau i hele mai, mailoko mai o ko lakou mau kulanakauhale.
Nítorí náà, ìwọ lọ sí ilé Olúwa ní ọjọ́ àwẹ̀, kí o sì kà nínú ìwé kíká náà ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ ti ẹnu mi kọ; ìwọ ó sì kà á ní etí gbogbo Juda, tí wọ́n jáde wá láti ìlú wọn.
7 Ina paha e nonoi lakou ia Iehova, a huli kela mea keia mea, mai koua aoao hewa mai. No ka mea, ua nui ka huhu a me ka inaina a Iehova i hai aku ai ia lakou.
Ó lè jẹ́ pé, ẹ̀bẹ̀ wọn yóò wá sí iwájú Olúwa, wọ́n ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn; nítorí pé títóbi ni ìbínú àti ìrunú tí Olúwa ti sọ sí àwọn ènìyàn yìí.”
8 A hana iho la o Baruka ke keiki a Neria, e like me na mea a pau a Ieremia, ke kaula i kauoha mai ai ia ia, e heluhelu ana ma ka palapala, i na olelo a pau a Iehova maloko o ka hale o Iehova.
Baruku ọmọ Neriah sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí wòlíì Jeremiah sọ fún, láti ka ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé ní ilé Olúwa.
9 A i ka makahiki elima o Iehoiakima, ke keiki a Iosia, ke alii o ka Iuda, i ka iwa o ka malama, kala ae la lakou i ka hookeai o na kanaka a pau ma Ierusalema imua o Iehova, a o na kanaka a pau i hele mai i Ierusalema, mai na kalanakauhale o ka Iuda mai.
Ní oṣù kẹsànán ọdún karùn-ún Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda ni wọ́n kéde àwẹ̀ níwájú Olúwa fún gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu àti fún gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wá láti ìlú Juda.
10 Alaila, heluhelu aku la o Baruka maloko o ka buke, i na olelo a pau a Ieremia, iloko o ka hale o Iehova, maloko o ke keena o Gemaria ke keiki a Sapana, ke kakauolelo, ma ke kahua maluna, ma ke komo ana o ka pukapa hou o ka hale o Iehova, ma na pepeiao o na kanaka a pau.
Láti inú yàrá Gemariah ọmọ Ṣafani akọ̀wé, ní àgbàlá òkè níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tuntun. Baruku sì ka ọ̀rọ̀ Jeremiah láti inú ìwé ní ilé Olúwa sí etí gbogbo ènìyàn.
11 A lohe o Mikaia, ke keiki a Gemaria ke keiki a Sapana, i na olelo a pau a Iehova maloko mai o ka buke;
Nígbà tí Mikaiah ọmọ Gemariah ọmọ Ṣafani gbọ́ gbogbo àkọsílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa láti inú ìwé náà;
12 Alaila, iho iho la ia ilalo i ka hale o ke alii, i ke keena o ke kakauolelo. Aia hoi, e noho ana na'lii a pau malaila, o Elisama ke kakauolelo, o Delaia ke keiki a Semaia, o Elenatana ke keiki a Akebora, o Gemaria ke keiki a Sapana, a me Zedekia ke keiki o Hanenia, a me na'lii a pau.
Ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé ọba sínú yàrá akọ̀wé; níbi tí gbogbo àwọn ìjòyè gbé jókòó sí: Eliṣama akọ̀wé, Delaiah ọmọ Ṣemaiah, Elnatani ọmọ Akbori, Gemariah ọmọ Ṣafani àti Sedekiah ọmọ Hananiah àti gbogbo àwọn ìjòyè.
13 Alaila, hai ae la o Mikaia ia lakou i na olelo a pau ana i lohe ai, ia Baruka i heluhelu ai i ka buke ma na pepeiao o na kanaka.
Lẹ́yìn tí Mikaiah sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí o ti gbọ́ fún wọn, nígbà tí Baruku kà láti inú ìwé kíkà náà ní etí àwọn ènìyàn.
14 Hoouna aku la na'lii a pau ia Iehudi, ke keiki a Netania, ke keiki a Selemia, ke keiki a Kusi, io Baruka la, i aku la, E lawe oe ma kou lima i ka owili, ka mea au i heluhelu ai ma na pepeiao o na kanaka, a e hele mai. Alaila, lawe iho la o Baruka, ke keiki a Neria i ka owili ma kona lima, a hele ae la io lakou la.
Gbogbo àwọn ìjòyè sì rán Jehudu ọmọ Netaniah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Kuṣi sí Baruku wí pé, mú ìwé kíká náà ní ọwọ́ rẹ láti inú èyí tí ìwọ kà ní etí àwọn ènìyàn; kí o si wá. Nígbà náà ni Baruku ọmọ Neriah wá sí ọ̀dọ̀ wọn pẹ̀lú ìwé kíká ní ọwọ́ rẹ̀.
15 I mai la lakou ia ia, E noho iho oe, a e heluhelu mai ia mea ma ko makou pepeiao. Heluhelu iho la o Baruka ma ko lakou pepeiao.
Wọ́n sì wí fún pé, “Jókòó, jọ̀wọ́ kà á sí etí wa!” Nígbà náà ni Baruku sì kà á ní etí wọn.
16 A i ko lakou lohe ana i na oleie a pau, makau ae la lakou, o kekahi, a me kekahi, a olelo mai la ia Baruka, Oiaio no e hai aku no makou i ke alii i keia mau olelo a pau.
Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ náà tan; wọ́n ń wo ara wọn lójú pẹ̀lú ẹ̀rù. Wọ́n sì wí fún Baruku pé, “Àwa gbọdọ̀ jábọ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún ọba.”
17 Ninau mai la lakou ia Baruka, i mai la, E hai mai oe, ea, pehea kau kakau ana i keia mau olelo a pau na kona waha?
Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Baruku pé, “Sọ fún wa báwo ni o ṣe kọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí? Ṣé Jeremiah ló sọ wọ́n?”
18 Alaila, hai aku la o Baruka ia lakou, Nana no i olelo mai ia'u i keia mau olelo a pau ma kona waha, a na'u no i kakau i ka inika ma ka buke.
Baruku sì dá wọn lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, láti ẹnu rẹ̀ ni, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ báyìí fún mi, èmi sì fi tàdáwà kọ wọ́n sínú ìwé náà.”
19 Alaila, olelo mai la na'lii ia Baruka, o hele, a pee, o oe, a me Ieremia. Mai hoike i kekahi kanaka i kahi o olua.
Nígbà náà ni àwọn ìjòyè sọ fún Baruku wí pé, “Lọ fi ara rẹ pamọ́ àti Jeremiah, má sì ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ibi tí ẹ̀yin wà.”
20 A komo aku la lakou iloko i ke alii maloko o ke kahua, ua kau aku la nae lakou i ka owili maloko o ke keena o Eliasama, ke kakauolelo, a hai aku la lakou i na olelo a pau ma na pepeiao o ke alii.
Lẹ́yìn tí wọ́n fi ìwé kíká náà pamọ́ sí iyàrá Eliṣama akọ̀wé, wọ́n sì wọlé tọ ọba lọ nínú àgbàlá, wọ́n sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà ní etí ọba.
21 Alaila hoouna ae la ke alii ia Iehudi e lawe mai i ka owili; a lawe ae la oia ia mea mailoko aku o ke keena o Elisama, ke kakauolelo. A heluhelu iho la o Iehudi ia mea ma na pepeiao o ke alii, a ma na pepeiao o na'lii a pau e ku pu ana me ke alii.
Ọba sì rán Jehudu láti lọ mú ìwé kíká náà wá, Jehudu sì mu jáde láti inú iyàrá Eliṣama akọ̀wé. Ó sì ka ìwé náà ní etí ọba àti ní etí gbogbo àwọn ìjòyè tí ó dúró ti ọba.
22 E noho ana no ke alii maloko o ka hale hoilo, i ka malama eiwa; a e a ana ke ahi ma ka ipu ahi imua ona.
Ó sì jẹ́ ìgbà òtútù nínú oṣù kẹsànán, ọba sì jókòó ní ẹ̀bá iná ààrò, iná náà sì ń jó ní iwájú rẹ̀.
23 A heluhelu o Iehudi i ekolu, a i eha paha lalani, alaila, okioki ae la oia ia mea i ka pahipeni, a hoolei aku la iloko o ke ahi ma ka ipu ahi, a pau ka owili i ke ahi maluna o ka ipu ahi.
Nígbà tí Jehudu ka ojú ìwé mẹ́ta sí mẹ́rin nínú ìwé náà, ọba fi ọ̀bẹ gé ìwé, ó sì sọ sínú iná tí ó wà nínú ìdáná, títí tí gbogbo ìwé kíká náà fi jóná tán.
24 Aole nae lakou i makau, aole i haehae i ko lakou aahu, aole ke alii, aole kekahi o kana mau kauwa i lohe i keia mau olelo a pau.
Síbẹ̀, ọba àti gbogbo àwọn ẹ̀mẹwà rẹ̀ tí wọ́n gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí kò bẹ̀rù; wọn kò sì fa aṣọ wọn yá.
25 Aka, ua nonoi aku a Elenatana a me Delaia a me Gemaria i ke alii i ole ia e puhi i ka owili. Aole ia i hoolohe mai i ka lakou.
Elnatani, Delaiah àti Gemariah sì bẹ ọba kí ó má ṣe fi ìwé kíká náà jóná, ṣùgbọ́n ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn.
26 Alaila, kena ae la ke alii ia Ierameela, ke keiki a Hameleka, a me Seraia, ke keiki a Azeriela, a me Selemia, ke keiki a Abedeela, e kii ia Baruka i ke kakauolelo, a me Ieremia ke kaula; huna nae o Iehova ia laua.
Dípò èyí ọba pàṣẹ fún Jerahmeeli ọmọ Hameleki, Seraiah ọmọ Asrieli àti Ṣelemiah ọmọ Abdeeli láti mú Baruku akọ̀wé àti Jeremiah wòlíì ṣùgbọ́n Olúwa fi wọ́n pamọ́.
27 Alaila hiki mai ka olelo a Iehova io Ieremia la, mahope iho o ka puhi ana o ke alii i ka owili, a me na olelo o Baruka i kakau ai mai ka waha mai o Ieremia, i mai la,
Lẹ́yìn tí ọba fi ìwé kíká náà tí ọ̀rọ̀ tí Baruku kọ láti ẹnu Jeremiah jóná tán, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá:
28 E lawe oe i owili hou nau, a e kakau iho maloko olaila i na olelo a pau o ka owili mua, ka mea a Iehoiakima ke alii o ka Iuda i puhi ai.
“Wí pé, tún mú ìwé kíká mìíràn kí o sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé kíká èkínní tí Jehoiakimu ọba Juda fi jóná.
29 A e olelo aku oe ia Iehoiakima, i ke alii o ka Iuda, Ke olelo mai nei o Iehova, penei; Ua puhi oe i keia owili, me ka ninau iho, No ke aha la oe i palapala maloko, i ka i ana ae, E oiaio no e hele mai ke alii o Babulona a e luku i keia aina, a e hoopau i ke kanaka a me ka holoholona, mai ia wahi aku?
Kí o sì wí fún Jehoiakimu ọba Juda pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ti fi ìwé kíká náà jóná, o sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi kọ̀wé sínú rẹ̀, pé lóòtítọ́ ni ọba Babeli yóò wá, yóò sì pa ilẹ̀ run, àti ènìyàn, àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀.”
30 Nolaila, ke olelo mai nei o Iehova, no Iehoiakima ke alii o ka Iuda penei; Aole e loaa ia ia ka mea nana e noho maluna o ka nohoalii o Davida: a e hoolei wale ia kona kupapau mawaho i ke ao ma ka wela, a i ka po ma ke hau.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí ní ti Jehoiakimu ọba Juda pé, Òun kì yóò ní ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, à ó sì sọ òkú rẹ̀ nù fún ooru ní ọ̀sán àti fún òtútù ní òru.
31 A nau no e hoopai aku ia ia, a me kana poe mamo, a me kana mau kauwa, no ko lakou hewa; a na'u no e lawe aku maluna o lakou, a maluna o ka poe e noho la ma Ierusalema, a maluna o na kanaka o ka Iuda, i ka hewa a pau a'u i olelo ai no lakou; aole nae lakou i hoolohe mai.
Èmi ó sì jẹ òun àti irú-ọmọ rẹ̀, ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ìyà nítorí àìṣedéédéé wọn; èmi ó sì mú gbogbo ibi tí èmi ti sọ sí wọn wá sórí wọn, àti sórí àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn Juda, nítorí tí wọn kò fetísí mi.’”
32 Alaila, lawe ae la o Ieremia i owili hou, a haawi ae la ia ia Baruka, i ke kakauolelo, ke keiki a Neria; a kakau iho la oia mai ka waha mai o Ieremia, i na olelo a pau o ka buke a Iehoiakima ke alii o ka Iuda i puhi ai iloko o ke ahi; a nui na olelo like i hoopili pu ia me lakou.
Nígbà náà ni Jeremiah mú ìwé kíká mìíràn fún Baruku akọ̀wé ọmọ Neriah, ẹni tí ó kọ̀wé sínú rẹ̀ láti ẹnu Jeremiah gbogbo ọ̀rọ̀ inú ìwé tí Jehoiakimu ọba Juda ti sun níná. A sì fi onírúurú ọ̀rọ̀ bí irú èyí kún pẹ̀lú.

< Ieremia 36 >